ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني سورة: النبإ   آية:

سورة النبإ - Suuratun-Naba'

عَمَّ يَتَسَآءَلُونَ
Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
التفاسير العربية:
عَنِ ٱلنَّبَإِ ٱلۡعَظِيمِ
Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
التفاسير العربية:
ٱلَّذِي هُمۡ فِيهِ مُخۡتَلِفُونَ
èyí tí wọ́n ń yapa-ẹnu lórí rẹ̀.
التفاسير العربية:
كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
التفاسير العربية:
ثُمَّ كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Lẹ́yìn náà, rárá sẹ́, wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
التفاسير العربية:
أَلَمۡ نَجۡعَلِ ٱلۡأَرۡضَ مِهَٰدٗا
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
التفاسير العربية:
وَٱلۡجِبَالَ أَوۡتَادٗا
àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
التفاسير العربية:
وَخَلَقۡنَٰكُمۡ أَزۡوَٰجٗا
A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
التفاسير العربية:
وَجَعَلۡنَا نَوۡمَكُمۡ سُبَاتٗا
A ṣe oorun yín ní ìsinmi.
التفاسير العربية:
وَجَعَلۡنَا ٱلَّيۡلَ لِبَاسٗا
A tún ṣe alẹ́ ní ìbora.
التفاسير العربية:
وَجَعَلۡنَا ٱلنَّهَارَ مَعَاشٗا
A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
التفاسير العربية:
وَبَنَيۡنَا فَوۡقَكُمۡ سَبۡعٗا شِدَادٗا
A tún mọ sánmọ̀ méje tó lágbára sókè yín.
التفاسير العربية:
وَجَعَلۡنَا سِرَاجٗا وَهَّاجٗا
A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ tó ń tàn gbòlà.
التفاسير العربية:
وَأَنزَلۡنَا مِنَ ٱلۡمُعۡصِرَٰتِ مَآءٗ ثَجَّاجٗا
Àti pé A sọ omi tó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
التفاسير العربية:
لِّنُخۡرِجَ بِهِۦ حَبّٗا وَنَبَاتٗا
nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
التفاسير العربية:
وَجَنَّٰتٍ أَلۡفَافًا
pẹ̀lú àwọn ọgbà tó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
التفاسير العربية:
إِنَّ يَوۡمَ ٱلۡفَصۡلِ كَانَ مِيقَٰتٗا
Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
التفاسير العربية:
يَوۡمَ يُنفَخُ فِي ٱلصُّورِ فَتَأۡتُونَ أَفۡوَاجٗا
(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
التفاسير العربية:
وَفُتِحَتِ ٱلسَّمَآءُ فَكَانَتۡ أَبۡوَٰبٗا
Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
التفاسير العربية:
وَسُيِّرَتِ ٱلۡجِبَالُ فَكَانَتۡ سَرَابًا
Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
التفاسير العربية:
إِنَّ جَهَنَّمَ كَانَتۡ مِرۡصَادٗا
Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
التفاسير العربية:
لِّلطَّٰغِينَ مَـَٔابٗا
(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
التفاسير العربية:
لَّٰبِثِينَ فِيهَآ أَحۡقَابٗا
Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
التفاسير العربية:
لَّا يَذُوقُونَ فِيهَا بَرۡدٗا وَلَا شَرَابًا
Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
التفاسير العربية:
إِلَّا حَمِيمٗا وَغَسَّاقٗا
àyàfi omi tó gbóná parí àti àwọnúwẹ̀jẹ̀.
التفاسير العربية:
جَزَآءٗ وِفَاقًا
(Ó jẹ́) ẹ̀san tó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
التفاسير العربية:
إِنَّهُمۡ كَانُواْ لَا يَرۡجُونَ حِسَابٗا
Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
التفاسير العربية:
وَكَذَّبُواْ بِـَٔايَٰتِنَا كِذَّابٗا
Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa ní irọ́ gan-an.
التفاسير العربية:
وَكُلَّ شَيۡءٍ أَحۡصَيۡنَٰهُ كِتَٰبٗا
Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
التفاسير العربية:
فَذُوقُواْ فَلَن نَّزِيدَكُمۡ إِلَّا عَذَابًا
Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fún yín bí kò ṣe ìyà.
التفاسير العربية:
إِنَّ لِلۡمُتَّقِينَ مَفَازًا
Dájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
التفاسير العربية:
حَدَآئِقَ وَأَعۡنَٰبٗا
Àwọn ọgbà oko àti èso àjàrà,
التفاسير العربية:
وَكَوَاعِبَ أَتۡرَابٗا
àti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,
التفاسير العربية:
وَكَأۡسٗا دِهَاقٗا
àti ife ọtí tó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).
التفاسير العربية:
لَّا يَسۡمَعُونَ فِيهَا لَغۡوٗا وَلَا كِذَّٰبٗا
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.
التفاسير العربية:
جَزَآءٗ مِّن رَّبِّكَ عَطَآءً حِسَابٗا
(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).
التفاسير العربية:
رَّبِّ ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَٱلۡأَرۡضِ وَمَا بَيۡنَهُمَا ٱلرَّحۡمَٰنِۖ لَا يَمۡلِكُونَ مِنۡهُ خِطَابٗا
(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun tó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.
التفاسير العربية:
يَوۡمَ يَقُومُ ٱلرُّوحُ وَٱلۡمَلَٰٓئِكَةُ صَفّٗاۖ لَّا يَتَكَلَّمُونَ إِلَّا مَنۡ أَذِنَ لَهُ ٱلرَّحۡمَٰنُ وَقَالَ صَوَابٗا
Ọjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ tó máa ṣe wẹ́kú.
التفاسير العربية:
ذَٰلِكَ ٱلۡيَوۡمُ ٱلۡحَقُّۖ فَمَن شَآءَ ٱتَّخَذَ إِلَىٰ رَبِّهِۦ مَـَٔابًا
Ìyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).
التفاسير العربية:
إِنَّآ أَنذَرۡنَٰكُمۡ عَذَابٗا قَرِيبٗا يَوۡمَ يَنظُرُ ٱلۡمَرۡءُ مَا قَدَّمَتۡ يَدَاهُ وَيَقُولُ ٱلۡكَافِرُ يَٰلَيۡتَنِي كُنتُ تُرَٰبَۢا
Dájúdájú A fi ìyà tó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fún yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: “Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà).”
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني سورة: النبإ
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق