ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني سورة: التكوير   آية:

سورة التكوير - Suuratut-Takweer

إِذَا ٱلشَّمۡسُ كُوِّرَتۡ
Nígbà tí wọ́n bá ká òòrùn kóróbójó dànù,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلنُّجُومُ ٱنكَدَرَتۡ
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلۡجِبَالُ سُيِّرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá mú àwọn àpáta rìn (kúrò ní àyè wọn, tí wọ́n kù wọ́n dànù),
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلۡعِشَارُ عُطِّلَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá pa àwọn ràkúnmí aboyún tì,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلۡوُحُوشُ حُشِرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ko àwọn ẹranko jọ,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلۡبِحَارُ سُجِّرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá mú àwọn agbami odò gbiná,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلنُّفُوسُ زُوِّجَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá so àwọn ẹ̀mí pọ̀ mọ́ra wọn, (ẹni rere pẹ̀lú ẹni rere, ẹni ibi pẹ̀lú ẹni ibi)
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلۡمَوۡءُۥدَةُ سُئِلَتۡ
àti nígbà tí ọmọbìnrin tí wọ́n bò mọ́lẹ̀ láàyè bá bèèrè pé
التفاسير العربية:
بِأَيِّ ذَنۢبٖ قُتِلَتۡ
ẹ̀ṣẹ̀ wo ni wọ́n pa òun fún,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلصُّحُفُ نُشِرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ṣí àwọn tákàdá (iṣẹ́ ẹ̀dá) sílẹ̀,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلسَّمَآءُ كُشِطَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ká sánmọ̀ kúrò lókè,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلۡجَحِيمُ سُعِّرَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá mú iná Jẹhīm jò fòfò,
التفاسير العربية:
وَإِذَا ٱلۡجَنَّةُ أُزۡلِفَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá sún Ọgbà Ìdẹ̀ra mọ́ (àwọn onígbàgbọ́ òdodo),
التفاسير العربية:
عَلِمَتۡ نَفۡسٞ مَّآ أَحۡضَرَتۡ
(nígbà náà ni) ẹ̀mí (kọ̀ọ̀kan) yóò mọ ohun tí ó mú wá (nínú iṣẹ́ ire àti iṣẹ́ ibi).
التفاسير العربية:
فَلَآ أُقۡسِمُ بِٱلۡخُنَّسِ
Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń fi àwọn ìràwọ̀ tó ń yọ ní alẹ́, tó ń wọ̀ọ̀kùn ní ọ̀sán búra,
التفاسير العربية:
ٱلۡجَوَارِ ٱلۡكُنَّسِ
(ìyẹn) àwọn ìràwọ̀ tó ń rìn lọ rìn bọ̀, tó ń wọ̀ọ̀kùn sí ibùwọ̀ wọn.
التفاسير العربية:
وَٱلَّيۡلِ إِذَا عَسۡعَسَ
Mo tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.¹
1. Ìtúmọ̀ mìíràn: Mo tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá wọlé búra.
التفاسير العربية:
وَٱلصُّبۡحِ إِذَا تَنَفَّسَ
Mo tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ó bá mọ́lẹ̀ búra.
التفاسير العربية:
إِنَّهُۥ لَقَوۡلُ رَسُولٖ كَرِيمٖ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán Jibrīl) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé,¹
1. Wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Hāƙƙọh; 69:40.
التفاسير العربية:
ذِي قُوَّةٍ عِندَ ذِي ٱلۡعَرۡشِ مَكِينٖ
alágbára, ẹni pàtàkì ní ọ̀dọ̀ Ẹni t’Ó ni Ìtẹ́-ọlá,
التفاسير العربية:
مُّطَاعٖ ثَمَّ أَمِينٖ
ẹni tí wọ́n ń tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ níbẹ̀ yẹn (nínú sánmọ̀), olùfọkàntán.
التفاسير العربية:
وَمَا صَاحِبُكُم بِمَجۡنُونٖ
Àti pé ẹni yín (Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -) kì í ṣe wèrè.
التفاسير العربية:
وَلَقَدۡ رَءَاهُ بِٱلۡأُفُقِ ٱلۡمُبِينِ
Ó kúkú rí i nínú òfurufú kedere.¹
1. Ìyẹn ni pé, Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - fojú ara rẹ̀ rí Mọlāika Jibrīl - kí ọlà Allāhu máa bá a - nínú òfurufú kedere. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah an-Najm; 53:13.
التفاسير العربية:
وَمَا هُوَ عَلَى ٱلۡغَيۡبِ بِضَنِينٖ
Àti pé kì í ṣe ahun (tàbí ẹni-afurasí) lórí ìró ìkọ̀kọ̀ (tí A fi ránṣẹ́ sí i).
التفاسير العربية:
وَمَا هُوَ بِقَوۡلِ شَيۡطَٰنٖ رَّجِيمٖ
Al-Ƙur’ān kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) Èṣù, ẹni ẹ̀kọ̀.
التفاسير العربية:
فَأَيۡنَ تَذۡهَبُونَ
Nítorí náà, ibo l’ẹ̀ ń lọ?
التفاسير العربية:
إِنۡ هُوَ إِلَّا ذِكۡرٞ لِّلۡعَٰلَمِينَ
Kí sì ni al-Ƙur’ān bí kò ṣe ìrántí fún gbogbo ẹ̀dá.
التفاسير العربية:
لِمَن شَآءَ مِنكُمۡ أَن يَسۡتَقِيمَ
(Ó wà) fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti dúró déédé.
التفاسير العربية:
وَمَا تَشَآءُونَ إِلَّآ أَن يَشَآءَ ٱللَّهُ رَبُّ ٱلۡعَٰلَمِينَ
Ẹ̀yin kò sì níí fẹ́ (láti dúró déédé) àyàfi tí Allāhu bá fẹ́, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني سورة: التكوير
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق