ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني سورة: الفجر   آية:

سورة الفجر - Suuratul-Faj'r

وَٱلۡفَجۡرِ
Allāhu fi àfẹ̀mọ́júmọ́ búra.
التفاسير العربية:
وَلَيَالٍ عَشۡرٖ
Ó tún fi àwọn òru mẹ́wàá kan búra.
التفاسير العربية:
وَٱلشَّفۡعِ وَٱلۡوَتۡرِ
Ó tún fi n̄ǹkan tí eéjì ń pín geerege àti n̄ǹkan tí eéjì kò pín geerege búra.
التفاسير العربية:
وَٱلَّيۡلِ إِذَا يَسۡرِ
Ó tún fi òru nígbà tí ó bá dé búra.
التفاسير العربية:
هَلۡ فِي ذَٰلِكَ قَسَمٞ لِّذِي حِجۡرٍ
Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?
التفاسير العربية:
أَلَمۡ تَرَ كَيۡفَ فَعَلَ رَبُّكَ بِعَادٍ
Ṣé o kò wòye sí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,
التفاسير العربية:
إِرَمَ ذَاتِ ٱلۡعِمَادِ
(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,
التفاسير العربية:
ٱلَّتِي لَمۡ يُخۡلَقۡ مِثۡلُهَا فِي ٱلۡبِلَٰدِ
àwọn tí A kò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?
التفاسير العربية:
وَثَمُودَ ٱلَّذِينَ جَابُواْ ٱلصَّخۡرَ بِٱلۡوَادِ
Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonúfojì,
التفاسير العربية:
وَفِرۡعَوۡنَ ذِي ٱلۡأَوۡتَادِ
àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?
التفاسير العربية:
ٱلَّذِينَ طَغَوۡاْ فِي ٱلۡبِلَٰدِ
(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn tó tayọ ẹnu-ààlà nínú ìlú.
التفاسير العربية:
فَأَكۡثَرُواْ فِيهَا ٱلۡفَسَادَ
Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.
التفاسير العربية:
فَصَبَّ عَلَيۡهِمۡ رَبُّكَ سَوۡطَ عَذَابٍ
Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.
التفاسير العربية:
إِنَّ رَبَّكَ لَبِٱلۡمِرۡصَادِ
Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).
التفاسير العربية:
فَأَمَّا ٱلۡإِنسَٰنُ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ رَبُّهُۥ فَأَكۡرَمَهُۥ وَنَعَّمَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَكۡرَمَنِ
Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti pọ́n mi lé.”
التفاسير العربية:
وَأَمَّآ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ فَقَدَرَ عَلَيۡهِ رِزۡقَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَهَٰنَنِ
Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi.”
التفاسير العربية:
كَلَّاۖ بَل لَّا تُكۡرِمُونَ ٱلۡيَتِيمَ
Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.
التفاسير العربية:
وَلَا تَحَٰٓضُّونَ عَلَىٰ طَعَامِ ٱلۡمِسۡكِينِ
Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.
التفاسير العربية:
وَتَأۡكُلُونَ ٱلتُّرَاثَ أَكۡلٗا لَّمّٗا
Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.
التفاسير العربية:
وَتُحِبُّونَ ٱلۡمَالَ حُبّٗا جَمّٗا
Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.
التفاسير العربية:
كَلَّآۖ إِذَا دُكَّتِ ٱلۡأَرۡضُ دَكّٗا دَكّٗا
Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (tó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),
التفاسير العربية:
وَجَآءَ رَبُّكَ وَٱلۡمَلَكُ صَفّٗا صَفّٗا
(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,
التفاسير العربية:
وَجِاْيٓءَ يَوۡمَئِذِۭ بِجَهَنَّمَۚ يَوۡمَئِذٖ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ وَأَنَّىٰ لَهُ ٱلذِّكۡرَىٰ
ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!
التفاسير العربية:
يَقُولُ يَٰلَيۡتَنِي قَدَّمۡتُ لِحَيَاتِي
Ó máa wí pé: “Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi.”
التفاسير العربية:
فَيَوۡمَئِذٖ لَّا يُعَذِّبُ عَذَابَهُۥٓ أَحَدٞ
Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).
التفاسير العربية:
وَلَا يُوثِقُ وَثَاقَهُۥٓ أَحَدٞ
Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).
التفاسير العربية:
يَٰٓأَيَّتُهَا ٱلنَّفۡسُ ٱلۡمُطۡمَئِنَّةُ
Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,
التفاسير العربية:
ٱرۡجِعِيٓ إِلَىٰ رَبِّكِ رَاضِيَةٗ مَّرۡضِيَّةٗ
padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.
التفاسير العربية:
فَٱدۡخُلِي فِي عِبَٰدِي
Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.
التفاسير العربية:
وَٱدۡخُلِي جَنَّتِي
Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني سورة: الفجر
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق