Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Surah: Al-Hāqqah   Ayah:

Suuratul-Haaqqah

ٱلۡحَآقَّةُ
Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo náà!
Arabic explanations of the Qur’an:
مَا ٱلۡحَآقَّةُ
Kí ni Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo náà?
Arabic explanations of the Qur’an:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا ٱلۡحَآقَّةُ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo náà?
Arabic explanations of the Qur’an:
كَذَّبَتۡ ثَمُودُ وَعَادُۢ بِٱلۡقَارِعَةِ
Àwọn ìjọ Thamūd àti ìjọ ‘Ād pe Àjíǹde (ajámọláya bí àrá) ní irọ́.¹
1. Nínú àwọn orúkọ fún Ọjọ́ Àjíǹde ni Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo náà àti Ajámọláyà bí àrá.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَأَمَّا ثَمُودُ فَأُهۡلِكُواْ بِٱلطَّاغِيَةِ
Ní ti ìjọ Thamūd, wọ́n fi igbe tó tayọ ẹnu-ààlà pa wọ́n rẹ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَأَمَّا عَادٞ فَأُهۡلِكُواْ بِرِيحٖ صَرۡصَرٍ عَاتِيَةٖ
Ní ti ìjọ ‘Ād, wọ́n fi atẹ́gùn líle tó tayọ ẹnu-ààlà pa wọ́n rẹ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
سَخَّرَهَا عَلَيۡهِمۡ سَبۡعَ لَيَالٖ وَثَمَٰنِيَةَ أَيَّامٍ حُسُومٗاۖ فَتَرَى ٱلۡقَوۡمَ فِيهَا صَرۡعَىٰ كَأَنَّهُمۡ أَعۡجَازُ نَخۡلٍ خَاوِيَةٖ
Ó dẹ ẹ́ sí wọn fún òru méje àti ọ̀sán mẹ́jọ láì dáwọ́ dúró. O sì máa rí ìjọ náà tí wọ́n ti kú sínú rẹ̀ bí ẹni pé kùkùté igi dàbínù tó ti luhò nínú ni wọ́n.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah Fussilat; 41:16.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَهَلۡ تَرَىٰ لَهُم مِّنۢ بَاقِيَةٖ
Ǹjẹ́ o rí ẹnì kan nínú wọn tó ṣẹ́ kù bí?
Arabic explanations of the Qur’an:
وَجَآءَ فِرۡعَوۡنُ وَمَن قَبۡلَهُۥ وَٱلۡمُؤۡتَفِكَٰتُ بِٱلۡخَاطِئَةِ
Fir‘aon àti àwọn tó ṣíwájú rẹ̀ àti àwọn ìlú tí wọ́n dojú rẹ̀ bolẹ̀ dé pẹ̀lú àwọn àṣìṣe.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَعَصَوۡاْ رَسُولَ رَبِّهِمۡ فَأَخَذَهُمۡ أَخۡذَةٗ رَّابِيَةً
Wọ́n yapa Òjíṣẹ́ Olúwa wọn. Ó sì gbá wọn mú ní ìgbámú tóléken̄kà.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّا لَمَّا طَغَا ٱلۡمَآءُ حَمَلۡنَٰكُمۡ فِي ٱلۡجَارِيَةِ
Dájúdájú nígbà tí omi tayọ ẹnu-ààlà. A gbe yín gun ọkọ̀ ojú-omi.
Arabic explanations of the Qur’an:
لِنَجۡعَلَهَا لَكُمۡ تَذۡكِرَةٗ وَتَعِيَهَآ أُذُنٞ وَٰعِيَةٞ
Nítorí kí Á lè fi ṣe ìrántí fún yín àti nítorí kí etí tó ń ṣọ́ n̄ǹkan lè ṣọ́ ọ.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَإِذَا نُفِخَ فِي ٱلصُّورِ نَفۡخَةٞ وَٰحِدَةٞ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún ikú ní fífọn ẹyọ kan,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَحُمِلَتِ ٱلۡأَرۡضُ وَٱلۡجِبَالُ فَدُكَّتَا دَكَّةٗ وَٰحِدَةٗ
tí wọ́n gbé ilẹ̀ àti àpáta sókè, tí wọ́n sì rún méjèèjì wómúwómú ní rírún ẹ̀ẹ̀ kan,
Arabic explanations of the Qur’an:
فَيَوۡمَئِذٖ وَقَعَتِ ٱلۡوَاقِعَةُ
ní ọjọ́ yẹn ni Ìṣẹ̀lẹ̀ máa ṣẹlẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱنشَقَّتِ ٱلسَّمَآءُ فَهِيَ يَوۡمَئِذٖ وَاهِيَةٞ
Àti pé sánmọ̀ yó fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Ó sì máa fúyẹ́ gẹgẹ ní ọjọ́ yẹn.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱلۡمَلَكُ عَلَىٰٓ أَرۡجَآئِهَاۚ وَيَحۡمِلُ عَرۡشَ رَبِّكَ فَوۡقَهُمۡ يَوۡمَئِذٖ ثَمَٰنِيَةٞ
Àwọn mọlāika sì máa wà ní àwọn ẹ̀gbẹ́ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àti pé ní ọjọ́ yẹn, lókè wọn, àwọn (mọlāika) mẹ́jọ ni wọ́n máa ru Ìtẹ́ Olúwa rẹ.
Arabic explanations of the Qur’an:
يَوۡمَئِذٖ تُعۡرَضُونَ لَا تَخۡفَىٰ مِنكُمۡ خَافِيَةٞ
Ní ọjọ́ yẹn, wọn yóò máa ṣẹ́rí yín wá (fún ìṣírò-iṣẹ́). Kò sì níí sí àṣírí yín kan tó máa pamọ́ (fún Wa).
Arabic explanations of the Qur’an:
فَأَمَّا مَنۡ أُوتِيَ كِتَٰبَهُۥ بِيَمِينِهِۦ فَيَقُولُ هَآؤُمُ ٱقۡرَءُواْ كِتَٰبِيَهۡ
Nítorí náà, ní ti ẹni tí wọ́n bá fún ní tírà rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, ó máa sọ pé: “Ẹ gbà, ẹ ka tírà mi wò.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنِّي ظَنَنتُ أَنِّي مُلَٰقٍ حِسَابِيَهۡ
Dájúdájú èmi ti mọ àmọ̀dájú pé dájúdájú èmi yóò bá ìṣírò-iṣẹ́ mi pàdé.”
Arabic explanations of the Qur’an:
فَهُوَ فِي عِيشَةٖ رَّاضِيَةٖ
Nítorí náà, ó máa wà nínú ìṣẹ̀mí tó máa yọ́nú sí
Arabic explanations of the Qur’an:
فِي جَنَّةٍ عَالِيَةٖ
nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.
Arabic explanations of the Qur’an:
قُطُوفُهَا دَانِيَةٞ
Àwọn èso rẹ̀ (sì) máa wà ní àrọ́wọ́tó.
Arabic explanations of the Qur’an:
كُلُواْ وَٱشۡرَبُواْ هَنِيٓـَٔۢا بِمَآ أَسۡلَفۡتُمۡ فِي ٱلۡأَيَّامِ ٱلۡخَالِيَةِ
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbàdún nítorí ohun tí ẹ tì síwájú nínú àwọn ọjọ́ tí ó ti ré kọjá.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَأَمَّا مَنۡ أُوتِيَ كِتَٰبَهُۥ بِشِمَالِهِۦ فَيَقُولُ يَٰلَيۡتَنِي لَمۡ أُوتَ كِتَٰبِيَهۡ
Ní ti ẹni tí wọ́n bá sì fún ní tírà rẹ̀ ní ọwọ́ òsì rẹ̀, ó máa wí pé: “Háà! Kí wọ́n sì má fún mi ni tírà mi!¹
1. Àwọn nasọ̄rọ̄ sọ pé, “Āyah yìí ń sọ pé ọwọ́ òsì ni àwọn aláìgbàgbọ́ máa fi gba ìwé iṣẹ́ wọn, àmọ́ sūrah al-’Inṣiƙọ̄ƙ; 84:10 ń sọ pé láti ẹ̀yìn ni wọ́n máa ti gbà á.” Wọ́n ní, “Ìtakora nìyẹn!”
Èsì: Ìtakora tófẹ́jọbẹ́ẹ̀ ni, kì í ṣe ìtakora tóríbẹ́ẹ̀. Àlàyé rẹ̀ nìyí, méjéèjì ló máa ṣẹlẹ̀ sí wọn nítorí pé, ọwọ́ òsì ni aláìgbàgbọ́ máa tì bọ inú igbá-àyà rẹ̀ bọ́ sí ẹ̀yìn rẹ̀ láti fi gba ìwé iṣẹ́ rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَمۡ أَدۡرِ مَا حِسَابِيَهۡ
Àti pé kí èmi sì má mọ ohun tí ìṣírò-iṣẹ́ mi jẹ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
يَٰلَيۡتَهَا كَانَتِ ٱلۡقَاضِيَةَ
Háà! Kí ikú sì jẹ́ òpin (ọ̀rọ̀ ẹ̀dá).
Arabic explanations of the Qur’an:
مَآ أَغۡنَىٰ عَنِّي مَالِيَهۡۜ
Dúkìá mi kò sì rọ̀ mí lọ́rọ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
هَلَكَ عَنِّي سُلۡطَٰنِيَهۡ
Agbára mi sì ti parun.”
Arabic explanations of the Qur’an:
خُذُوهُ فَغُلُّوهُ
Ẹ mú un, kí ẹ dè é ní ọwọ́ mọ́ ọrùn.
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ ٱلۡجَحِيمَ صَلُّوهُ
Lẹ́yìn náà, inú iná Jẹhīm ni kí ẹ mú un wọ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ فِي سِلۡسِلَةٖ ذَرۡعُهَا سَبۡعُونَ ذِرَاعٗا فَٱسۡلُكُوهُ
Lẹ́yìn náà, inú ẹ̀wọ̀n tí gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin gígùn thar‘u¹ ni kí ẹ kì í sí.
1. Gígùn “Thar‘u” kan ni gígùn láti ìlú Mọkkah sí ibi tí ó jìnnà jùlọ sí ìlú Mọkkah.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّهُۥ كَانَ لَا يُؤۡمِنُ بِٱللَّهِ ٱلۡعَظِيمِ
Dájúdájú òun kì í gbàgbọ́ nínú Allāhu, Atóbi.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَا يَحُضُّ عَلَىٰ طَعَامِ ٱلۡمِسۡكِينِ
Kì í sì gba ènìyàn níyànjú láti bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَلَيۡسَ لَهُ ٱلۡيَوۡمَ هَٰهُنَا حَمِيمٞ
Nítorí náà, kò níí sí ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ kan fún un níbí yìí ní òní.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَا طَعَامٌ إِلَّا مِنۡ غِسۡلِينٖ
Kò sì níí sí oúnjẹ kan (fún un) bí kò ṣe (oúnjẹ) àwọnúwẹ̀jẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
لَّا يَأۡكُلُهُۥٓ إِلَّا ٱلۡخَٰطِـُٔونَ
Kò sí ẹni tí ó máa jẹ ẹ́ bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَلَآ أُقۡسِمُ بِمَا تُبۡصِرُونَ
Nítorí náà, Èmi ń fi ohun tí ẹ̀ ń fojú rí búra
Arabic explanations of the Qur’an:
وَمَا لَا تُبۡصِرُونَ
àti ohun tí ẹ ò fojú rí.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّهُۥ لَقَوۡلُ رَسُولٖ كَرِيمٖ
Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé.¹
1. “Ọ̀rọ̀ òjíṣẹ́” ni ìtúmọ̀ “ƙọolu rọsūl, àmọ́ al-Ƙur’ān kì í ṣe ọ̀rọ̀ Òjíṣẹ́ bí kò ṣe “Ọ̀rọ̀ Allāhu”. Àgbékalẹ̀ irúfẹ́ ọ̀rọ̀ yìí ni ṣíṣe àfitì ọ̀rọ̀ sí ọ̀dọ̀ alágbàsọ. Bákan náà, āyah yìí jọ āyah 19 nínú sūrah at-Tẹkwīr ní ìsọ, àmọ “Òjíṣẹ́” tí wọ́n gbàlérò nínú āyah ti sūrah al-Hāƙƙọh ni Òjíṣẹ́ abara, ìyẹn Ànábì wa Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, Òjíṣẹ́ mọlāika ni wọ́n sì gbàlérò nínú āyah ti sūrah at-Tẹkwīr. Sàkánì ti ìkọ̀ọ̀kan ti jẹyọ l’ó ṣàfi hàn èyí bẹ́ẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَمَا هُوَ بِقَوۡلِ شَاعِرٖۚ قَلِيلٗا مَّا تُؤۡمِنُونَ
Kì í ṣe ọ̀rọ̀ eléwì. Ohun tí ẹ gbàgbọ́ kéré púpọ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَا بِقَوۡلِ كَاهِنٖۚ قَلِيلٗا مَّا تَذَكَّرُونَ
Kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ adábigba. Díẹ̀ lẹ̀ ń lò nínú ìrántí.
Arabic explanations of the Qur’an:
تَنزِيلٞ مِّن رَّبِّ ٱلۡعَٰلَمِينَ
Wọ́n sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَوۡ تَقَوَّلَ عَلَيۡنَا بَعۡضَ ٱلۡأَقَاوِيلِ
Tí ó bá jẹ́ pé (Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ) dá àdápa apá kan ọ̀rọ̀ náà mọ́ Wa ni,
Arabic explanations of the Qur’an:
لَأَخَذۡنَا مِنۡهُ بِٱلۡيَمِينِ
Àwa ìbá gbá a mú lọ́wọ́ ọ̀tún.
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ لَقَطَعۡنَا مِنۡهُ ٱلۡوَتِينَ
Lẹ́yìn náà, Àwa ìbá já isan ọrùn rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَمَا مِنكُم مِّنۡ أَحَدٍ عَنۡهُ حَٰجِزِينَ
Kò sì sí ẹnì kan nínú yín tí ó máa gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ (Wa).
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِنَّهُۥ لَتَذۡكِرَةٞ لِّلۡمُتَّقِينَ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ìrántí fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِنَّا لَنَعۡلَمُ أَنَّ مِنكُم مُّكَذِّبِينَ
Dájúdájú Àwa sì mọ̀ pé àwọn tó ń pe al-Ƙur’ān ní irọ́ wà nínú yín.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِنَّهُۥ لَحَسۡرَةٌ عَلَى ٱلۡكَٰفِرِينَ
Dájúdájú al-Ƙur’ān máa jẹ́ àbámọ̀ ńlá fún àwọn aláìgbàgbọ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِنَّهُۥ لَحَقُّ ٱلۡيَقِينِ
Dájúdájú al-Ƙur’ān ni òdodo tó dájú.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَسَبِّحۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلۡعَظِيمِ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa Rẹ, Atóbi.
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Surah: Al-Hāqqah
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close