Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Sourate: AN-NAJM   Verset:

Suuratun-Naj'm

وَٱلنَّجۡمِ إِذَا هَوَىٰ
Allāhu fi gbólóhùn kọ̀ọ̀kan nínú al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé nígbà tí ó bá sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ búra.¹
1. Ìtúmọ̀ kejì ni pé, Allāhu fi ìràwọ̀ nígbà tí ó bá wálẹ̀ (wọ̀ọ̀kùn ní ìdájí) búra. Àmọ́ ìtúmọ̀ àkọ́kọ́ ló súnmọ́ jùlọ ní ìbámu sí sàkánì rẹ̀ pẹ̀lú àwọn āyah tí ó tẹ̀lé e.
Wòóore! Wọ́n ń pe gbólóhùn ẹyọ kọ̀ọ̀kan nínú al-Ƙur’ān ní “an-najm”. Wọ́n sì ń pe ìràwọ̀ ní “an-najm”. Kódà “ìtàkùn” náà ń jẹ́ “an-najm” nínú èdè Lárúbáwá.(Tafsīr ’Adwā’ul-bayān)
Les exégèses en arabe:
مَا ضَلَّ صَاحِبُكُمۡ وَمَا غَوَىٰ
Ẹni yín kò ṣìnà, kò sì sọnù.¹
1. Ènìyàn “dọlla” nígbà tí ó bá fi àìmọ̀kan sẹ̀sìn. Ènìyàn tí kò tẹ̀lé ìmọ̀ tí ó mọ̀, òun ló “gawā”. Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - kò fi àìmọ̀kan sẹ̀sìn. Kò sì yapa ìmọ̀ tí Allāhu sọ̀kalẹ̀ fún un.
Les exégèses en arabe:
وَمَا يَنطِقُ عَنِ ٱلۡهَوَىٰٓ
Àti pé kò níí sọ̀rọ̀ ìfẹ́-inú.
Les exégèses en arabe:
إِنۡ هُوَ إِلَّا وَحۡيٞ يُوحَىٰ
Kò níí sọ ohun kan tayọ ìmísí tí A fi ránṣẹ́ sí i.¹
1. Ìyẹn ni pé, ìmísí mímọ́ ni al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé àti sunnah Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -. Àmọ́ ìgbàkígbà tí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - bá kánjú ṣíwájú ìmísí gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́ran ara, Allāhu kì í fi bùn un bí kò ṣe pé, ìmísì máa wá lórí rẹ̀ láti tètè ṣàtúnṣe rẹ̀.
Les exégèses en arabe:
عَلَّمَهُۥ شَدِيدُ ٱلۡقُوَىٰ
Alágbára (ìyẹn, mọlāika Jibrīl) l’ó kọ́ ọ ní ìmọ̀ (al-Ƙur’ān).
Les exégèses en arabe:
ذُو مِرَّةٖ فَٱسۡتَوَىٰ
Ó ní àlàáfíà tó péye, ó sì dúró wámúwámú,
Les exégèses en arabe:
وَهُوَ بِٱلۡأُفُقِ ٱلۡأَعۡلَىٰ
nígbà tí ó wà nínú òfurufú lókè pátápátá.
Les exégèses en arabe:
ثُمَّ دَنَا فَتَدَلَّىٰ
Lẹ́yìn náà, ó sún mọ́ (Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -). Ó sì sọ̀kalẹ̀ (tọ̀ ọ́ wá).
Les exégèses en arabe:
فَكَانَ قَابَ قَوۡسَيۡنِ أَوۡ أَدۡنَىٰ
(Àlàfo ààrin àwọn méjèèjì) sì tó ìwọ̀n ọrún ọfà méjì, tàbí kí ó kéré (sí ìyẹn).¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:74.
Les exégèses en arabe:
فَأَوۡحَىٰٓ إِلَىٰ عَبۡدِهِۦ مَآ أَوۡحَىٰ
Allāhu sì fún ẹrúsìn Rẹ̀ ní ìmísí tó fún un.
Les exégèses en arabe:
مَا كَذَبَ ٱلۡفُؤَادُ مَا رَأَىٰٓ
Ọkàn (Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -) kò parọ́ ohun tó rí.
Les exégèses en arabe:
أَفَتُمَٰرُونَهُۥ عَلَىٰ مَا يَرَىٰ
Ṣé ẹ óò jà á níyàn nípa ohun tó rí ni?
Les exégèses en arabe:
وَلَقَدۡ رَءَاهُ نَزۡلَةً أُخۡرَىٰ
Àti pé dájúdájú ó tún rí i nígbà kejì¹
1. Gbólóhùn “rọ’āhu” jẹyọ nínú āyah yìí. Ó tún jẹyọ bẹ́ẹ̀ nínú sūrah at-Takwīr; 81:23. Ìtúmọ̀ rẹ̀ sì ni pé, “Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - rí i.” Ta ni ó rí? Ṣé Allāhu ni tàbí mọlāika Jibrīl? Àní sẹ́, ta ni ọ̀rọ̀ arọ́pò-orúkọ ẹnì kẹta yìí “hu” tó jẹyọ nínú gbólóhùn yìí ń tọ́ka sí? Kí á má gbàgbé pé āyah yẹn ń sọ̀rọ̀ nípa ìrìn-àjò òru àti ìgun sánmọ̀ tí Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ṣe ni.
Èsì: Àwọn igun kan nínú àwọn àáfà sọ pé, mọlāika Jibrīl ni Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - rí. Igun kejì sì sọ pé, Allāhu - tó ga jùlọ - ni ó rí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igun yìí fi kún un pé ọkàn l’ó fi rí Allāhu, kì í ṣe ojú. Ṣebí bí ẹ̀dá ṣe ní ojú ìta, ni ó ní ojú inú. Àmọ́ èyí tí ó gbéwọ̀n jùlọ lọ́dọ̀ ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ àwọn onímọ̀ ẹ̀sìn ’Islām ni pé, orúkọ mọlāika Jibrīl - kí ọlà Allāhu máa bá a - ni “hu” yẹn ń rọ́pò.
Ìdí tí èyí fi rí bẹ́ẹ̀ ni hadīth tí ìyá wa ‘Ā’iṣah - kí Allāhu yọ́nú sí i - gbàwá lórí ọ̀rọ̀ náà pé, “Èmi ni àkọ́kọ́ nínú ìjọ yìí tí ó béèrè nípa ìyẹn lọ́dọ̀ Òjíṣẹ́ Allāhu - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -. Ó sì sọ pé. “Jibrīl ni mo rí.” (Muslim).
Bákan náà, nínú ẹ̀gbàwá Abū Tharr - kí Allāhu yọ́nú sí i -, ó sọ pé, mo bi Òjíṣẹ́ Allāhu ní ìbéèrè pé, “Ṣé o fojú rí Olúwa rẹ bí?” Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - sì sọ pé: “Ìmọ́lẹ̀ kan (dí mi lọ́wọ́), báwo ni mo ṣe máa rí I nígbà náà!” (Muslim)
Irú èyí náà l’ó ṣẹlẹ̀ sí Ànábì Mūsā - kí ọlà Allāhu máa bá a - gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà nínú sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:143.
Tọ́ọ̀, ó ṣeé ṣe kí á rí ọ̀rọ̀ mìíràn kan láti ọ̀dọ̀ àwọn Sọhābah - kí Allāhu yọ́nú sí wọn -, bíi ọ̀rọ̀ tí ó tọ̀dọ̀ Ọmọ ‘Abbās - kí Allāhu yọ́nú sí i - wá pé, “Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - fi ọkàn rẹ̀ rí Allāhu ni.” Ìyẹn ni pé, ó fojú inú rí I, kì í ṣe ojú ìta.
Kíyè sí i, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí ó lágbára tó èyí tí ó tọ̀dọ̀ Ànábì fúnra rẹ̀ wá tààrà lórí ọ̀rọ̀ náà. Ẹ̀gbàwá ‘Ā’iṣah àti ẹ̀gbàwá Abū Tharr sì ni ẹ̀gbàwá tó ti ọ̀dọ̀ Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - wá lórí ọ̀rọ̀ náà. Má ṣe fọkàn sí ibò míìràn. Àti pé, sūrah al-’Ani‘ām; 6:103 àti sūrah aṣ-Ṣūrā; 42:51 ti fi rinlẹ̀ pé, ojú kan kò lè fojú rinjú pẹ̀lú Allāhu, yálà fún gbígba iṣẹ́ òjíṣẹ́ láti ọ̀dọ̀ Allāhu tàbí fún n̄ǹkan mìíràn.
Àmọ́ sá, rírí Allāhu sójú máa wáyé fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo nìkan lọ́jọ́ Àjíǹde. Èyí sì wà ní ìbámu sí sūrah al-Ƙiyāmọh; 75:22 - 23.
Les exégèses en arabe:
عِندَ سِدۡرَةِ ٱلۡمُنتَهَىٰ
níbi igi sidirah al-Muntahā,
Les exégèses en arabe:
عِندَهَا جَنَّةُ ٱلۡمَأۡوَىٰٓ
nítòsí rẹ̀ ni Ọgbà Ibùgbé (gbére) wà.
Les exégèses en arabe:
إِذۡ يَغۡشَى ٱلسِّدۡرَةَ مَا يَغۡشَىٰ
(Rántí) nígbà tí ohun tó bo igi Sidirah bò ó mọ́lẹ̀.
Les exégèses en arabe:
مَا زَاغَ ٱلۡبَصَرُ وَمَا طَغَىٰ
Ojú (Ànábì) kò yẹ̀, kò sì tayọ ẹnu-ààlà.
Les exégèses en arabe:
لَقَدۡ رَأَىٰ مِنۡ ءَايَٰتِ رَبِّهِ ٱلۡكُبۡرَىٰٓ
Dájúdájú ó rí nínú àwọn àmì Olúwa rẹ̀, tó tóbi.
Les exégèses en arabe:
أَفَرَءَيۡتُمُ ٱللَّٰتَ وَٱلۡعُزَّىٰ
Ẹ sọ fún mi nípa òrìṣà Lāt àti òrìṣà ‘Uzzā,
Les exégèses en arabe:
وَمَنَوٰةَ ٱلثَّالِثَةَ ٱلۡأُخۡرَىٰٓ
àti Mọnāh, òrìṣà kẹta mìíràn.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Hajj; 22:52.
Les exégèses en arabe:
أَلَكُمُ ٱلذَّكَرُ وَلَهُ ٱلۡأُنثَىٰ
Ṣé ọmọkùnrin ni tiyín, ọmọbìnrin sì ni tiRẹ̀?
Les exégèses en arabe:
تِلۡكَ إِذٗا قِسۡمَةٞ ضِيزَىٰٓ
Ìpín àbòsí nìyẹn nígbà náà.
Les exégèses en arabe:
إِنۡ هِيَ إِلَّآ أَسۡمَآءٞ سَمَّيۡتُمُوهَآ أَنتُمۡ وَءَابَآؤُكُم مَّآ أَنزَلَ ٱللَّهُ بِهَا مِن سُلۡطَٰنٍۚ إِن يَتَّبِعُونَ إِلَّا ٱلظَّنَّ وَمَا تَهۡوَى ٱلۡأَنفُسُۖ وَلَقَدۡ جَآءَهُم مِّن رَّبِّهِمُ ٱلۡهُدَىٰٓ
(Àwọn orúkọ òrìṣà wọ̀nyẹn) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe àwọn orúkọ kan tí ẹ̀yin àti àwọn bàbá yín sọ (àwọn òrìṣà yín fúnra yín). Allāhu kò sọ ẹ̀rí ọ̀rọ̀ kan kalẹ̀ nípa rẹ̀. Wọn kò sì tẹ̀lé kiní kan bí kò ṣe àbá dídá àti ohun tí ẹ̀mí (wọn) ń fẹ́ (ìfẹ́-inú). Ìmọ̀nà kúkú ti dé bá wọn láti ọ̀dọ̀ Olúwa wọn.
Les exégèses en arabe:
أَمۡ لِلۡإِنسَٰنِ مَا تَمَنَّىٰ
Tàbí ti ènìyàn ni n̄ǹkan tó bá ń fẹ́!
Les exégèses en arabe:
فَلِلَّهِ ٱلۡأٓخِرَةُ وَٱلۡأُولَىٰ
Ti Allāhu sì ni ọ̀run àti ayé.
Les exégèses en arabe:
۞ وَكَم مِّن مَّلَكٖ فِي ٱلسَّمَٰوَٰتِ لَا تُغۡنِي شَفَٰعَتُهُمۡ شَيۡـًٔا إِلَّا مِنۢ بَعۡدِ أَن يَأۡذَنَ ٱللَّهُ لِمَن يَشَآءُ وَيَرۡضَىٰٓ
Àti pé mélòó mélòó nínú àwọn mọlāika tó wà nínú àwọn sánmọ̀, tí ìṣìpẹ̀ wọn kò níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ kiní kan àyàfi lẹ́yìn ìgbà tí Allāhu bá yọ̀ǹda fún ẹni tí Ó bá fẹ́, tí Ó sì yọ́nú sí.
Les exégèses en arabe:
إِنَّ ٱلَّذِينَ لَا يُؤۡمِنُونَ بِٱلۡأٓخِرَةِ لَيُسَمُّونَ ٱلۡمَلَٰٓئِكَةَ تَسۡمِيَةَ ٱلۡأُنثَىٰ
Dájúdájú àwọn tí kò ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Ọjọ́ Ìkẹ́yìn, àwọn ni wọ́n ń fún àwọn mọlāika ní orúkọ obìnrin.
Les exégèses en arabe:
وَمَا لَهُم بِهِۦ مِنۡ عِلۡمٍۖ إِن يَتَّبِعُونَ إِلَّا ٱلظَّنَّۖ وَإِنَّ ٱلظَّنَّ لَا يُغۡنِي مِنَ ٱلۡحَقِّ شَيۡـٔٗا
Kò sí ìmọ̀ kan fún wọn nípa rẹ̀. Wọn kò sì tẹ̀lé kiní kan bí kò ṣe àbá dídá. Dájúdájú àbá dídá kò sì níí rọrọ̀ kiní kan lára òdodo.
Les exégèses en arabe:
فَأَعۡرِضۡ عَن مَّن تَوَلَّىٰ عَن ذِكۡرِنَا وَلَمۡ يُرِدۡ إِلَّا ٱلۡحَيَوٰةَ ٱلدُّنۡيَا
Nítorí náà, ṣẹ́rí kúrò ní ọ̀dọ̀ ẹni tó kẹ̀yìn sí ìrántí Wa, tí kò sì gbèrò kiní kan àfi ìṣẹ̀mí ayé.
Les exégèses en arabe:
ذَٰلِكَ مَبۡلَغُهُم مِّنَ ٱلۡعِلۡمِۚ إِنَّ رَبَّكَ هُوَ أَعۡلَمُ بِمَن ضَلَّ عَن سَبِيلِهِۦ وَهُوَ أَعۡلَمُ بِمَنِ ٱهۡتَدَىٰ
Ìyẹn ni ohun tí wọ́n wọ̀n nínú ìmọ̀. Dájúdájú Olúwa rẹ lÓ nímọ̀ jùlọ nípa ẹni tó ṣìnà kúrò lójú ọ̀nà Rẹ̀. Ó sì nímọ̀ jùlọ nípa ẹni tó mọ̀nà.
Les exégèses en arabe:
وَلِلَّهِ مَا فِي ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَمَا فِي ٱلۡأَرۡضِ لِيَجۡزِيَ ٱلَّذِينَ أَسَٰٓـُٔواْ بِمَا عَمِلُواْ وَيَجۡزِيَ ٱلَّذِينَ أَحۡسَنُواْ بِٱلۡحُسۡنَى
Ti Allāhu ni ohunkóhun tó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ohunkóhun tó wà nínú ilẹ̀ nítorí kí Ó lè san àwọn tó ṣe iṣẹ́ aburú ní ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe níṣẹ́ àti nítorí kí Ó lè san àwọn tó ṣe iṣẹ́ rere ni ẹ̀san rere.
Les exégèses en arabe:
ٱلَّذِينَ يَجۡتَنِبُونَ كَبَٰٓئِرَ ٱلۡإِثۡمِ وَٱلۡفَوَٰحِشَ إِلَّا ٱللَّمَمَۚ إِنَّ رَبَّكَ وَٰسِعُ ٱلۡمَغۡفِرَةِۚ هُوَ أَعۡلَمُ بِكُمۡ إِذۡ أَنشَأَكُم مِّنَ ٱلۡأَرۡضِ وَإِذۡ أَنتُمۡ أَجِنَّةٞ فِي بُطُونِ أُمَّهَٰتِكُمۡۖ فَلَا تُزَكُّوٓاْ أَنفُسَكُمۡۖ هُوَ أَعۡلَمُ بِمَنِ ٱتَّقَىٰٓ
Àwọn tó ń jìnnà sí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá ńlá àti ìwà ìbàjẹ́ àyàfi àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wẹẹrẹ, dájúdájú Olúwa rẹ gbòòrò ní àforíjìn. Ó nímọ̀ jùlọ nípa yín nígbà tí Ó ṣẹ̀dá yín láti inú ilẹ̀ àti nígbà tí ẹ wà ní ọlẹ̀ nínú àwọn ikùn ìyá yín. Nítorí náà, ẹ má ṣe fọra yín mọ́.¹ Òun l’Ó nímọ̀ jùlọ nípa ẹni tó bẹ̀rù (Rẹ̀).
1. Ìyẹn ni pé, ẹ má ṣe yin ara yín.
Les exégèses en arabe:
أَفَرَءَيۡتَ ٱلَّذِي تَوَلَّىٰ
Sọ fún mi nípa ẹni tó gbúnrí (kúrò níbi òdodo),
Les exégèses en arabe:
وَأَعۡطَىٰ قَلِيلٗا وَأَكۡدَىٰٓ
tí ó fi díẹ̀ tọrẹ, tí ó sì di ìyókù mọ́wọ́!
Les exégèses en arabe:
أَعِندَهُۥ عِلۡمُ ٱلۡغَيۡبِ فَهُوَ يَرَىٰٓ
Ṣé ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ wà ní ọ̀dọ̀ rẹ, tí ó sì ń rí i (pé ẹlòmíìràn l’ó ma bá òun jìyà lọ́run)?
Les exégèses en arabe:
أَمۡ لَمۡ يُنَبَّأۡ بِمَا فِي صُحُفِ مُوسَىٰ
Tàbí wọn kò fún un ní ìró ohun tó wà nínú tírà (Ànábì) Mūsā ni,
Les exégèses en arabe:
وَإِبۡرَٰهِيمَ ٱلَّذِي وَفَّىٰٓ
àti (tírà Ànábì) ’Ibrọ̄hīm, ẹni tó mú (òfin Allāhu) ṣẹ,
Les exégèses en arabe:
أَلَّا تَزِرُ وَازِرَةٞ وِزۡرَ أُخۡرَىٰ
pé dájúdájú ẹlẹ́rù-ẹ̀ṣẹ̀ kan kò níí ru ẹrù-ẹ̀ṣẹ̀ ẹlòmíìràn.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah an-Nahl; 16:25.
Les exégèses en arabe:
وَأَن لَّيۡسَ لِلۡإِنسَٰنِ إِلَّا مَا سَعَىٰ
Àti pé kò sí kiní kan fún ènìyàn àfi ohun tó ṣe níṣẹ́.
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّ سَعۡيَهُۥ سَوۡفَ يُرَىٰ
Àti pé dájúdájú iṣẹ́ rẹ̀, láìpẹ́ wọ́n máa fi hàn án.
Les exégèses en arabe:
ثُمَّ يُجۡزَىٰهُ ٱلۡجَزَآءَ ٱلۡأَوۡفَىٰ
Lẹ́yìn náà, wọ́n máa san án ní ẹ̀san rẹ̀, ní ẹ̀san tó kún jùlọ.
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّ إِلَىٰ رَبِّكَ ٱلۡمُنتَهَىٰ
Àti pé dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin (ìrìn-àjò ẹ̀dá).
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّهُۥ هُوَ أَضۡحَكَ وَأَبۡكَىٰ
Dájúdájú Òun l’Ó ń pa (ẹ̀dá) ní ẹ̀rín. Ó sì ń pa (ẹ̀dá) ní ẹkún.
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّهُۥ هُوَ أَمَاتَ وَأَحۡيَا
Dájúdájú Òun l’Ó ń sọ (ẹ̀dá) di òkú. Ó sì ń sọ (ẹ̀dá) di alààyè.
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّهُۥ خَلَقَ ٱلزَّوۡجَيۡنِ ٱلذَّكَرَ وَٱلۡأُنثَىٰ
Dájúdájú Òun l’Ó dá ẹ̀dá ní oríṣi méjì, ọkùnrin àti obìnrin,¹
1. Ẹ̀dá ènìyàn ni èròǹgbà nínú āyah yìí, kì í ṣe ẹ̀dá mìíràn. Āyah 46 l’ó fi èyí rinlẹ̀.
Les exégèses en arabe:
مِن نُّطۡفَةٍ إِذَا تُمۡنَىٰ
láti ara àtọ̀ nígbà tí wọ́n bá dà á sínú àpòlùkẹ́.
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّ عَلَيۡهِ ٱلنَّشۡأَةَ ٱلۡأُخۡرَىٰ
Dájúdájú Òun l’Ó máa ṣe ìṣẹ̀dá ìkẹ́yìn fún àjíǹde,
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّهُۥ هُوَ أَغۡنَىٰ وَأَقۡنَىٰ
Dájúdájú Òun l’Ó ń fún ẹ̀dá ní ọrọ̀ dúkìá, Ó sì ń ta ẹ̀dá ní òṣì.
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّهُۥ هُوَ رَبُّ ٱلشِّعۡرَىٰ
Dájúdájú Òun sì ni Olúwa ìràwọ̀ Ṣi‘rọ̄ (tí wọ́n sọ di òrìṣà).
Les exégèses en arabe:
وَأَنَّهُۥٓ أَهۡلَكَ عَادًا ٱلۡأُولَىٰ
Dájúdájú Òun l’Ó pa ìran ‘Ād rẹ́, àwọn ẹni àkọ́kọ́;
Les exégèses en arabe:
وَثَمُودَاْ فَمَآ أَبۡقَىٰ
àti ìran Thamūd, kò sì ṣẹ́ wọn kù;
Les exégèses en arabe:
وَقَوۡمَ نُوحٖ مِّن قَبۡلُۖ إِنَّهُمۡ كَانُواْ هُمۡ أَظۡلَمَ وَأَطۡغَىٰ
àti ìjọ Nūh tó ṣíwájú (wọn), dájúdájú wọ́n jẹ́ alábòsí jùlọ, wọ́n sì tayọ ẹnu-ààlà jùlọ;
Les exégèses en arabe:
وَٱلۡمُؤۡتَفِكَةَ أَهۡوَىٰ
àti ìlú tó dojú bolẹ̀ (ìlú Ànábì Lūt), Allāhu ló yẹ̀ ẹ́ lulẹ̀ (láti òkè).
Les exégèses en arabe:
فَغَشَّىٰهَا مَا غَشَّىٰ
Ohun tó bò wọ́n mọ́lẹ̀ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Les exégèses en arabe:
فَبِأَيِّ ءَالَآءِ رَبِّكَ تَتَمَارَىٰ
Nítorí náà, èwo nínú ìdẹ̀ra Olúwa rẹ ni ìwọ (ènìyàn) ń jà níyàn?
Les exégèses en arabe:
هَٰذَا نَذِيرٞ مِّنَ ٱلنُّذُرِ ٱلۡأُولَىٰٓ
Èyí ni ìkìlọ̀ kan nínú àwọn ìkìlọ̀ àkọ́kọ́.
Les exégèses en arabe:
أَزِفَتِ ٱلۡأٓزِفَةُ
Ohun tó súnmọ́¹ súnmọ́.
1. “Ohun tó súnmọ́” jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn orúkọ fún Ọjọ́ àjíǹde.
Les exégèses en arabe:
لَيۡسَ لَهَا مِن دُونِ ٱللَّهِ كَاشِفَةٌ
Lẹ́yìn Allāhu, kò sí ẹni tó lè tú gbèdéke Àkókò náà jáde.¹
1. Ó tún túmọ̀ sí pé, “Lẹ́yìn Allāhu, kò sí ẹni tó lè gbé ìdààmú ọjọ́ Àkókò náà kúrò fún ẹ̀dá.”
Les exégèses en arabe:
أَفَمِنۡ هَٰذَا ٱلۡحَدِيثِ تَعۡجَبُونَ
Ṣé ọ̀rọ̀ yìí l’ó ń ṣe yín ní kàyéfì?
Les exégèses en arabe:
وَتَضۡحَكُونَ وَلَا تَبۡكُونَ
Ẹ̀ ń rẹ́rìn-ín, ẹ kò sì sunkún!
Les exégèses en arabe:
وَأَنتُمۡ سَٰمِدُونَ
Afọ́nú-fọ́ra ni yín.
Les exégèses en arabe:
فَٱسۡجُدُواْۤ لِلَّهِۤ وَٱعۡبُدُواْ۩
Nítorí náà, ẹ forí kanlẹ̀ fún Allāhu, kí ẹ jọ́sìn (fún Un).
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Sourate: AN-NAJM
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture