Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Sourate: AN-NÂZI’ÂT   Verset:

Suuratun-Naazihaat

وَٱلنَّٰزِعَٰتِ غَرۡقٗا
Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.
Les exégèses en arabe:
وَٱلنَّٰشِطَٰتِ نَشۡطٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.
Les exégèses en arabe:
وَٱلسَّٰبِحَٰتِ سَبۡحٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.
Les exégèses en arabe:
فَٱلسَّٰبِقَٰتِ سَبۡقٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.
Les exégèses en arabe:
فَٱلۡمُدَبِّرَٰتِ أَمۡرٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.
Les exégèses en arabe:
يَوۡمَ تَرۡجُفُ ٱلرَّاجِفَةُ
Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
Les exégèses en arabe:
تَتۡبَعُهَا ٱلرَّادِفَةُ
Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn ìkejì fún àjíǹde máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
Les exégèses en arabe:
قُلُوبٞ يَوۡمَئِذٖ وَاجِفَةٌ
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
Les exégèses en arabe:
أَبۡصَٰرُهَا خَٰشِعَةٞ
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
Les exégèses en arabe:
يَقُولُونَ أَءِنَّا لَمَرۡدُودُونَ فِي ٱلۡحَافِرَةِ
Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
Les exégèses en arabe:
أَءِذَا كُنَّا عِظَٰمٗا نَّخِرَةٗ
Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”
Les exégèses en arabe:
قَالُواْ تِلۡكَ إِذٗا كَرَّةٌ خَاسِرَةٞ
Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”
Les exégèses en arabe:
فَإِنَّمَا هِيَ زَجۡرَةٞ وَٰحِدَةٞ
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
Les exégèses en arabe:
فَإِذَا هُم بِٱلسَّاهِرَةِ
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
Les exégèses en arabe:
هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ مُوسَىٰٓ
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
Les exégèses en arabe:
إِذۡ نَادَىٰهُ رَبُّهُۥ بِٱلۡوَادِ ٱلۡمُقَدَّسِ طُوًى
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.
Les exégèses en arabe:
ٱذۡهَبۡ إِلَىٰ فِرۡعَوۡنَ إِنَّهُۥ طَغَىٰ
Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.
Les exégèses en arabe:
فَقُلۡ هَل لَّكَ إِلَىٰٓ أَن تَزَكَّىٰ
Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
Les exégèses en arabe:
وَأَهۡدِيَكَ إِلَىٰ رَبِّكَ فَتَخۡشَىٰ
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”
Les exégèses en arabe:
فَأَرَىٰهُ ٱلۡأٓيَةَ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.
Les exégèses en arabe:
فَكَذَّبَ وَعَصَىٰ
(Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).
Les exégèses en arabe:
ثُمَّ أَدۡبَرَ يَسۡعَىٰ
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
Les exégèses en arabe:
فَحَشَرَ فَنَادَىٰ
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
Les exégèses en arabe:
فَقَالَ أَنَا۠ رَبُّكُمُ ٱلۡأَعۡلَىٰ
Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”
Les exégèses en arabe:
فَأَخَذَهُ ٱللَّهُ نَكَالَ ٱلۡأٓخِرَةِ وَٱلۡأُولَىٰٓ
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).¹
1. Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: “Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!” Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
Les exégèses en arabe:
إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَعِبۡرَةٗ لِّمَن يَخۡشَىٰٓ
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).
Les exégèses en arabe:
ءَأَنتُمۡ أَشَدُّ خَلۡقًا أَمِ ٱلسَّمَآءُۚ بَنَىٰهَا
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
Les exégèses en arabe:
رَفَعَ سَمۡكَهَا فَسَوَّىٰهَا
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.
Les exégèses en arabe:
وَأَغۡطَشَ لَيۡلَهَا وَأَخۡرَجَ ضُحَىٰهَا
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
Les exégèses en arabe:
وَٱلۡأَرۡضَ بَعۡدَ ذَٰلِكَ دَحَىٰهَآ
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
Les exégèses en arabe:
أَخۡرَجَ مِنۡهَا مَآءَهَا وَمَرۡعَىٰهَا
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
Les exégèses en arabe:
وَٱلۡجِبَالَ أَرۡسَىٰهَا
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
Les exégèses en arabe:
مَتَٰعٗا لَّكُمۡ وَلِأَنۡعَٰمِكُمۡ
Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
Les exégèses en arabe:
فَإِذَا جَآءَتِ ٱلطَّآمَّةُ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
Les exégèses en arabe:
يَوۡمَ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ مَا سَعَىٰ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.
Les exégèses en arabe:
وَبُرِّزَتِ ٱلۡجَحِيمُ لِمَن يَرَىٰ
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.
Les exégèses en arabe:
فَأَمَّا مَن طَغَىٰ
Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,
Les exégèses en arabe:
وَءَاثَرَ ٱلۡحَيَوٰةَ ٱلدُّنۡيَا
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
Les exégèses en arabe:
فَإِنَّ ٱلۡجَحِيمَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Les exégèses en arabe:
وَأَمَّا مَنۡ خَافَ مَقَامَ رَبِّهِۦ وَنَهَى ٱلنَّفۡسَ عَنِ ٱلۡهَوَىٰ
Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
Les exégèses en arabe:
فَإِنَّ ٱلۡجَنَّةَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Les exégèses en arabe:
يَسۡـَٔلُونَكَ عَنِ ٱلسَّاعَةِ أَيَّانَ مُرۡسَىٰهَا
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”
Les exégèses en arabe:
فِيمَ أَنتَ مِن ذِكۡرَىٰهَآ
Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?¹
1. Ìyẹn ni pé, ìwọ kò lè ní ìmọ̀ ọjọ́ rẹ̀. Ìmọ̀ nípa ọjọ́ wo gan-an ni òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ ni kò sí ìmọ̀ rẹ̀ ní ọ̀dọ̀ Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - àti gbogbo ẹ̀dá pátápátá. Ọ̀dọ̀ Allāhu nìkan ṣoṣo ni ìmọ̀ rẹ̀ wà. Àmọ́ Allāhu fi àwọn àmì ìṣáájú ọjọ́ náà mọ Ànábì Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, ìyẹn ni àwọn àmì òpin ayé.
Les exégèses en arabe:
إِلَىٰ رَبِّكَ مُنتَهَىٰهَآ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
Les exégèses en arabe:
إِنَّمَآ أَنتَ مُنذِرُ مَن يَخۡشَىٰهَا
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.
Les exégèses en arabe:
كَأَنَّهُمۡ يَوۡمَ يَرَوۡنَهَا لَمۡ يَلۡبَثُوٓاْ إِلَّا عَشِيَّةً أَوۡ ضُحَىٰهَا
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Sourate: AN-NÂZI’ÂT
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture