Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Vers: (4) Surah / Kapitel: Al-Mu’minûn
وَٱلَّذِينَ هُمۡ لِلزَّكَوٰةِ فَٰعِلُونَ
àti àwọn tó ń ṣe àfọ̀mọ́ (ẹ̀mí àti ara) wọn.¹
1. Ìtúmọ̀ mìíràn fún āyah yìí nìyí: “àti àwọn tó ń yọ zakāh”. Àmọ́ ìtúmọ̀ òkè yẹn ló bá a mu jùlọ nítorí àwọn ìwòye mẹ́ta kan.
Ìkíní: Sūrah Mọkkah àti āyah Mọkkah ni āyah yìí. Zakāh yíyọ kò sì bẹ̀rẹ̀ ní Mọkkah Alápọ̀n-ọ́nlé, bí kò ṣe ní Mọdīnah Onímọ̀ọ́lẹ̀. Ìkejì: Nínú al-Ƙur’ān Alápọ̀n-ọ́nlé, gbogbo āyah tó ń sọ̀rọ̀ nípa zakāh yíyọ nínú dúkìá máa ń sopọ̀ mọ́ ìrun kíkí “ẹ kí ìrun, ẹ yọ zakāh”.
Ìkẹta: “Ītā’u zakāh” yíyọ zakāh ní èdè al-Ƙur’ān Alápọ̀n-ọ́nlé tí ó bá ń sọ̀rọ̀ nípa zakāh dúkìá, kì í lo “fi‘lu-zakāh” ṣíṣe zakāh.
Nípa ìwọ̀nyẹn, zakāh tẹ̀mí àti tara ni èròǹgbà Allāhu nínú āyah yìí, kì í ṣe zakāh ti dúkìá.
Zakāh tẹ̀mí: òhun ni fífi “taohīdullāh” mímú Allāhu ní ọ̀kan ṣoṣo tí a gbọ́dọ̀ jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo àti “al-’iklās” ọkàn tó mọ́ kúrò níbi “riyā’” ṣekárími jọ́sìn fún Allāhu - Ọba mímọ́, kí á fi àwọn n̄ǹkan méjèèjì yẹn ṣe àfọ̀mọ́ ọkàn wa kúrò níbi “ṣirk” ẹbọ, “kufr” àìgbàgbọ́, “nifāƙ” ìṣojú-méjì àti “’amrọ̄dul-ƙulūb” àwọn àìsàn-ọkàn bíi “kibr” motómotó, “hasad” kèéta àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ní ti zakāh tara, òhun ni fífi ìtẹ̀lé àṣẹ Allāhu àti àṣẹ Òjíṣẹ́ Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà máa bá a - yapa sí àṣẹ Èṣù. Ìyẹn ni pé, ṣíṣe ohun tí ẹ̀sìn pa wá ní àṣẹ rẹ̀ àti jíjìnnà sí ohun tí ẹ̀sìn kọ̀ fún wa. Wallāhu ’a‘lam.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Vers: (4) Surah / Kapitel: Al-Mu’minûn
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen