Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Vers: (71) Surah / Kapitel: An-Nisâ’
يَٰٓأَيُّهَا ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ خُذُواْ حِذۡرَكُمۡ فَٱنفِرُواْ ثُبَاتٍ أَوِ ٱنفِرُواْ جَمِيعٗا
Ẹ̀yin tí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo, ẹ mú ohun ìṣọ́ra yín lọ́wọ́, kí ẹ sì tú jáde s’ójú ogun ẹ̀sìn níkọ̀níkọ̀ tàbí kí ẹ tú jáde ní àpapọ̀.¹
1. Àkànlò èdè ni mímú ìṣọ́ra lọ́wọ́. N̄ǹkan ìjagun bí ọfà àti idà ló ṣe é mú lọ́wọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àtẹ ìgbọfà wà nínú ìṣọ́ra tí ó ṣe é mú lọ́wọ́, wíwà tífura-tìfura lójú ogun ẹ̀sìn ní wíwà-ojú-lalákàn-fi-í- ṣọ́rí ni àgbọ́yé āyah náà. Má ṣe gba ìtànjẹ nípa títúmọ̀ ìṣọ́ra sí lílo òògùn bíi àgbéró, òkígbẹ́, ìṣíjú, ayẹta, àfẹ́ẹ̀rí, asákì àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Èèwọ̀ ni gbogbo ìwọ̀nyẹn nítorí pé, wọn kò là níbi idán pípa àti bíbẹ àwọn ẹ̀mí àìrí èṣù àlùjànnú kan níṣẹ́. Nítorí náà, ẹnì kan kò níí fi òògùn abẹnugọ̀ǹgọ̀ ja’gun ẹ̀sìn àfi kí ó jẹ́ ẹlẹ́bọ.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Vers: (71) Surah / Kapitel: An-Nisâ’
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen