Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Vers: (35) Surah / Kapitel: Muhammad
فَلَا تَهِنُواْ وَتَدۡعُوٓاْ إِلَى ٱلسَّلۡمِ وَأَنتُمُ ٱلۡأَعۡلَوۡنَ وَٱللَّهُ مَعَكُمۡ وَلَن يَتِرَكُمۡ أَعۡمَٰلَكُمۡ
Ẹ má ṣe káàárẹ̀, kí ẹ sì má ṣe pèpè fún kòsógunmọ́, nígbà tí ẹ bá ń lékè lọ́wọ́. Allāhu wà pẹ̀lú yín; kò sì níí kó àdínkù bá ẹ̀san àwọn iṣẹ́ yín.¹
1. Lẹ́yìn tí ìtayọ ẹnu-ààlà ti wáyé láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀ṣẹbọ àti àwọn ahlul-kitāb sí àwa mùsùlùmí, tí wọ́n ti fọwọ́ ara wọn fa ogun, tí Allāhu sì ti pa á láṣẹ fún àwa mùsùlùmí láti jàjà gbára fún ẹ̀sìn wa, ẹ̀mí wa àti dúkìá wa, ogun ẹ̀sìn kò níí kásẹ̀ nílẹ̀ mọ́ lórí ilẹ̀ ayé àfi pẹ̀lú ọ̀kan nínú n̄ǹkan méjì; yálà kí àwọn aláìgbàgbọ́ wọ̀nyẹn gba ’Islām nítorí pé, òhun nìkan ni ẹ̀sìn òdodo tàbí kí wọ́n máa san owó ìsákọ́lẹ̀ fún ìjọba ’Islām láì níí fi ẹ̀sìn irọ́ wọn dí àwa mùsùlùmí lọ́wọ́. Èyí ni òfin tí ó máa múlẹ̀ ní èyíkéyìí orílẹ̀-èdè ’Islām. Àmọ́ nígbà tí Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - bá sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ kò níí sí owó ìsákọ́lẹ̀ mọ́ àfi gbígba ’Islām nìkan.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Vers: (35) Surah / Kapitel: Muhammad
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen