Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: Al-Wâqi‘ah   Vers:

Suuratul-Waakiha

إِذَا وَقَعَتِ ٱلۡوَاقِعَةُ
Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَيۡسَ لِوَقۡعَتِهَا كَاذِبَةٌ
- kò sí irọ́ kan nípa ìṣẹ̀lẹ̀ rẹ̀-
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
خَافِضَةٞ رَّافِعَةٌ
ó máa mú (àwọn kan) wálẹ̀ (sínú Iná), ó sì máa gbé (àwọn kan) sókè (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِذَا رُجَّتِ ٱلۡأَرۡضُ رَجّٗا
Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímìtìtì,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَبُسَّتِ ٱلۡجِبَالُ بَسّٗا
àti nígbà tí Wọ́n bá fọ́ àwọn àpáta ní fífọ́ wómúwómú,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَكَانَتۡ هَبَآءٗ مُّنۢبَثّٗا
- wọ́n sì máa di eruku àfẹ́dànù -
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكُنتُمۡ أَزۡوَٰجٗا ثَلَٰثَةٗ
ẹ̀yin sì máa jẹ́ oríṣi mẹ́ta.¹
1. Àwọn nasọ̄rọ̄ lérò pé āyah tó pín ẹ̀dá sí mẹ́ta ní ọjọ́ Àjíǹde tako āyah tó pín wọn sí ìjọ méjì.
Èsì: Kò sí ìtakora láààrin wọn. Nínú sūrah yìí, Allāhu - tó ga jùlọ - sọ pé oríṣi ìjọ mẹ́ta ni àwọn ẹ̀dá máa pín sí ní ọjọ́ Àjíǹde. Ìjọ ọ̀tún, ìjọ òsì àti ìjọ aṣíwájú. Àmọ́ nínú sūrah al-Balad; 90:18 - 19 àti sūrah az-Zalzalah; 99:6 - 8, Allāhu - tó ga jùlọ - pín wọn sí ìjọ méjì. Ìjọ méjì = = kúkú ni gbogbo ẹ̀dá ní ọ̀run, ìjọ ọ̀tún àti ìjọ òsì nítorí pé, Ọgbà Ìdẹ̀ra wà fún ìjọ ọ̀tún, Ọgbà Iná sì wá fún ìjọ òsì. Àmọ́, Allāhu - tó ga jùlọ - ṣe àtúnpín ìjọ ọ̀tún sí ìjọ ọ̀tún àti ìjọ aṣíwájú nítorí pé, ìgbádùn ìkíní kejì yàtọ̀ gan-an síra wọn. Ìdí nìyí tí Allāhu fi sọ nípa ìgbádùn ìjọ aṣíwájú láti āyah 10 sí āyah 26. Ó sọ nípa ìgbádùn ìjọ ọ̀tún láti āyah 27 sí āyah 40. Ó sì sọ nípa oníran-ànran ìyà ìjọ òsì láti āyah 41 sí āyah 56.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَأَصۡحَٰبُ ٱلۡمَيۡمَنَةِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَيۡمَنَةِ
Àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَأَصۡحَٰبُ ٱلۡمَشۡـَٔمَةِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَشۡـَٔمَةِ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلسَّٰبِقُونَ ٱلسَّٰبِقُونَ
Àwọn aṣíwájú sì ni àwọn aṣíwájú.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أُوْلَٰٓئِكَ ٱلۡمُقَرَّبُونَ
Àwọn wọ̀nyẹn ni alásùn-únmọ́ (Allāhu)
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فِي جَنَّٰتِ ٱلنَّعِيمِ
nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُلَّةٞ مِّنَ ٱلۡأَوَّلِينَ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَقَلِيلٞ مِّنَ ٱلۡأٓخِرِينَ
Wọ́n sì kéré nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَلَىٰ سُرُرٖ مَّوۡضُونَةٖ
(Wọn yóò wà) lórí ìtẹ́ tí wọ́n fi góòlù hun.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
مُّتَّكِـِٔينَ عَلَيۡهَا مُتَقَٰبِلِينَ
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí rẹ̀, wọn sì máa dojú kọra wọn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
يَطُوفُ عَلَيۡهِمۡ وِلۡدَٰنٞ مُّخَلَّدُونَ
Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí kò níí darúgbó yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
بِأَكۡوَابٖ وَأَبَارِيقَ وَكَأۡسٖ مِّن مَّعِينٖ
pẹ̀lú àwọn ife omi, ohun ìrọmi fẹ̀ǹfẹ̀ àti ife ọtí aládùn láti inú odò kan tó ń ṣàn (káà kiri ọ̀dọ̀ wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَّا يُصَدَّعُونَ عَنۡهَا وَلَا يُنزِفُونَ
Kò níí fọ́ wọn lórí; kò sì níí mú wọn húnrìrà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَفَٰكِهَةٖ مِّمَّا يَتَخَيَّرُونَ
Èso tí wọn yóò máa ṣẹ̀ṣà nínú rẹ̀ (tún wà fún wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَلَحۡمِ طَيۡرٖ مِّمَّا يَشۡتَهُونَ
Àti ẹran ẹyẹ, èyí tí wọ́n ń fẹ́ (yó wà fún wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَحُورٌ عِينٞ
Àwọn obìnrin ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ (tún wà fún wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَأَمۡثَٰلِ ٱللُّؤۡلُوِٕ ٱلۡمَكۡنُونِ
Wọ́n dà bí àlúùúlù (òkúta olówó-iye-bíye) tí wọ́n fi pamọ́ sínú apó rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
جَزَآءَۢ بِمَا كَانُواْ يَعۡمَلُونَ
(Ìwọ̀nyí ni) ẹ̀san fún ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَا يَسۡمَعُونَ فِيهَا لَغۡوٗا وَلَا تَأۡثِيمًا
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِلَّا قِيلٗا سَلَٰمٗا سَلَٰمٗا
Àyàfi ọ̀rọ̀ àlàáfíà, àlàáfíà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَأَصۡحَٰبُ ٱلۡيَمِينِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلۡيَمِينِ
Àwọn èrò ọwọ́ ọtún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọtún?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فِي سِدۡرٖ مَّخۡضُودٖ
(Wọn yóò wà) ní ìdí igi tí kò ní ẹ̀gún,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَطَلۡحٖ مَّنضُودٖ
àti ọ̀gẹ̀dẹ̀ tó so jìgbìnnì,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَظِلّٖ مَّمۡدُودٖ
àti ibòji tó gbòòrò,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَمَآءٖ مَّسۡكُوبٖ
àti omi tó ń ṣàn láì dáwọ́ dúró,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَفَٰكِهَةٖ كَثِيرَةٖ
àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَّا مَقۡطُوعَةٖ وَلَا مَمۡنُوعَةٖ
tí kò níí já (ní ọ̀dọ̀ wọn), kò sì níí dèèwọ̀ (fún wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَفُرُشٖ مَّرۡفُوعَةٍ
(Wọ́n máa wà lórí) ìtẹ́ tí wọ́n gbé sókè.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّآ أَنشَأۡنَٰهُنَّ إِنشَآءٗ
Dájúdájú Àwa dá (àwọn obìnrin Ọgbà Ìdẹ̀ra) ní ẹ̀dá kan (tó yàtọ̀ sí tayé).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَجَعَلۡنَٰهُنَّ أَبۡكَارًا
A sì ṣe wọ́n ní wúńdíá,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عُرُبًا أَتۡرَابٗا
olólùfẹ́ ọkọ. Wọ́n sì dọ́gba ní ọjọ́ orí.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لِّأَصۡحَٰبِ ٱلۡيَمِينِ
(Wọ́n wà) fún àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُلَّةٞ مِّنَ ٱلۡأَوَّلِينَ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَثُلَّةٞ مِّنَ ٱلۡأٓخِرِينَ
Wọ́n tún pọ̀ nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.¹
1. Àwọn ẹni àkọ́kọ́ dúró fún àwọn ènìyàn láti àsìkò Ànábì Ādam títí di àsìkò Ànábì ‘Īsā - kí ọlà Allāhu máa bá wọn -. Àwọn ẹni Ìkẹ́yìn sì dúró fún ìjọ Ànábì wa nìkan - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَأَصۡحَٰبُ ٱلشِّمَالِ مَآ أَصۡحَٰبُ ٱلشِّمَالِ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فِي سَمُومٖ وَحَمِيمٖ
(Wọn yóò wà) nínú atẹ́gùn gbígbóná (iná) àti omi tó gbóná parí,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَظِلّٖ مِّن يَحۡمُومٖ
àti ní abẹ́ ibòji eléèéfín dúdú,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَّا بَارِدٖ وَلَا كَرِيمٍ
kò tutù, kò sì dára.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّهُمۡ كَانُواْ قَبۡلَ ذَٰلِكَ مُتۡرَفِينَ
Dájúdájú wọ́n ti jẹ́ onígbẹdẹmukẹ ṣíwájú ìyẹn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكَانُواْ يُصِرُّونَ عَلَى ٱلۡحِنثِ ٱلۡعَظِيمِ
Wọ́n sì máa ń ṣoríkunkun lórí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكَانُواْ يَقُولُونَ أَئِذَا مِتۡنَا وَكُنَّا تُرَابٗا وَعِظَٰمًا أَءِنَّا لَمَبۡعُوثُونَ
Wọ́n sì máa ń wí pé: “Ṣé nígbà tí a bá di òkú, tí a sì di erùpẹ̀ àti egungun, ǹjẹ́ Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَوَءَابَآؤُنَا ٱلۡأَوَّلُونَ
Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
قُلۡ إِنَّ ٱلۡأَوَّلِينَ وَٱلۡأٓخِرِينَ
Sọ pé: “Dájúdájú àwọn ẹni àkọ́kọ́ àti àwọn ẹni Ìkẹ́yìn,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَمَجۡمُوعُونَ إِلَىٰ مِيقَٰتِ يَوۡمٖ مَّعۡلُومٖ
dájúdájú A óò kó wọn jọ papọ̀ ní àkókò ọjọ́ kan tí A ti mọ̀.”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُمَّ إِنَّكُمۡ أَيُّهَا ٱلضَّآلُّونَ ٱلۡمُكَذِّبُونَ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ̀yin olùṣìnà, olùpe-òdodo-nírọ́,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَأٓكِلُونَ مِن شَجَرٖ مِّن زَقُّومٖ
dájúdájú ẹ̀yin máa jẹ nínú igi zaƙƙūm (igi iwọ).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَمَالِـُٔونَ مِنۡهَا ٱلۡبُطُونَ
Ikùn yín sì máa kún bámúbámú fún (jíjẹ) igi náà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَشَٰرِبُونَ عَلَيۡهِ مِنَ ٱلۡحَمِيمِ
Ẹ̀yin yó sì máa mu omi tó gbóná parí lé e lórí.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَشَٰرِبُونَ شُرۡبَ ٱلۡهِيمِ
Ẹ̀yin yóò máa mu ún ní ìmumi ràkúnmí tí òǹgbẹ ń gbẹ.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
هَٰذَا نُزُلُهُمۡ يَوۡمَ ٱلدِّينِ
Èyí ni n̄ǹkan àlejò wọn ní Ọjọ́ ẹ̀san.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
نَحۡنُ خَلَقۡنَٰكُمۡ فَلَوۡلَا تُصَدِّقُونَ
Àwa l’A ṣẹ̀dá yín. Kí ni kò jẹ́ kí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo!
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَفَرَءَيۡتُم مَّا تُمۡنُونَ
Ẹ sọ fún Mi nípa àtọ̀ tí ẹ̀ ń dà jáde (sínú àpòlùkẹ́),
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ءَأَنتُمۡ تَخۡلُقُونَهُۥٓ أَمۡ نَحۡنُ ٱلۡخَٰلِقُونَ
ṣé ẹ̀yin lẹ ṣẹ̀dá rẹ̀ ni tàbí Àwa l’A ṣẹ̀dá rẹ̀?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
نَحۡنُ قَدَّرۡنَا بَيۡنَكُمُ ٱلۡمَوۡتَ وَمَا نَحۡنُ بِمَسۡبُوقِينَ
Àwa l’A yan kádàrá (ọjọ́) ikú fún gbogbo yín. Kò sì sí ẹni tó lè dá Wa lágara
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَلَىٰٓ أَن نُّبَدِّلَ أَمۡثَٰلَكُمۡ وَنُنشِئَكُمۡ فِي مَا لَا تَعۡلَمُونَ
láti yí irú yín padà (láti inú erùpẹ̀ sí alààyè), kí á sì ṣẹ̀dá yín (ní ọ̀tun) sínú ohun tí ẹ kò mọ̀ (nínú àwọn ìrísí).
1. Ẹ tún wo sūrah al-Mọ̄‘rij; 70:40-41 àti sūrah al-Ƙiyāmọh; 75:3-4.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَلَقَدۡ عَلِمۡتُمُ ٱلنَّشۡأَةَ ٱلۡأُولَىٰ فَلَوۡلَا تَذَكَّرُونَ
Ẹ kúkú mọ ìṣẹ̀dá àkọ́kọ́ (pé láti ibi àìsí ni ẹ ti di alààyè), ẹ kò ṣe lo ìrántí?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَفَرَءَيۡتُم مَّا تَحۡرُثُونَ
Ẹ sọ fún Mi nípa n̄ǹkan tí ẹ̀ ń gbìn sínú ilẹ̀,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ءَأَنتُمۡ تَزۡرَعُونَهُۥٓ أَمۡ نَحۡنُ ٱلزَّٰرِعُونَ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń jẹ́ kí ó hù jáde tàbí Àwa l’À ń jẹ́ kí ó hù jáde?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَوۡ نَشَآءُ لَجَعَلۡنَٰهُ حُطَٰمٗا فَظَلۡتُمۡ تَفَكَّهُونَ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá sọ ọ́ di gbígbẹ, ẹ̀yin yó sì máa ṣèèmọ̀ (tí ẹ óò máa ká àbámọ̀).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّا لَمُغۡرَمُونَ
(Ẹ̀yin yó sì wí pé:) “Dájúdájú àwa ti di onígbèsè.”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
بَلۡ نَحۡنُ مَحۡرُومُونَ
(Àwọn mìíràn yó sì wí pé:) “Rárá o! Wọ́n ṣe ìkórè oko ní èèwọ̀ fún wa ni.”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَفَرَءَيۡتُمُ ٱلۡمَآءَ ٱلَّذِي تَشۡرَبُونَ
Ẹ sọ fún mi nípa omi tí ẹ̀ ń mu,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ءَأَنتُمۡ أَنزَلۡتُمُوهُ مِنَ ٱلۡمُزۡنِ أَمۡ نَحۡنُ ٱلۡمُنزِلُونَ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti inú ẹ̀ṣújò ni tàbí Àwa l’À ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَوۡ نَشَآءُ جَعَلۡنَٰهُ أُجَاجٗا فَلَوۡلَا تَشۡكُرُونَ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá ṣe é ní omi tó móró. Ẹ ò ṣe máa dúpẹ́?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَفَرَءَيۡتُمُ ٱلنَّارَ ٱلَّتِي تُورُونَ
Ẹ sọ fún Mi nípa iná tí ẹ̀ ń dá,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ءَأَنتُمۡ أَنشَأۡتُمۡ شَجَرَتَهَآ أَمۡ نَحۡنُ ٱلۡمُنشِـُٔونَ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ ṣẹ̀dá igi rẹ̀ ni tàbí Àwa ni Aṣẹ̀dá?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
نَحۡنُ جَعَلۡنَٰهَا تَذۡكِرَةٗ وَمَتَٰعٗا لِّلۡمُقۡوِينَ
Àwa ṣe iná ayé ní ìrántí (fún Iná ọ̀run) àti n̄ǹkan èlò fún àwọn onírìn-àjò.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَسَبِّحۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلۡعَظِيمِ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
۞ فَلَآ أُقۡسِمُ بِمَوَٰقِعِ ٱلنُّجُومِ
Nítorí náà, Mò ń fi àwọn àyè tí ìkọ̀ọ̀kan gbólóhùn al-Ƙur’ān wà nínú sánmọ̀ búra.¹
1. “Mọwāƙi‘u-nnujūm” tún lè túmọ̀ sí “àwọn ibùsọ̀ ìràwọ̀ nínú sánmọ̀”. Nítorí náà, ìtúmọ̀ mìíràn fún āyah yìí nìyí: “Nítorí náà, Mò ń fi àwọn ibùsọ̀ ìràwọ̀ búra.” Ẹ wo sūrah an-Najm; 53:1 àti ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَإِنَّهُۥ لَقَسَمٞ لَّوۡ تَعۡلَمُونَ عَظِيمٌ
Dájúdájú ìbúra ńlá ni, tí ẹ bá mọ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّهُۥ لَقُرۡءَانٞ كَرِيمٞ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni n̄ǹkan kíké alápọ̀n-ọ́nlé.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فِي كِتَٰبٖ مَّكۡنُونٖ
Ó wà nínú Tírà kan tí wọ́n ń fi ààbò bò (ìyẹn Laohul-Mahfūṭḥ).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَّا يَمَسُّهُۥٓ إِلَّا ٱلۡمُطَهَّرُونَ
Kò sí ẹni tó lè fọwọ́ kàn án (ní ọ̀dọ̀ Allāhu) àfi àwọn ẹni mímọ́ (ìyẹn, àwọn mọlāika).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
تَنزِيلٞ مِّن رَّبِّ ٱلۡعَٰلَمِينَ
Wọ́n sọ al-Ƙur’ān kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَفَبِهَٰذَا ٱلۡحَدِيثِ أَنتُم مُّدۡهِنُونَ
Nítorí náà, ṣé ọ̀rọ̀ (al-Ƙur’ān) yìí l’ẹ̀ ń pè ní irọ́?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَتَجۡعَلُونَ رِزۡقَكُمۡ أَنَّكُمۡ تُكَذِّبُونَ
Ẹ sì ń sọ ìdúpẹ́ arísìkí yín di pé dájúdájú ẹ̀ ń pe òdodo ní irọ́.¹
1. Ìyẹn ni pé, àwọn ọ̀ṣẹbọ ń dúpẹ́ fún ìràwọ̀ nítorí pé, wọ́n gbàgbọ́ pé òhun l’ó ń rọ̀jò lẹ́yìn Allāhu. Irọ́ àti àìgbàgbọ́ nínú Allāhu ni èyí. Allāhu - tó ga jùlọ - ni Ẹni t’Ó ń rọ̀jò fún ẹ̀dá Rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَلَوۡلَآ إِذَا بَلَغَتِ ٱلۡحُلۡقُومَ
Kí ni ó máa ti rí (fún yín) nígbà tí ẹ̀mí (yín) bá dé ọ̀nà ọ̀fun,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَأَنتُمۡ حِينَئِذٖ تَنظُرُونَ
tí ẹ̀yin yó sì máa wò bọ̀ọ̀ nígbà yẹn?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَنَحۡنُ أَقۡرَبُ إِلَيۡهِ مِنكُمۡ وَلَٰكِن لَّا تُبۡصِرُونَ
Àwa sì súnmọ́ ọn ju ẹ̀yin lọ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò ríran.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Mujādilah; 58:7.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَلَوۡلَآ إِن كُنتُمۡ غَيۡرَ مَدِينِينَ
Ẹ̀yin kò ṣe jẹ́ ẹni tí A ò níí gbẹ̀san lára rẹ̀,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
تَرۡجِعُونَهَآ إِن كُنتُمۡ صَٰدِقِينَ
kí ẹ sì dá (ẹ̀mí tí ó fẹ́ bọ́) padà, tí ẹ bá jẹ́ olódodo.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَأَمَّآ إِن كَانَ مِنَ ٱلۡمُقَرَّبِينَ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (Wa),
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَرَوۡحٞ وَرَيۡحَانٞ وَجَنَّتُ نَعِيمٖ
ìsinmi, èsè tó dára àti Ọgbà Ìdẹ̀ra (ni tirẹ̀).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَأَمَّآ إِن كَانَ مِنۡ أَصۡحَٰبِ ٱلۡيَمِينِ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَسَلَٰمٞ لَّكَ مِنۡ أَصۡحَٰبِ ٱلۡيَمِينِ
àlàáfíà ni fún ọ láààrin àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَأَمَّآ إِن كَانَ مِنَ ٱلۡمُكَذِّبِينَ ٱلضَّآلِّينَ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn olùpe-òdodo-nírọ́, àwọn olùṣìnà,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَنُزُلٞ مِّنۡ حَمِيمٖ
n̄ǹkan àlejò (wọn) ni omi tó gbóná parí
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَتَصۡلِيَةُ جَحِيمٍ
àti wíwọ inú iná Jẹhīm.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّ هَٰذَا لَهُوَ حَقُّ ٱلۡيَقِينِ
Dájúdájú èyí, òhun ni òdodo tó dájú.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَسَبِّحۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلۡعَظِيمِ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: Al-Wâqi‘ah
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen