قۇرئان كەرىم مەنىلىرىنىڭ تەرجىمىسى - يورۇباچە تەرجىمىسى * - تەرجىمىلەر مۇندەرىجىسى

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

مەنالار تەرجىمىسى ئايەت: (159) سۈرە: سۈرە نىسا
وَإِن مِّنۡ أَهۡلِ ٱلۡكِتَٰبِ إِلَّا لَيُؤۡمِنَنَّ بِهِۦ قَبۡلَ مَوۡتِهِۦۖ وَيَوۡمَ ٱلۡقِيَٰمَةِ يَكُونُ عَلَيۡهِمۡ شَهِيدٗا
Kò sì níí sí ẹnì kan nínú àwọn onítírà (láyé nígbà tí ‘Īsā ọmọ Mọryam bá sọ̀kalẹ̀ padà láti ojú sánmọ̀) àfi kí ó gbà á gbọ́ ní òdodo ṣíwájú ikú rẹ̀.¹Ní Ọjọ́ Àjíǹde, ó sì máa jẹ́ ẹlẹ́rìí lórí wọn.
1. Àgbọ́yé méjì ni àwọn tafsīr mú wá lórí arọ́pò ọ̀rọ̀-orúkọ tó jẹyọ nínú àpólà ọ̀rọ̀-orúkọ yìí “قَبْلَ مَوْتِهِۦۖ”.
Àgbọ́yé kìíní ni pé, arọ́pò ọ̀rọ̀-orúkọ náà dúró fún ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a -. Nípa bẹ́ẹ̀ ìtúmọ̀ āyah náà máa lọ báyìí pé: “Kò sì níí sí ẹnì kan nínú àwọn onítírà (láyé nígbà tí ‘Īsā bá sọ̀kalẹ̀ padà láti ojú sánmọ̀) àfi kí ó gba ‘Īsā ọmọ Mọryam gbọ́ ní òdodo ṣíwájú ikú ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a -.” Èyí sì máa jẹ́ oore ìronúpìwàdà àti ìpadà sínú ẹ̀sìn ’Islām fún ọ̀wọ́ àwọn tí ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - bá padà bá láyé nínú àwọn tó ti sọ ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - di olúwa àti olùgbàlà wọn.
Àgbọ́yé kejì ni pé, arọ́pò ọ̀rọ̀-orúkọ náà dúró fún ikú àwọn onítírà tó ń pọ́kàkà ikú. Nípa bẹ́ẹ̀ ìtúmọ̀ āyah náà máa lọ báyìí pé: “Kò sì níí sí ẹnì kan nínú àwọn onítírà àfi kí ó gba ‘Īsā ọmọ Mọryam gbọ́ ní òdodo ṣíwájú ikú àwọn onítírà náà lásìkò ìpọ́kàkà ikú.”
Àlàyé tí àwọn onímọ̀ Tafsīr mú wá fún àgbọ́yé kejì yìí ni pé, àwọn mọlāika máa fi àwòrán ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - han ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ kú láti fojú rí àṣìṣe rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a -. Ó máa ronú pìwàdà lásìkò náà, àmọ́ kò sí ìronúpìwàdà àti ìgbàgbọ́ òdodo tó wúlò lásìkò ìpọ́kàkà ikú.
Àgbọ́yé méjèèjì wọ̀nyí kúkú dára, àmọ́ nígbà tí pọ́n-na (ṣubhah) bá jẹyọ nínú āyah al-Ƙur’ān, ọ̀nà kan pàtàkì nínú ìyọnípọ́n-na ni lílo hadīth Ànábì. Àmọ́, ṣíwájú kí á tó lè lo hadīth kan kan fún ìyọnípọ́n-na, al-Ƙur’ān fúnra rẹ̀ ni ohun àkọ́kọ́ tí a máa lò. Èyí máa ṣẹlẹ̀ nípasẹ̀ wíwo sàkánì tí ọ̀rọ̀ onípọ́n-na náa ti jẹyọ. A máa wòye sí ọ̀rọ̀ tí ń bá á bọ̀ níwájú (tàbí) àti ọ̀rọ̀ tí ó tún mú wá lẹ́yìn rẹ̀ (bí ó bá wà). Kódà ìwòye yìí lè ṣẹlẹ̀ nígbà mìíràn nínú āyah kan náà. Nítorí náà, lórí āyah yìí, àgbọ́yé tó gbéwọ̀n jùlọ ni àgbọ́yé kìíní. Èyí tí ó ń fi rinlẹ̀ pé ikú ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - lópin ayé ni arọ́pò ọ̀rọ̀-orúkọ náà dúró fún. Èyí rí bẹ́ẹ̀ nítorí pé, ọ̀rọ̀ tó jẹyọ nínú āyah 157 ń sọ nípa pé àwọn kan ń sọ pé àwọn pa ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a -, àwọn kàn án mọ́ igi àgbélébùú. Ó sì ti kú. Allāhu - subhānahu wa ta'ālā - sì sọ pé ọ̀rọ̀ náà kò rí bẹ́ẹ̀ rárá bí kò ṣe pé Òun gbé ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - wá sókè lọ́dọ̀ Òun ni. Òkodoro ọ̀rọ̀ náà sì máa hàn sí gbogbo ayé ní àsìkò ìpadà-sọ̀kalẹ̀ rẹ̀ láti ojú sánmọ̀. Ìyẹn sì ni àlàyé tó jẹyọ nínú àwọn āyah 158 àti 159.
Síwájú sí i, kalmọh “رفع” (rọfa‘a) lè túmọ̀ sí àgbéga tẹ̀mí (ìyẹn, àgbéga ipò gẹ́gẹ́ bí èyí tó jẹyọ nínú sūrah Al-’a‘rọ̄f; 7:176 àti sūrah Mọryam; 19:57) tàbí kí ó túmọ̀ sí àgbéga tara (ìyẹn gbígbé ara kúrò láti àyè ìsàlẹ̀ sí àyè òkè gẹ́gẹ́ bí èyí tó jẹyọ nínú sūrah Fātir; 35:10). Àmọ́ kò ní tàbí-ṣùgbọ́n nínú mọ́ pé, ìgbàkígbà tí harafi “إلى” bá ti tẹ̀lé “رفع”, àgbéga tara l’ó máa jẹ́ ìtúmọ̀ rẹ̀. Wàyí, níwọ̀n ìgbà tí ó sì ti jẹ́ pé òkè sánmọ̀ ni pàápàá bíbẹ Allāhu - subhānahu wa ta'ālā - wà, ìdí nìyí tí “بَل رَّفَعَهُ ٱللَّهُ إِلَيْهِۚ” fi túmọ̀ sí “kò rí bẹ́ẹ̀, Allāhu gbé ‘Īsā ọmọ Mọryam wá sókè sínú sánmọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀ ni.”
Bí ẹnì kan bá wá ń retí kalmọh “السماء” (sánmọ̀) nínú āyah náà ṣíwájú kí ó tó lè gbàgbọ́ pé nínú sánmọ̀ ni Allāhu gbé ‘Īsā ọmọ Mọryam wá ní ẹ̀mí àti ara, bóyá ni onítọ̀ún gbàgbọ́ pé sánmọ̀ ni pàápàá bíbẹ Allāhu gan-an wà. Lórí èyí, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-’Ani‘ām; 6:18.
Nítorí náà, gbogbo Mùsùlùmí onisunnah l’ó mọ̀ ní àmọ̀dájú pé, òkè sánmọ̀ keje ni Allahu wà nítorí pé, sánmọ̀ yìí náà ni Ànábì wa Muhammad - kí ọlà Allāhu máa bá a - gùn lọ láti lọ gba ìrun wákàtí márààrùn wá lọ́dọ̀ Allāhu - subhānahu wa ta'ālā - lásìkò ìrìn òru àti ìgun-sánmọ̀ gẹ́gẹ́ bí Allāhu ṣe fi rinlẹ̀ ní ìbẹ̀rẹ̀ sūrah al-’Isrọ̄’.
Kíyè sí i! Tòhun ti bí àìgbàgbọ́ Fir‘aon ṣe gbópọn tó, ó kúkú gbà pé sánmọ̀ ni Allāhu wà. Ó sì bẹ Hāmọ̄n ní ilé gíga fíofío kọ́. Ó fẹ́ yọjú wo Allāhu! (sūrah al-Ƙọsọs; 28:38). Nítorí náà, inú sánmọ̀ ni Allāhu gbé ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - wá. Ó sì wà níbẹ̀, kì í ṣe ní ti ìgbésí ayé ti ayé, àmọ́ ní ti ìgbésí ayé tó bá inú sánmọ̀ mu, ìyẹn irú ìgbésí ayé tàwọn mọlāika, tí wọn kì í jẹun, tí wọn kì í mu, tí wọn kì í ṣẹ̀gbin, tí wọn kì í dàgbà sí i, tí wọn kì í gbó lára àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Àti pé nípasẹ̀ àwọn iṣẹ́ tí ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - máa ṣe nígbà tí ó bá padà dé láti ojú sánmọ̀ níbi rírún àgbélébùú, pípa ẹlẹ́dẹ̀, kíkọ gbogbo ẹ̀sìn àfi ẹ̀sìn ’Islām nìkan ṣoṣo, pípa Mọsīh Dajjāl àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ l’ó máa mú kí àwọn onítírà àsìkò náà ronú pìwàdà sínú ẹ̀sìn ’Islām.
Kíyè sí i, ìpadàbọ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - lópin ayé kì í ṣe ní àwòrán ipò Ànábì, bí kò ṣe ní àwòrán ọmọlẹ́yìn Ànábì wa Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - àti adájọ́ onídéédé nítorí pé, kò níí sí Ànábì titun kan kan mọ́ lẹ́yìn Ànábì wa Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -. Àti pé, ìjọ Ànábì wa - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - nìkan l’ó wà láyé báyìí, nítorí náà Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - ẹni tí kádàrá rẹ̀ jẹmọ́ ìpadàbọ̀ sáyé kò níí wà nípò Ànábì lásìkò náà bí kò ṣe pé, ó máa wà nípò ọ̀kan nínú àwọn ọmọlẹ́yìn Ànábì àsìkò yìí. Ìdí sì nìyí tí kò fi níí fi tírà kan dájọ́ lẹ́yìn al-Ƙur’ān. Pẹ̀lú àlàyé yìí, àgbọ́yé kejì kò lè rọ́nà lọ.
Àmọ́ sá, tí ẹnì kan bá bá àgbọ́yé kejì yìí lọ, kò la àtakò lọ níwọ̀n ìgbà tí onítọ̀ún kò bá ti tako ìsọ̀kalẹ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - láti ojú sánmọ̀ l’ópin ayé nítorí pé, níwọ̀n ìgbà tí hadīth tó fẹsẹ̀ rinlẹ̀ ti fi rinlẹ̀, aláìgbàgbọ́ tí ó máa jẹ̀bi ikú lábẹ́ òfin ’Islām ni ẹnikẹ́ni nínú àwọn mùsùlùmí tó bá tako ìsọ̀kalẹ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - láti ojú sánmọ̀ l’ópin ayé. Wòóore! Gbogbo òǹkà arọ́pò ọ̀rọ̀-orúkọ “ẹyọ ẹnì kẹta” ìyẹn “هـُ” tó jẹyọ láti inú āyah 157 títí dé 159 nínú sūrah yìí jẹ́ méjìlá. Àyè kan péré l’ó ti ń tọ́ka sí Allāhu, ìyẹn sì ni kalmọh “إِلَيْهِ”, ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - ni mọ́kànlá yòókù ń tọ́ka sí nítorí pé, ọ̀rọ̀ rẹ̀ nìkan ni kókó nínú àwọn āyah náà. Ìwòyesí yìí tún jẹ́ àtìlẹ́yìn fún àgbọ́yé kìíní láti fi rinlẹ̀ pé “قَبْلَ مَوْتِهِۦۖ” ń túmọ̀ sí “ṣíwájú ikú ‘Isā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - lópin ayé.
ئەرەپچە تەپسىرلەر:
 
مەنالار تەرجىمىسى ئايەت: (159) سۈرە: سۈرە نىسا
سۈرە مۇندەرىجىسى بەت نومۇرى
 
قۇرئان كەرىم مەنىلىرىنىڭ تەرجىمىسى - يورۇباچە تەرجىمىسى - تەرجىمىلەر مۇندەرىجىسى

قۇرئان كەرىمنىڭ يورۇباچە تەرجىمىسىنى شەيىخ ئەبۇ رەھىمە مىيكائىل ئەيكۇينى تەرجىمە قىلغان، ھىجىريە 1432-يىلى بېسىلغان.

تاقاش