قۇرئان كەرىم مەنىلىرىنىڭ تەرجىمىسى - يورۇباچە تەرجىمىسى * - تەرجىمىلەر مۇندەرىجىسى

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

مەنالار تەرجىمىسى ئايەت: (6) سۈرە: سۈرە نىسا
وَٱبۡتَلُواْ ٱلۡيَتَٰمَىٰ حَتَّىٰٓ إِذَا بَلَغُواْ ٱلنِّكَاحَ فَإِنۡ ءَانَسۡتُم مِّنۡهُمۡ رُشۡدٗا فَٱدۡفَعُوٓاْ إِلَيۡهِمۡ أَمۡوَٰلَهُمۡۖ وَلَا تَأۡكُلُوهَآ إِسۡرَافٗا وَبِدَارًا أَن يَكۡبَرُواْۚ وَمَن كَانَ غَنِيّٗا فَلۡيَسۡتَعۡفِفۡۖ وَمَن كَانَ فَقِيرٗا فَلۡيَأۡكُلۡ بِٱلۡمَعۡرُوفِۚ فَإِذَا دَفَعۡتُمۡ إِلَيۡهِمۡ أَمۡوَٰلَهُمۡ فَأَشۡهِدُواْ عَلَيۡهِمۡۚ وَكَفَىٰ بِٱللَّهِ حَسِيبٗا
Ẹ dán àwọn ọmọ òrukàn wò¹ títí wọn yóò fi dàgbà wọ ẹni tí ò lè ṣe ìgbéyàwó.² Tí ẹ bá sì ti rí òye lára wọn, kí ẹ dá dúkìá wọn padà fún wọn. Ẹ ò gbọdọ̀ jẹ dúkìá wọn ní ìjẹ àpà àti ìjẹkújẹ kí wọ́n tó dàgbà. Ẹni tí ó bá jẹ́ ọlọ́rọ̀, kí ó mójú kúrò (níbẹ̀). Ẹni tí ó bá jẹ́ aláìní, kí ó jẹ nínú rẹ̀ ní ọ̀nà tó dára. Nítorí náà, tí ẹ bá fẹ́ dá dúkìá wọn padà fún wọn, ẹ pe àwọn ẹlẹ́rìí sí wọn. Allāhu sì tó ní Olùṣírò.
1. Ìyẹn ni pé, ẹ kọ́kọ́ fi díẹ̀ tó kéré gan-an lé e lọ́wọ́ nínú ogún rẹ̀ tó jẹ́ ohun àmúṣọrọ̀, kí ẹ wo bí ó ṣe máa ṣe àmójútó rẹ̀.
2. “eni tí ó lè ṣe ìgbéyàwó” ni ẹni tí ó ti di ọmọkùnrin tàbí ẹni tí ó ti di ọmọbìnrin. Irú ọmọ náà ni a óò sọ nípa rẹ̀ pé, “ó ti bàlágà”. Ẹni tí ó = = ti bàlágà ni ẹni tí ó lè ṣe ìgbéyàwó. Ẹni tí ó ti bàlágà sì ni ẹni tí ó ti kúrò nípò ọmọdé. Ẹni tí ó ti bàlágà sì ni ẹni tí wọ́n ti la àwọn iṣẹ́ ẹ̀sìn bọ̀ lọ́rùn “mukallaf”. Nípa bẹ́ẹ̀, bí ó bá ṣe iṣẹ́ rere, ó máa gba ẹ̀san rẹ̀. Bí ó bá sì ṣe iṣẹ́ aburú, ó máa gba ẹ̀san rẹ̀. Kí wá ni àwọn àmì tí ẹ̀sìn ’Islām gbékalẹ̀ fún bíbàlágà ọmọdé? Òhun ni ìwọ̀nyí: (1) Dída àtọ̀ mọniyyu sára yálà láti ojú-oorun tàbí láti ojú-ayé nípasẹ̀ oorun ìfẹ́ tàbí ní ọ̀nà mìíràn, (2) tàbí híhu irun abẹ́, (3) tàbí kí ọjọ́ orí ẹni wọ ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún pẹ̀lú òǹkà oṣù ’Islām, (4) tàbí kí obìnrin bẹ̀rẹ̀ n̄ǹkan oṣù rẹ̀ (héélà), (5) tàbí kí obìnrin ní oyún. Èyíkéyìí tí ó bá kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀ nínú àwọn n̄ǹkan márààrún wọ̀nyí ti sọ ọmọdé di àgbà (ẹni tí ó bàlágà).
ئەرەپچە تەپسىرلەر:
 
مەنالار تەرجىمىسى ئايەت: (6) سۈرە: سۈرە نىسا
سۈرە مۇندەرىجىسى بەت نومۇرى
 
قۇرئان كەرىم مەنىلىرىنىڭ تەرجىمىسى - يورۇباچە تەرجىمىسى - تەرجىمىلەر مۇندەرىجىسى

قۇرئان كەرىمنىڭ يورۇباچە تەرجىمىسىنى شەيىخ ئەبۇ رەھىمە مىيكائىل ئەيكۇينى تەرجىمە قىلغان، ھىجىريە 1432-يىلى بېسىلغان.

تاقاش