የቅዱስ ቁርዓን ይዘት ትርጉም - የሩቡኛ ቋንቋ ትርጉም * - የትርጉሞች ማዉጫ

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

የይዘት ትርጉም ምዕራፍ: ሱረቱ አል ፈጅር   አንቀጽ:

Suuratul-Faj'r

وَٱلۡفَجۡرِ
Allāhu fi àfẹ̀mọ́júmọ́ búra.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَلَيَالٍ عَشۡرٖ
Ó tún fi àwọn òru mẹ́wàá kan búra.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَٱلشَّفۡعِ وَٱلۡوَتۡرِ
Ó tún fi n̄ǹkan tí eéjì ń pín geerege àti n̄ǹkan tí eéjì kò pín geerege búra.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَٱلَّيۡلِ إِذَا يَسۡرِ
Ó tún fi òru nígbà tí ó bá dé búra.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
هَلۡ فِي ذَٰلِكَ قَسَمٞ لِّذِي حِجۡرٍ
Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
أَلَمۡ تَرَ كَيۡفَ فَعَلَ رَبُّكَ بِعَادٍ
Ṣé o kò wòye sí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
إِرَمَ ذَاتِ ٱلۡعِمَادِ
(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
ٱلَّتِي لَمۡ يُخۡلَقۡ مِثۡلُهَا فِي ٱلۡبِلَٰدِ
àwọn tí A kò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَثَمُودَ ٱلَّذِينَ جَابُواْ ٱلصَّخۡرَ بِٱلۡوَادِ
Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonúfojì,
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَفِرۡعَوۡنَ ذِي ٱلۡأَوۡتَادِ
àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
ٱلَّذِينَ طَغَوۡاْ فِي ٱلۡبِلَٰدِ
(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn tó tayọ ẹnu-ààlà nínú ìlú.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
فَأَكۡثَرُواْ فِيهَا ٱلۡفَسَادَ
Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
فَصَبَّ عَلَيۡهِمۡ رَبُّكَ سَوۡطَ عَذَابٍ
Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
إِنَّ رَبَّكَ لَبِٱلۡمِرۡصَادِ
Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
فَأَمَّا ٱلۡإِنسَٰنُ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ رَبُّهُۥ فَأَكۡرَمَهُۥ وَنَعَّمَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَكۡرَمَنِ
Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti pọ́n mi lé.”
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَأَمَّآ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ فَقَدَرَ عَلَيۡهِ رِزۡقَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَهَٰنَنِ
Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi.”
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
كَلَّاۖ بَل لَّا تُكۡرِمُونَ ٱلۡيَتِيمَ
Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَلَا تَحَٰٓضُّونَ عَلَىٰ طَعَامِ ٱلۡمِسۡكِينِ
Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَتَأۡكُلُونَ ٱلتُّرَاثَ أَكۡلٗا لَّمّٗا
Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَتُحِبُّونَ ٱلۡمَالَ حُبّٗا جَمّٗا
Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
كَلَّآۖ إِذَا دُكَّتِ ٱلۡأَرۡضُ دَكّٗا دَكّٗا
Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (tó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَجَآءَ رَبُّكَ وَٱلۡمَلَكُ صَفّٗا صَفّٗا
(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَجِاْيٓءَ يَوۡمَئِذِۭ بِجَهَنَّمَۚ يَوۡمَئِذٖ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ وَأَنَّىٰ لَهُ ٱلذِّكۡرَىٰ
ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
يَقُولُ يَٰلَيۡتَنِي قَدَّمۡتُ لِحَيَاتِي
Ó máa wí pé: “Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi.”
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
فَيَوۡمَئِذٖ لَّا يُعَذِّبُ عَذَابَهُۥٓ أَحَدٞ
Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَلَا يُوثِقُ وَثَاقَهُۥٓ أَحَدٞ
Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
يَٰٓأَيَّتُهَا ٱلنَّفۡسُ ٱلۡمُطۡمَئِنَّةُ
Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
ٱرۡجِعِيٓ إِلَىٰ رَبِّكِ رَاضِيَةٗ مَّرۡضِيَّةٗ
padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
فَٱدۡخُلِي فِي عِبَٰدِي
Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
وَٱدۡخُلِي جَنَّتِي
Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.
የአረብኛ ቁርኣን ማብራሪያ:
 
የይዘት ትርጉም ምዕራፍ: ሱረቱ አል ፈጅር
የምዕራፎች ማውጫ የገፅ ቁጥር
 
የቅዱስ ቁርዓን ይዘት ትርጉም - የሩቡኛ ቋንቋ ትርጉም - የትርጉሞች ማዉጫ

በአቡ ራሒማ ሚካኢል አይክዌኒ ወደ ዮሩባ ቋንቋ የተተረጎመ የቁርኣን ትርጉም፣ በ1432 ዓ.ሂ የታተመ።

መዝጋት