ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني آية: (2) سورة: الفاتحة
ٱلۡحَمۡدُ لِلَّهِ رَبِّ ٱلۡعَٰلَمِينَ
Gbogbo ẹyìn¹ ń jẹ́ ti Allāhu, Olúwa² gbogbo ẹ̀dá,
1. Nínú èdè Lárúbáwá, “hamd” yàtọ̀ sí “ṣukr” àmọ́ ìtúmọ̀ ìkíní kejì fẹ́ súnmọ́ ara wọn.
Ìtúmọ̀ “hamd” ni “ẹyìn” èyí tí a sọ jáde ní ẹnu pẹ̀lú ìfẹ́ àti gbígbé-títóbi fún ẹni tí ẹyìn tọ́ sí nítorí pé ẹni náà jẹ́ ẹni tí ó pé tán pátápátá tí kò kù sí ibì kan kan níbi pàápàá rẹ̀, àwọn ìròyìn rẹ̀ àti àwọn ìṣe rẹ̀. Kò sì sí ẹni tí ó pé tán pátápátá bí kò ṣe Allāhu - Ọba tó ga jùlọ -. Nítorí náà, Allāhu nìkan ṣoṣo ni a gbọ́dọ̀ máa yìn gẹ́gẹ́ bí ó ṣe jẹ́ pé, Òun nìkan náà ni a gbọ́dọ̀ máa jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo. Nígbà tí a bá yin ẹ̀dá ẹgbẹ́ wa, “mọdh” ni wọ́n ń pe ìyẹn nínú èdè Lárúbáwá. Kò sì pọn dandan kí ẹyìn náà dénú, ó lè má kọjá orí ahọ́n, gẹ́gẹ́ bí ẹyìn àwọn eléwì.
Ní ti “ṣukr”, ìtúmọ̀ rẹ̀ ni mímọ rírì oore àti sísọ ọ́ jáde. Ẹni tí ó bá mọ rírì oore kan, tí ó sì sọ ọ́ jáde ló dúpẹ́ oore náà fún ẹni tí ó ṣe oore náà fún un. Bí Allāhu bá ṣe oore kan fún mi, mo lè sọ pé, “’aṣkuru-llāh / ṣukrān lillāh” (mo dúpẹ́ fún Allāhu). Bí ìwọ bá ṣoore kan fún mi, mo lè sọ pé, “ ’aṣkuruk / ṣukrān lak (mo dúpẹ́ fún ọ). Paban̄barì rẹ̀ ni pé kí n̄g sọ fún ọ pé, “jazākumullāhu kọerā” (Allāhu á san yín ní ẹ̀san rere.). Kí ìwọ náà yára fọ èsì pé, “ wa ’antum fajazākumullāhu kọerā” (Àti ẹ̀yin náà, Allāhu á san yín ní ẹ̀san rere.) Èsì kọ́ ni “wa’iyyākum”
Àmọ́ a kò gbọ́dọ̀ lo “hamd” fún ẹ̀dá kan lẹ́yìn Allāhu - Ọba Ẹlẹ́yìn. Ẹni tí ó bá wá sọ pé, “alhamdu lillāh” Ó ti kó ẹyìn àti ọpẹ́ sínú. Nítorí náà, kí ẹ̀dá máa ṣe “alhamdu lillāh” ní àsìkò tí a bá rí oore kan gbà láti ọ̀dọ̀ Allāhu àti ní àsìkò tí a kò ì rí oore náà gbá nítorí pé, oore Allāhu lọ́dọ̀ wa pọ̀ láì ní òǹkà.
Ìdí nìyí tí ó fi jẹ́ pé, nígbà tí ìdùnnú kan bá ṣẹlẹ̀ sí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, ó máa sọ pé “ alhamdu lillāh allathī bi ni‘mọtihi tatimmu-ssọ̄lihāt” (gbogbo ẹyìn ń jẹ́ ti Allāhu, ẹni tí àwọn ohun rere ń pé (ń kẹ́sẹjá) pẹ̀lú ìdẹ̀ra Rẹ̀. Tí ìdà kejì bá sì ṣẹlẹ̀, ó máa sọ pé, “alhamdu lillāhi ‘alā kulli hāl” (gbogbo ẹyìn ń jẹ́ ti Allāhu lórí gbogbo ipò (tí ẹ̀dá bá wà).
2. Ọ̀rọ̀ yìí “rọbb” (Olúwa), ó kó ọ̀rọ̀ mẹ́ta sínú. Dídá ẹ̀dá, ṣíṣe ìjọba lórí ẹ̀dá tàbí níni ẹ̀dá àti dídarí ọ̀rọ̀ ẹ̀dá. Nígbà tí a bá pe Allāhu ní “rọbb” (Olúwa), gbogbo ìwọ̀nyẹn ló kó sínú nítorí pé, Allāhu ni Ẹlẹ́dàá wa, tiRẹ̀ ni ìjọba lórí gbogbo ẹ̀dá, Òun sì ni Ó ń darí kádàrá ẹ̀dá. Nítorí náà, Allāhu ni Olúwa wa.
Àmọ́ nígbà tí a bá pe ẹ̀dá kan ní “rọbb”, kò lè kó gbogbo ìròyìn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyẹn sínú. Bí àpẹ̀ẹrẹ, à ń pe onílé ní “rọbbul-baet” nítorí pé, ìtúmọ̀ kan nínú àwọn ìtúmọ̀ “rọbb” ni níni n̄ǹkan”
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني آية: (2) سورة: الفاتحة
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق