ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني آية: (71) سورة: هود
وَٱمۡرَأَتُهُۥ قَآئِمَةٞ فَضَحِكَتۡ فَبَشَّرۡنَٰهَا بِإِسۡحَٰقَ وَمِن وَرَآءِ إِسۡحَٰقَ يَعۡقُوبَ
Ìyàwó rẹ̀ wà ní ìdúró, ó rẹ́rìn-ín. A sì fún un ní ìró ìdùnnú (pé ó máa bí) ’Ishāƙ. Àti pé lẹ́yìn ’Ishāƙ ni Ya‘ƙūb (ìyẹn, ọmọọmọ).¹
1. Àsìkò tí àwọn mọlāika fẹ́ pa ìjọ Ànábì Lūt - kí ọlà Allāhu máa bá a - rẹ́ ni àsìkò tí ìró ìdùnnú àsọtẹ́lẹ̀ bíbí Ànábì ’Ishāƙ - kí ọlà Allāhu máa bá a - bọ́ sí. Èyí túmọ̀ sí pé, lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ tí Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - ti fẹ́ fi àkọ́bí rẹ̀ Ànábì ’Ismọ̄‘īl - kí ọlà Allāhu máa bá a - jọ́sìn fún Allāhu - subhānahu wa ta'ālā - ni àsọtẹ́lẹ̀ bíbí Ànábì ’Ishāƙ - kí ọlà Allāhu máa bá a - ṣẹlẹ̀. Ìdí ni pé, ọlá àdúà tí Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - ṣe láti tọrọ ọmọ ló jẹ́ sábàbí fún bíbí Ànábì ’Ismọ̄‘īl - kí ọlà Allāhu máa bá a -. Àmọ́ ọlá ìtẹ̀lé àṣẹ tí Allāhu pa pé kí Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - fi “ọmọ àdúà náà” Ànábì ’Ismọ̄‘īl - kí ọlà Allāhu máa bá a - jọ́sìn fún Òun ló jẹ́ sábàbí fún bíbí Ànábì ’Ishāƙ - kí ọlà Allāhu máa bá a -.
Kíyè sí i, àdúà “ìrawọ́rasẹ̀” sí Allāhu tí Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - ṣe láti fi tọrọ Ànábì ’Ismọ̄‘īl - kí ọlà Allāhu máa bá a - kò la ìjẹ́jẹ̀ẹ́ kan kan lọ, gẹ́gẹ́ bí àwọn kan ṣe lérò. Ẹ ka sūrah ‘Ibrọ̄hīm; 14:39 àti sūrah as-Sọ̄ffāt; 37: 100 - 113.
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني آية: (71) سورة: هود
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق