ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني آية: (9) سورة: ابراهيم
أَلَمۡ يَأۡتِكُمۡ نَبَؤُاْ ٱلَّذِينَ مِن قَبۡلِكُمۡ قَوۡمِ نُوحٖ وَعَادٖ وَثَمُودَ وَٱلَّذِينَ مِنۢ بَعۡدِهِمۡ لَا يَعۡلَمُهُمۡ إِلَّا ٱللَّهُۚ جَآءَتۡهُمۡ رُسُلُهُم بِٱلۡبَيِّنَٰتِ فَرَدُّوٓاْ أَيۡدِيَهُمۡ فِيٓ أَفۡوَٰهِهِمۡ وَقَالُوٓاْ إِنَّا كَفَرۡنَا بِمَآ أُرۡسِلۡتُم بِهِۦ وَإِنَّا لَفِي شَكّٖ مِّمَّا تَدۡعُونَنَآ إِلَيۡهِ مُرِيبٖ
Ṣé ìró àwọn tó ṣíwájú yín kò tí ì dé ba yín ni? Ìjọ (Ànábì) Nūh, ìjọ ‘Ād, ìjọ Thamūd àti àwọn tó wá lẹ́yìn wọn; kò sí ẹni tí ó mọ̀ wọ́n àfi Allāhu. Àwọn Òjíṣẹ́ wọn mú àwọn ẹ̀rí tó yanjú wá bá wọn. Nígbà náà, wọ́n dá ọwọ́ wọn padà sí ẹnu wọn¹, wọ́n sì wí pé: “Dájúdájú àwa ṣàì gbàgbọ́ nínú n̄ǹkan tí wọ́n fi ran yín níṣẹ́. Àti pé dájúdájú àwa wà nínú iyèméjì tó gbópọn nípa ohun tí ẹ̀ ń pè wá sí.”
1. Ọmọ ‘Abbās - kí Allāhu yọ́nú sí àwọn méjèèjì - sọ pé, “Dájúdájú ìtúmọ̀ “wọ́n dá ọwọ́ wọn padà sí ẹnu wọn “ ni pé, dájúdájú àwọn ènìyàn náà, nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Allāhu, wọ́n ṣèèmọ̀, wọ́n sì dá ọwọ́ wọn padà sí ẹnu wọn bí ẹni tí ó fẹ́ kí ẹni tí ó jìnnà sí òun gbọ́ ohùn rẹ̀. Ìyẹn ni pé, dájúdájú èyí ni ìsọ tó ń tọ́ka sí bí wọ́n ṣe gbé ohùn wọn sókè, tí wọ́n ń lọgun pé, àwọn kò gbàgbọ́ nínú iṣẹ́ tí àwọn Òjíṣẹ́ jẹ́.” Àfijọ èyí ni bí ẹni tí ó káwọ́ rẹ̀ méjèèjì sẹ́nu láti hu sí ẹnì kan nínú igbó.
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني آية: (9) سورة: ابراهيم
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق