ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني آية: (16) سورة: النحل
وَعَلَٰمَٰتٖۚ وَبِٱلنَّجۡمِ هُمۡ يَهۡتَدُونَ
àti àwọn àmì òpópónà (fún ìtọ́sọ́nà ìrìn ọ̀sán). Wọ́n tún ń fi ìràwọ̀ dá ojú ọ̀nà mọ̀ (lálẹ́).¹
1. Àwọn n̄ǹkan tí Allāhu - subhānahu wa ta'ālā - dá fún dídá ojú ọ̀nà mọ̀ wọ̀nyí dúró fún rírína rí ojú ọ̀nà, yálà ní alẹ́ pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ tàbí ní ọ̀sán pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ òòrùn àti àwọn atọ́ka òpópónà. Nítorí náà, mímọ̀ nípa ìràwọ̀ kò sí fún mímọ ìkọ̀kọ̀ àti ìṣẹ̀lẹ̀ ọjọ́ ọ̀la. Kò sì wulẹ̀ rọrùn fún ẹnikẹ́ni láti mọ ìkọ̀kọ̀ tàbí ìṣẹ̀lẹ̀ ọjọ́ ọ̀la. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah Luƙmọ̄n; 31:34 àti sūrah an-Naml; 27:65.
Síwájú sí i, ẹnikẹ́ni tó ń ṣe iṣẹ́ àyẹ̀wò láti sọ nípa ohun tí ó pamọ́ fún ẹ̀dá, ó ti di aláìgbàgbọ́. Bákan náà ni ọ̀rọ̀ ṣe rí lára ẹni tó gbàgbọ́ nínú ọ̀rọ̀ ẹnu alábigba, awòràwọ̀, oníyanrìn-títẹ̀, onítẹ̀sùnbáà-wíwò àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Àmọ́ sa, ’Islām kò lòdì sí ṣíṣe àyẹ̀wò àìsàn ara, àìsàn inú ẹ̀jẹ̀, yíya àwòrán egungun àti àwòrán ọlẹ̀ ní ilé ìwòsàn àwọn akọ́ṣẹ́-mọṣẹ́ ti òyìnbó.
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني آية: (16) سورة: النحل
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق