ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني آية: (4) سورة: محمد
فَإِذَا لَقِيتُمُ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ فَضَرۡبَ ٱلرِّقَابِ حَتَّىٰٓ إِذَآ أَثۡخَنتُمُوهُمۡ فَشُدُّواْ ٱلۡوَثَاقَ فَإِمَّا مَنَّۢا بَعۡدُ وَإِمَّا فِدَآءً حَتَّىٰ تَضَعَ ٱلۡحَرۡبُ أَوۡزَارَهَاۚ ذَٰلِكَۖ وَلَوۡ يَشَآءُ ٱللَّهُ لَٱنتَصَرَ مِنۡهُمۡ وَلَٰكِن لِّيَبۡلُوَاْ بَعۡضَكُم بِبَعۡضٖۗ وَٱلَّذِينَ قُتِلُواْ فِي سَبِيلِ ٱللَّهِ فَلَن يُضِلَّ أَعۡمَٰلَهُمۡ
Nítorí náà, nígbà tí ẹ bá pàdé àwọn tó ṣàì gbàgbọ́ (lójú ogun ẹ̀sìn), ẹ máa bẹ́ wọn lọ́rùn ǹsó títí di ìgbà tí ẹ máa fi rí wọn pa dáadáa. (Nígbà tí ọwọ́ yín bá ti bà wọ́n tán), ẹ dè wọ́n mọ́lẹ̀ sórí ìgbèkùn. Lẹ́yìn náà, ẹ lè tú wọn sílẹ̀ ní ọ̀fẹ́ tàbí kí ẹ tú wọn sílẹ̀ pẹ̀lú owó ìtúsílẹ̀ títí kò fi níí sí ogun ẹ̀sìn mọ́.1 Ìyẹn (wà bẹ́ẹ̀). Tí ó bá jẹ́ pé Allāhu bá fẹ́, ìbá gbẹ̀san fúnra Rẹ̀ (láì níí la ogun lọ), ṣùgbọ́n nítorí kí Ó lè dán apá kan yín wò lára apá kan ni. Àwọn mùsùlùmí tí wọ́n sì pa sí ojú-ọ̀nà Allāhu, Allāhu kò níí sọ iṣẹ́ wọn dòfo.
1. “títí kò fi níí sí ogun ẹ̀sìn mọ́” Ìgbà wo ni ìyẹn máa ṣẹlẹ̀ nílé ayé? Mujāhid - kí Allāhu kẹ́ ẹ - sọ pé, “Títí di ìgbà tí Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - yóò fi sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ ní òpin ayé.” Ìyẹn ni pé, ó di ìgbà tí Ànábì ‘Īsā bá tó sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ kí ogun ẹ̀sìn tó kásẹ̀ nílẹ̀. Ƙọtādah - kí Allāhu kẹ́ ẹ - sọ pé, “Títí di ìgbà tí kò bá sí ìbọ̀rìsà mọ́ nílé ayé.” Ibn Kathīr.
Kíyè sí i! Nígbà tí ogun ẹ̀sìn ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ní àsìkò Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, kò sí kíkó ẹrú ogun wálé. Èyí jẹ́ òfin ìpìlẹ̀ tí ó wà nínú sūrah Al-’Anfāl; 8:67. Àmọ́ lẹ́yìn tí ọwọ́ pípa ti dun àwọn aláìgbàgbọ́ dáadáa lójú ogun ẹ̀sìn, tí àwọn èèkàn èèkan nínú wọn ti bá ogun lọ, ẹ̀tọ́ wà nígbà náà láti máa sọ wọ́n di ẹrú ogun. Èyí sì ni ó jẹyọ nínú āyah òkè yìí.
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني آية: (4) سورة: محمد
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق