Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Vers: (6) Surah / Kapitel: Al-Baqarah
إِنَّ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ سَوَآءٌ عَلَيۡهِمۡ ءَأَنذَرۡتَهُمۡ أَمۡ لَمۡ تُنذِرۡهُمۡ لَا يُؤۡمِنُونَ
Dájúdájú àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, bákan náà ni fún wọn, yálà o kìlọ̀ fún wọn tàbí o kò kìlọ̀ fún wọn, wọn kò níí gbàgbọ́.¹
1. Àwọn wọ̀nyẹn ni àwọn tí kádàrá wọn lórí jíjẹ́ kèfèrí wọn kò níí yí padà. Àmọ́ ní ti àwọn tí kádàrá ìrònúpìwàdà máa borí wọn, ìkìlọ̀ máa sọ wọ́n di mùsùlùmí. Āyah yìí sọ̀kalẹ̀ nítorí àwọn tí wọ́n ń kú sínú kèfèrí lẹ́yìn tí ìkìlọ̀ ti dé etí ìgbọ́ wọn pé, ọmọ Iná ni gbogbo ẹni tí kò bá kú sínú ’Islām. Nítorí náà, āyah yìí kò sọ̀kalẹ̀ nítorí gbogbo àwọn aláìgbàgbọ́ nítorí pé, a kúkú ń fojú rí àwọn kan nínú wọn tí wọ́n ń gba ’Islām. Àti pé ọ̀wọ́ àwọn tí àdánwò èdídí ọkàn, èdídí ìgbọ́rọ̀ àti èbìbò ojú bá wà lára wọn ló máa takú sínú kèfèrí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Vers: (6) Surah / Kapitel: Al-Baqarah
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen