Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Vers: (91) Surah / Kapitel: Al-Anbiyâ’
وَٱلَّتِيٓ أَحۡصَنَتۡ فَرۡجَهَا فَنَفَخۡنَا فِيهَا مِن رُّوحِنَا وَجَعَلۡنَٰهَا وَٱبۡنَهَآ ءَايَةٗ لِّلۡعَٰلَمِينَ
(Ẹ rántí obìnrin) èyí tí ó ṣọ́ abẹ́ rẹ̀. A sì fẹ́ atẹ́gùn nínú àwọn atẹ́gùn ẹ̀mí tí A dá sí i lára. A sì ṣe òun àti ọmọkùnrin rẹ̀ ní àmì fún gbogbo ẹ̀dá.¹
1. Kíyè sí i! Ṣíṣe tí Allāhu - Ọba tó ga jùlọ - ṣe Mọryam àti ọmọ rẹ̀, Ànábì ‘Īsā - kí ọlà Allāhu máa bá a - ní àmì fún gbogbo ẹ̀dá, kò túmọ̀ sí pé ìkíní kejì wọn jẹ́ olúwa àti olùgbàlà. Àmọ́ kí ẹ̀dá lè wòye sí agbára Allāhu pé, Ó máa ń ṣe ọ̀rọ̀ ẹ̀dá bí Ó bá ṣe fẹ́. Tí ẹnì kan bá wá tìtorí ìyẹn sọ ẹ̀dá kan di olúwa àti olùgbàlà lẹ́yìn Allāhu, Ọba Oníṣẹ́-ìyanu, onítọ̀ún ti sọnù jìnnà. Bákan náà, ẹ tún wo irú gbólóhùn yìí “àmì fún gbogbo ẹ̀dá” nínú sūrah al-’Ankabūt; 29:15.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Vers: (91) Surah / Kapitel: Al-Anbiyâ’
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen