Mímọ́ ni fún Ẹni tí Ó mú ẹrúsìn Rẹ̀ ṣe ìrìn-àjò ní alẹ́ láti Mọ́sálásí Haram sí Mọ́sálásí Aƙsọ̄ tí A fi ìbùkún yí ká, nítorí kí Á lè fi nínú àwọn àmì Wa hàn án. Dájúdájú Allāhu, Òun ni Olùgbọ́, Olùríran.¹
1. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn kan lérò pé àlá lílá ni ìrìn-àjò òru tí Allāhu - subhānahu wa ta ‘ālā - mú Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -rìn, ohun tí ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀ jùlọ ni pé, ìrìn-àjò òru náà jẹ́ ìrìn-àjò ẹ̀mí àti ara. Èyí rí bẹ́ẹ̀ nítorí pé Allāhu - subhānahu wa ta ‘ālā - kò sọ ọ̀rọ̀ ìrìn-àjò náà ní ìsọ àlá lílá páàpáà. Ẹ wo àgbékalẹ̀ āyah ìrìn-àjò ẹ̀mí àti ara yìí sí àgbékalẹ̀ àwọn āyah àlá lílá wọ̀nyí nínú sūrah Yūsuf; 12:4 & 43, sūrah as-Sọ̄ffāt; 37:102 àti sūrah al-Fat-h; 48:27.
Bákan náà, ìrìn-àjò náà ìbá jẹ́ àlá lílá, àwọn ọ̀ṣẹbọ ìbá tí ṣe àtakò sí i. Àti pé ṣíṣe àtakò sí ìrìn-àjò náà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀ṣẹbọ nípa bí ìró ìṣẹ̀lẹ̀ ìrìn-àjò òru náà ṣe ga tayọ òye wọn ló kó wọn sínú àdánwò tí Allāhu - subhānahu wa ta ‘ālā - sọ nípa rẹ̀ nínú āyah 60 nínú sūrah yìí.
Kíyè sí i, gbólóhùn “subhān-llathī” ìbá tí bẹ̀rẹ̀ āyah yìí, Tí ó bá jẹ́ pé ìrìn-àjò ojú àlá lásán ni.
Síwájú sí i, àwọn n̄ǹkan pàtàkì pàtàkì ni Ànábì wa - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - fojú rí nínú àwọn sánmọ̀ àti lókè sánmọ̀ keje lórí ìrìn-àjò òru rẹ̀ tí Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā - mú un rìn. Nínú ìrìn-àjò òru náà ni Allāhu sì ti fún un ní àwọn ìrun wákàtí = = márùn-ún. Àmọ́ Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - kò fojú rí Allāhu rárá - subhānahu wa ta‘ālā - ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ ìyá wa ‘Ā’iṣah - kí Allāhu yọ́nú sí i - tí ó sọ pé: “Dájúdájú òpùrọ́ ni ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ pé (Ànábì) Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - fojú rí Olúwa rẹ̀. Lẹ́yìn náà, ìyá wa, ‘Ā’iṣah - kí Allāhu yọ́nú sí i - fi sūrah al-’An‘ām; 6:103 àti sūrah aṣ-Ṣūrọ̄; 42:51 ṣe ẹ̀rí ọ̀rọ̀ náà.” (al-Bukāriy)
Síwájú sí i, àwọn mùsùlùmí, wọ́n ti ń kí ìrun ṣíwájú ìrìn-àjò òru náà, àmọ́ kì í ṣe ìrun wákàtí márùn-ún, kódà kì í ṣe ìrun ọ̀ran-anyàn. Ìrìn-àjò òru àti ìgun-sánmọ̀-lọ Ànábì wa - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ló bí ìrun ọ̀ran-anyàn àti ìrun wákàtí márùn-ún ojoojúmọ́.
Síwájú sí i, ọ̀rọ̀ yìí “bi ‘abdih” (ẹrúsìn Rẹ̀). Ẹrúsìn Rẹ̀ nínú āyah yìí kò dúró fún ẹnì kan bí kò ṣe Ànábì wa Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -. Àpẹ̀ẹrẹ àyè mìíràn nìyí: sūrah al-Kahf; 18:1, sūrah al-Furƙọ̄n; 25:1, sūrah az-Zumọr; 39:36, sūrah an-Najm; 53:10 àti sūrah al-Hadīd; 57:9. Àyè ẹyọ kan péré tí “‘abdah” kò ti dúró fún un, Allāhu - subhānahu wa ta ‘ālā - kúkú dárúkọ ẹni tí “‘abdah” dúró fún níbẹ̀. Àyè náà ni sūrah Mọryam; 19:2.
Contents of the translations can be downloaded and re-published, with the following terms and conditions:
1. No modification, addition, or deletion of the content.
2. Clearly referring to the publisher and the source (QuranEnc.com).
3. Mentioning the version number when re-publishing the translation.
4. Keeping the transcript information inside the document.
5. Notifying the source (QuranEnc.com) of any note on the translation.
6. Updating the translation according to the latest version issued from the source (QuranEnc.com).
7. Inappropriate advertisements must not be included when displaying translations of the meanings of the Noble Quran.
Search results:
API specs
Endpoints:
Sura translation
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/sura/{translation_key}/{sura_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified sura (by its number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114)
Returns:
json object containing array of objects, each object contains the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/aya/{translation_key}/{sura_number}/{aya_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified aya (by its number sura_number and aya_number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114) aya_number: [1-...] (Aya number in the sura)
Returns:
json object containing the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".