Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Ayah: (78) Surah: Al-An‘ām
فَلَمَّا رَءَا ٱلشَّمۡسَ بَازِغَةٗ قَالَ هَٰذَا رَبِّي هَٰذَآ أَكۡبَرُۖ فَلَمَّآ أَفَلَتۡ قَالَ يَٰقَوۡمِ إِنِّي بَرِيٓءٞ مِّمَّا تُشۡرِكُونَ
Nígbà tí ó rí òòrùn tó yọ, ó sọ pé: “Èyí ni olúwa mi; èyí tóbi jùlọ.” Nígbà tó wọ̀, ó sọ pé: “Ẹ̀yin ènìyàn mi, dájúdájú èmi yọwọ́ yọsẹ̀ nínú ohun tí ẹ ń fi ṣẹbọ (sí Allāhu).¹
1. Nínú àwọn āyah 76, 77 àti 78, ní tẹ̀léǹtẹ̀lé ni Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - ti pe ìràwọ̀, òṣùpá àti òòrùn ní olúwà rẹ̀ lẹ́yìn Allāhu! Èèwọ̀ sì ni sísọ bẹ́ẹ̀. Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - tún wọ́gi lé ìkọ̀ọ̀kan wọn ní tẹ̀léǹtẹ̀lé àti lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀! Ǹjẹ́ pípè tí Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - pe ìràwọ̀, òṣùpá àti òòrùn ní olúwà rẹ̀ sọ ọ́ di ọ̀ṣẹbọ bí? Rárá. Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - kò jọ́sìn fún ìràwọ̀, òṣùpá, òòrùn àti òrìṣà kan kan rí nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀, láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí ọjọ́ ikú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àwọn yòókù nínú àwọn Ànábì àti àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu - kí ọlà Allāhu máa bá gbogbo wọn - kò ṣe ṣẹbọ rí. Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā - sì ti ṣe àfọ̀mọ́ Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - pé kò ṣẹbọ rí, gẹ́gẹ́ bí èyí ṣe rinlẹ̀ bẹ́ẹ̀ nínú sūrah al-Baƙọrah; 2:135, sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:67 àti 95, sūrah al-’Ani‘ām; 6:161 àti sūrah an-Nahl; 16:120 àti 123. Àwọn onímọ̀ sì ṣe àlàyé lórí àwọn āyah 76, 77 àti 78 nínú sūrah al-’Ani‘ām yìí púpọ̀ pẹ̀lú èròǹgbà láti ṣọ́ ẹnu wa níbi sísọ ìsọkúsọ nípa Ànábì ’Ibrọ̄hīm, àyò Allāhu (kọlīlu-llāh). Èyí tí àwọn onímọ̀ ṣe yìí pé kí á ṣọ́ ẹnu wa níbi sísọ ìsọkúsọ nípa Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - wà ní ìbámu sí sūrah Mọryam; 90:50.
Lẹ́yìn náà, èyí tí ó tẹ́rùn jùlọ gẹ́gẹ́ bí ibùgbékà ọ̀rọ̀ náà ni àlàyé tí àwọn àfáà mú wá pé, “Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - mú ọ̀rọ̀ náà wá lójú pọ̀n-nà ìgbémọ́ra àti ìjẹ́nilẹ́gọ̀ọ́ láti sọ àròjàre ìjọ rẹ̀ di àròjẹ̀bi wọn, kì í ṣe lójú pọ̀n-nà ìṣeyèméjì nípa Allāhu - subhānahu wa ta'ālā -. Bí ọ̀rọ̀ ṣe rí gẹ́lẹ́ nìyẹn - w-Allahu ’a‘lam - nítorí pé ohun tí ọ̀rọ̀ náà jọ ni kí a sọ pé, Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - sọ pé, “Ṣé èyí “ìràwọ̀” ni olúwa mi? Rárá. Ṣé èyí “òṣùpá” ni olúwá mi? Rárá… Ìwọ̀nyẹn sì ni àwọn n̄ǹkan tí ìjọ rẹ̀ ń jọ́sìn fún lẹ́yìn Allāhu. Ìjọ rẹ̀ l’ó ń pe ìwọ̀nyẹn ní olúwa wọn. Àmọ́ Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - ń wá ọ̀nà tí ó máa gbà fi yé wọn pé ìràwọ̀, òṣùpá, òòrùn tàbí òrìṣà kan kò lè jẹ́ olúwa kí ó máa sá lọ sá bọ̀.
A kúkú tún rí ìṣẹ̀lẹ̀ mìíràn lọ́dọ̀ Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - lójú pọ̀n-nà ẹ̀lọ́. Ìyẹn nígbà tí àwọn abọ̀rìṣà bi í léèrè pé, “Ṣé ìwọ l’o ṣe èyí pẹ̀lú àwọn ọlọ́hun wa, ’Ibrọ̄hīm?” Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - sì sọ pé: “Rárá o, àgbà wọn yìí l’ó ṣe (wọ́n bẹ́ẹ̀).” Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - l’ó sì yọ àáké ti àwọn òrìṣà wọn, tí ó sì rún wọn wómúwómú. Àmọ́ ó kúkú sọ òye tó fẹ́ kí àwọn ọ̀ṣẹbọ mú jáde nínú ìṣẹ̀lẹ̀ náà. Òye náà ni pé, ó sọ pé: “Nítorí náà, ẹ bi wọ́n léèrè wò tí wọ́n bá máa ń sọ̀rọ̀.” (sūrah al-’Anbiyā’; 21:62-63).
Èyí kò kúkú sọ Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - di òpùrọ́, ìyẹn kò sì sọ Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - di ọ̀ṣẹbọ, àmọ́ ìkíní kejì wà lábẹ́ fífi òye ṣàyẹ̀wò òye wọn wò bóyá òye wọn ti rí ìmọ́lẹ̀ tàbí ó sì wà nínú òkùnkùn. Òye tí ó bá rí ìmọ́lẹ̀ l’ó máa rí ìdáláre fún ohun tí Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a - ṣe wọ̀nyí. Àmọ́ tí òye bá wà nínú òkùnkùn kò níí rí ìdáláre náà, gẹ́gẹ́ bí òye àwọn ọ̀ṣẹbọ ọjọ́ náà kò ṣe rí ìdáláre fún Ànábì ’Ibrọ̄hīm - kí ọlà Allāhu máa bá a -.
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Ayah: (78) Surah: Al-An‘ām
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close