Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Surah: Al-Infitār   Ayah:

Suuratul-Infitoor

إِذَا ٱلسَّمَآءُ ٱنفَطَرَتۡ
Nígbà tí sánmọ̀ bá fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,¹
1. Ẹ wo sūrah al-Baƙọrah ; 2:210, sūrah al-Furƙọ̄n; 25:25 àti Sūrah al-’Inṣiƙọ̄ƙ; 84:1-2
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِذَا ٱلۡكَوَاكِبُ ٱنتَثَرَتۡ
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِذَا ٱلۡبِحَارُ فُجِّرَتۡ
àti nígbà tí àwọn ibúdò bá ṣàn jára wọn,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِذَا ٱلۡقُبُورُ بُعۡثِرَتۡ
àti (nígbà tí A bá ta ilẹ̀ sókè), tí A sì mú àwọn òkú jáde (láàyè) láti inú àwọn sàréè,
Arabic explanations of the Qur’an:
عَلِمَتۡ نَفۡسٞ مَّا قَدَّمَتۡ وَأَخَّرَتۡ
(nígbà náà ni) ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan yóò mọ ohun tí ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tí ó fi sẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
Arabic explanations of the Qur’an:
يَٰٓأَيُّهَا ٱلۡإِنسَٰنُ مَا غَرَّكَ بِرَبِّكَ ٱلۡكَرِيمِ
Ìwọ ènìyàn, kí ni ó tàn ọ́ jẹ nípa Olúwa rẹ, Alápọ̀n-ọ́nlé,
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱلَّذِي خَلَقَكَ فَسَوَّىٰكَ فَعَدَلَكَ
Ẹni t’Ó ṣẹ̀dá rẹ? Ó ṣẹ̀dá rẹ̀ ní pípé. Ó sì mú ọ dọ́gba jalẹ̀ léèyàn.
Arabic explanations of the Qur’an:
فِيٓ أَيِّ صُورَةٖ مَّا شَآءَ رَكَّبَكَ
Ó to ẹ̀yà ara rẹ papọ̀ sínú èyíkéyìí àwòrán tí Ó fẹ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّا بَلۡ تُكَذِّبُونَ بِٱلدِّينِ
Rárá! Bí kò ṣe pé ẹ̀ ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِنَّ عَلَيۡكُمۡ لَحَٰفِظِينَ
Dájúdájú àwọn ẹ̀ṣọ́ sì wà ní ọ̀dọ̀ yín.
Arabic explanations of the Qur’an:
كِرَامٗا كَٰتِبِينَ
(Wọ́n jẹ́) alápọ̀n-ọ́nlé, òǹkọ̀wé-iṣẹ́ ẹ̀dá.
Arabic explanations of the Qur’an:
يَعۡلَمُونَ مَا تَفۡعَلُونَ
Wọ́n mọ ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّ ٱلۡأَبۡرَارَ لَفِي نَعِيمٖ
Dájúdájú àwọn ẹni rere yóò kúkú wà nínú ìgbádùn.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَإِنَّ ٱلۡفُجَّارَ لَفِي جَحِيمٖ
Dájúdájú àwọn ẹni ibi yó sì kúkú wà nínú iná Jẹhīm.
Arabic explanations of the Qur’an:
يَصۡلَوۡنَهَا يَوۡمَ ٱلدِّينِ
Wọn yóò wọ inú rẹ̀ ní Ọjọ́ ẹ̀san.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَمَا هُمۡ عَنۡهَا بِغَآئِبِينَ
Wọn kò sì níí kúrò nínú rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا يَوۡمُ ٱلدِّينِ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ مَآ أَدۡرَىٰكَ مَا يَوۡمُ ٱلدِّينِ
Lẹ́yìn náà, kí ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
Arabic explanations of the Qur’an:
يَوۡمَ لَا تَمۡلِكُ نَفۡسٞ لِّنَفۡسٖ شَيۡـٔٗاۖ وَٱلۡأَمۡرُ يَوۡمَئِذٖ لِّلَّهِ
(Ọjọ́ ẹ̀san ni) ọjọ́ tí ẹ̀mí kan kò níí kápá kiní kan fún ẹ̀mí kan. Gbogbo àṣẹ ọjọ́ yẹn sì ń jẹ́ ti Allāhu.
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Surah: Al-Infitār
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close