Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Surah: Al-‘Alaq   Ayah:

Suuratul-Halaq

ٱقۡرَأۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلَّذِي خَلَقَ
Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.
Arabic explanations of the Qur’an:
خَلَقَ ٱلۡإِنسَٰنَ مِنۡ عَلَقٍ
Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱقۡرَأۡ وَرَبُّكَ ٱلۡأَكۡرَمُ
Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱلَّذِي عَلَّمَ بِٱلۡقَلَمِ
Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.
Arabic explanations of the Qur’an:
عَلَّمَ ٱلۡإِنسَٰنَ مَا لَمۡ يَعۡلَمۡ
Ó fi ìmọ̀ tí ènìyàn kò mọ̀ mọ̀ ọ́n.
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّآ إِنَّ ٱلۡإِنسَٰنَ لَيَطۡغَىٰٓ
Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-ààlà
Arabic explanations of the Qur’an:
أَن رَّءَاهُ ٱسۡتَغۡنَىٰٓ
nítorí pé ó rí ara rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّ إِلَىٰ رَبِّكَ ٱلرُّجۡعَىٰٓ
Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.
Arabic explanations of the Qur’an:
أَرَءَيۡتَ ٱلَّذِي يَنۡهَىٰ
Sọ fún mi nípa ẹni tó ń kọ̀
Arabic explanations of the Qur’an:
عَبۡدًا إِذَا صَلَّىٰٓ
fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!
Arabic explanations of the Qur’an:
أَرَءَيۡتَ إِن كَانَ عَلَى ٱلۡهُدَىٰٓ
Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)
Arabic explanations of the Qur’an:
أَوۡ أَمَرَ بِٱلتَّقۡوَىٰٓ
tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!
Arabic explanations of the Qur’an:
أَرَءَيۡتَ إِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰٓ
Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo ní irọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?
Arabic explanations of the Qur’an:
أَلَمۡ يَعۡلَم بِأَنَّ ٱللَّهَ يَرَىٰ
Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّا لَئِن لَّمۡ يَنتَهِ لَنَسۡفَعَۢا بِٱلنَّاصِيَةِ
Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ọ̀tá Allāhu ṣe rò ó sí.¹) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí² rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);
1. Ẹni yẹn ni Abu Jahl.
2. àásó orí; irun iwájú orí.
Arabic explanations of the Qur’an:
نَاصِيَةٖ كَٰذِبَةٍ خَاطِئَةٖ
àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَلۡيَدۡعُ نَادِيَهُۥ
Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
سَنَدۡعُ ٱلزَّبَانِيَةَ
Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّا لَا تُطِعۡهُ وَٱسۡجُدۡۤ وَٱقۡتَرِب۩
Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ó ṣe ń sọ nípa Wa). Má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o sì súnmọ́ (Allāhu).
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Surah: Al-‘Alaq
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close