Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (47) Capítulo: Sura Yunus
وَلِكُلِّ أُمَّةٖ رَّسُولٞۖ فَإِذَا جَآءَ رَسُولُهُمۡ قُضِيَ بَيۡنَهُم بِٱلۡقِسۡطِ وَهُمۡ لَا يُظۡلَمُونَ
Òjíṣẹ́ ti wà fún ìjọ kọ̀ọ̀kan.¹ Nítorí náà, nígbà tí Òjíṣẹ́ wọn bá dé, A óò ṣèdájọ́ láààrin wọn pẹ̀lú déédé; A ò sì níí ṣàbòsí sí wọn.
1. Āyah yìí àti tinú sūrah Fātir; 35:24 jẹ́ ọ̀kan nínú ọ̀nà tí ìjọ Ahmadiyyah gbà di kèfèrí. Ìdí ni pé, nítorí àwọn āyah wọ̀nyẹn ni ìjọ náà fi pe gbogbo òrìṣà ní ànábì Ọlọ́hun, àti pé wọ́n gbàgbọ́ pé kò sí ìlú tí Allāhu kò ti gbé òjíṣẹ́ kọ̀ọ̀kan dìde, títí dé ilẹ̀ Yorùbá, ilẹ̀ Haúsá, ilẹ̀ Yíbò àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ìtọ́kasí wọn nìyí: “In pursuance of this doctrine, he (mirza Ghulam Ahmad al-Ƙadiyyaaniy) testified to the truth of Krishna, Ram Chandra and Buddha, the prophets of India, and Zoroaster, the prophet of Persia, and described the rejection of their claims as, in a sense, amounting to a denial of the universal Providence of God.” Ìtúmọ̀ “Láti lè tẹ̀lé ìgbàgbọ́ yìí ló mú kí mirza Ghulam Ahmad jẹ́rìí pé òdodo ni òrìṣà Krishna, òrìṣà Ram Chandra àti òrìṣà Buda, tí wọ́n jẹ́ àwọn ànábì ilẹ̀ India. Àti òrìṣà Zoroaster, tí ó jẹ́ ànábì ilẹ̀ Persia. Mirza Ghulam Ahmad sì gbà pé ẹni tí ó bá tako àwọn òrìṣà náà, ó ti tako oore tí Allāhu ṣe fún àgbáyé.” Ahmadiyyah Movement, láti ọwọ́ Bashirud-din Mahmud Ahmad, ojú ewé: 69.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (47) Capítulo: Sura Yunus
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar