Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (75) Capítulo: Sura Al-Hayy
ٱللَّهُ يَصۡطَفِي مِنَ ٱلۡمَلَٰٓئِكَةِ رُسُلٗا وَمِنَ ٱلنَّاسِۚ إِنَّ ٱللَّهَ سَمِيعُۢ بَصِيرٞ
Allāhu l’Ó ń ṣa àwọn kan lẹ́ṣà (láti jẹ́) Òjíṣẹ́ nínú àwọn mọlāika àti nínú àwọn ènìyàn. Dájúdájú Allāhu ni Olùgbọ́, Olùríran.¹
1. Kíyè sí i! Āyah yìí jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn āyah tí àwọn òpùrọ́ àsoòkùn sẹ́sìn máa ń lò láti fi sọ pé, Allāhu kò ì dáwọ́ fífi iṣẹ́ jíjẹ́ Rẹ̀ rán àwọn ènìyàn kan níṣẹ́ sáyé lẹ́yìn ikú Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - . Àwọn tí wọ́n pa irọ́ ńlá yìí mọ Allāhu kò gbàgbọ́ pé tírà ìkẹ́yìn tí wọ́n fi jíṣẹ́ Allāhu fún gbogbo ayé ni al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé. Àti pé, wọ́n kò gbàgbọ́ pé, Ànábì wa Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ni òpin gbogbo àwọn tí Allāhu fi iṣẹ́ jíjẹ́ Rẹ̀ rán nínú àwọn ènìyàn àti àlùjànnú.
Nípa àìgbàgbọ́ wọn yìí, wọ́n sọ àwọn ààfáà wọn di “wòlíì onímìísí”. Irú àwọn wọ̀nyí ni ìjọ Ahmadiyyah, ìjọ onísūfī Tijäniyyah àti Ƙọ̄diriyyah, àti àwọn ìjọ ẹlẹ́mìí gbígbé. Irú àwọn wọ̀nyí tí jáde kúrò nínú ìgbàgbọ́ òdodo tí ’Islām mú wá pátápátá. Wọ́n ti di aláìgbàgbọ́. Èèwọ̀ sì ni fún mùsùlùmí òdodo láti kí ìrun lẹ́yìn wọn. Bí irú àwọn aláìgbàgbọ́ wọ̀nyí bá wà ní orí ilẹ̀ tí wọ́n ti ń lo ìjọba ’Islām, ìdájọ́ ikú ni ọ̀ràn tí wọ́n dá, àfi tí wọ́n bá tètè ronú pìwàdà. Ẹ tún ka ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-’Ahzāb; 33:40.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (75) Capítulo: Sura Al-Hayy
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar