Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (5) Capítulo: Sura Al-Ahzaab
ٱدۡعُوهُمۡ لِأٓبَآئِهِمۡ هُوَ أَقۡسَطُ عِندَ ٱللَّهِۚ فَإِن لَّمۡ تَعۡلَمُوٓاْ ءَابَآءَهُمۡ فَإِخۡوَٰنُكُمۡ فِي ٱلدِّينِ وَمَوَٰلِيكُمۡۚ وَلَيۡسَ عَلَيۡكُمۡ جُنَاحٞ فِيمَآ أَخۡطَأۡتُم بِهِۦ وَلَٰكِن مَّا تَعَمَّدَتۡ قُلُوبُكُمۡۚ وَكَانَ ٱللَّهُ غَفُورٗا رَّحِيمًا
Ẹ pè wọ́n pẹ̀lú orúkọ bàbá wọn. Òhun l’ó ṣe déédé jùlọ lọ́dọ̀ Allāhu, ṣùgbọ́n tí ẹ kò bá mọ (orúkọ) bàbá wọn, ọmọ ìyá yín nínú ẹ̀sìn àti ẹrú yín kúkú ni wọ́n.¹ Kò sí ẹ̀ṣẹ̀ fún yín níbi ohun tí ẹ ti ṣàṣìṣe, ṣùgbọ́n (ẹ̀ṣẹ̀ wà níbi) ohun tí ọkàn yín mọ̀ọ́mọ̀ ṣe. Allāhu sì ń jẹ́ Aláforíjìn, Àṣàkẹ́-ọ̀run.
1. Àṣẹ pípe ẹrú pẹ̀lú orúkọ bàbá rẹ̀, tí fífi orúkọ olówó-ẹrú pe ẹrú kò sì dára, èyí ti fi hàn kedere pé, kò lẹ́tọ̀ọ́ fún obìnrin láti fi orúkọ ọkọ rẹ̀ pààrọ̀ orúkọ bàbá rẹ̀. Àṣà àwọn aláìgbàgbọ́ ni àṣà fífi orúkọ ọkọ pààrọ̀ orúkọ bàbá. Yàtọ̀ sí pé, àṣà náà jẹ́ àṣà àwọn aláìgbàgbọ́, ó tún jẹ́ àbòsí láti ọ̀dọ̀ ọmọ sí bàbá rẹ̀ nítorí pé, òfin tó ní kí ọkùnrin máa jẹ́ orúkọ bàbá rẹ lọ, ìbáà di ọkọ ìyàwó, òfin yìí náà l’ó ní kí ọmọbìnrin máa jẹ́ orúkọ bàbá rẹ̀ lọ, ìbáà di ìyàwó. Nítorí náà, yálà kí obìnrin dárúkọ ara rẹ̀ báyìí “lágbájá ọmọ lámọrín” tàbí kí ó sọ pé “lágbájá aya tàmẹ̀dùn”. Àgbékalẹ̀ orúkọ rẹ̀ gbọ́dọ̀ ṣàfi hàn ìbátan tó wà láààrin orúkọ rẹ̀ àti orúkọ ọkùnrin tó pè mọ́ra rẹ̀. Wọn kò sì gbọ́dọ̀ dárúkọ ọkọ nìkan láti fi pe ìyàwó, gẹ́gẹ́ bí wọ́n kò ṣe gbọ́dọ̀ dárúkọ bàbá nìkan láti fi pe ọmọ. Ẹ pe ẹnì kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú orúkọ rẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (5) Capítulo: Sura Al-Ahzaab
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar