Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (15) Capítulo: Sura Al-Nisaa
وَٱلَّٰتِي يَأۡتِينَ ٱلۡفَٰحِشَةَ مِن نِّسَآئِكُمۡ فَٱسۡتَشۡهِدُواْ عَلَيۡهِنَّ أَرۡبَعَةٗ مِّنكُمۡۖ فَإِن شَهِدُواْ فَأَمۡسِكُوهُنَّ فِي ٱلۡبُيُوتِ حَتَّىٰ يَتَوَفَّىٰهُنَّ ٱلۡمَوۡتُ أَوۡ يَجۡعَلَ ٱللَّهُ لَهُنَّ سَبِيلٗا
Àwọn tó ń ṣe sìná nínú àwọn obìnrin yín, ẹ wá ẹlẹ́rìí mẹ́rin nínú yín tí ó máa jẹ́rìí lé wọn lórí. Tí wọ́n bá jẹ́rìí lé wọn lórí, kí ẹ dè wọ́n mọ́ inú ilé títí ikú yóò fi pa wọ́n tàbí (títí) Allāhu yóò fi gbé ọ̀nà (ìjìyà) kan kalẹ̀ fún wọn.¹
1. Èyí ni òfin àkọ́kọ́ lórí ìdíyàjẹ onísìná obìnrin tó ti ní yìgì lórí rí. Lẹ́yìn náà, òfin lílẹ onísìná lókò pa dé lórí ẹni tí ó bá ṣe sìná lẹ́yìn tí ó ti ṣe nikāh rí, yálà obìnrin tàbí ọkùnrin. Èyí sì ni ọ̀nà mìíràn tí Allāhu mú wá lórí ahọ́n Òjíṣẹ́ Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -. Òfin àkọ́kọ́ yẹn “títi onísìná adélébọ̀ àti abilékọ obìnrin mọ́nú ilé d’ọjọ́ ikú” ni àwọn kògbédè-ó-gbékèé ń lò fún ẹ̀há (hijāb) àwọn obìnrin mùsùlùmí. Ọ̀rọ̀ kò sì rí bẹ́ẹ̀. Ọ̀tọ̀ ni āyah ìdíyàjẹ onísìná bíi tinú sūrah an-Nūr; 24:2, ọ̀tọ̀ sì ni āyah ẹ̀há (hijāb) bíi tinú sūrah an-Nūr; 24:31 àti sūrah al-’Ahzāb; 33:59.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (15) Capítulo: Sura Al-Nisaa
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar