Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (40) Capítulo: Sura Ghafir
مَنۡ عَمِلَ سَيِّئَةٗ فَلَا يُجۡزَىٰٓ إِلَّا مِثۡلَهَاۖ وَمَنۡ عَمِلَ صَٰلِحٗا مِّن ذَكَرٍ أَوۡ أُنثَىٰ وَهُوَ مُؤۡمِنٞ فَأُوْلَٰٓئِكَ يَدۡخُلُونَ ٱلۡجَنَّةَ يُرۡزَقُونَ فِيهَا بِغَيۡرِ حِسَابٖ
Ẹni tí ó bá ṣe aburú kan, Wọn kò níí san án ní ẹ̀san kan àyàfi irú rẹ̀. Ẹni tí ó bá sì ṣe iṣẹ́ rere ní ọkùnrin tàbí ní obìnrin, tí ó sì jẹ́ onígbàgbọ́ òdodo,¹ àwọn wọ̀nyẹn ni wọ́n máa wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Wọn yóò máa pèsè ìjẹ-ìmu àti ìgbádùn fún wọn nínú rẹ̀ láì níí ní ìṣírò.²
1. Kíyè sí gbólóhùn yìí dáradára “tí ó sì jẹ́ onígbàgbọ́ òdodo”. Ó ń túmọ̀ sí pé, èyíkéyìí iṣẹ́ rere tí Ànábì kan bá mú wá fún ìjọ rẹ̀, bí ẹni tí kò bá ní ìgbàgbọ́ òdodo ’Islām bá ṣe iṣẹ́ rere náà fún gbogbo ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀, Allāhu kò níí gbà á lọ́wọ́ rẹ̀. Nítorí náà, májẹ̀mu kan lọ́tọ̀ ni ìgbàgbọ́ òdodo ’Islām jẹ́ lórí ṣíṣe iṣẹ́ rere.
2. Ìyẹn ni pé, ẹ̀san rere tó máa jẹ́ àwọn ìjẹ-ìmu àti àwọn ìgbádùn oníran-ànran ní ọ̀run fún àwọn olùṣe-rere máa pọ̀ gan-an jaburata. Ẹ tún wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:212.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (40) Capítulo: Sura Ghafir
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar