Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (81) Capítulo: Sura Ghafir
وَيُرِيكُمۡ ءَايَٰتِهِۦ فَأَيَّ ءَايَٰتِ ٱللَّهِ تُنكِرُونَ
(Allāhu) ń fi àwọn àmì Rẹ̀ hàn yín. Nítorí náà, èwo nínú àwọn àmì Allāhu l’ẹ máa takò?¹
1. Kíyè sí i! Àwọn asòòkùn sẹ́sìn àti àwọn onibidiah yóò máa pe iṣẹ́ aburú ọwọ́ wọn nípasẹ̀ idán pípa àti bidiah ṣíṣe ní “àmì Allāhu” láti lè ṣi àwọn ènìyàn lọ́nà. Kíyè sí i, ohunkóhun tí ó bá máa jẹ́ “àmì Allāhu / àmì Ọlọ́hun” kò níí fi ọ̀nà kan kan lòdì sí “āyah” kan kan nínú al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé nítorí pé, àwọn āyah al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé ni òṣùwọ̀n ìdáláre àti ìdálẹ́bi fún ohun tí ẹnikẹ́ni bá pè ní “àmì Ọlọ́hun”. Kódà, ohunkóhun tí ó bá máa jẹ́ “àmì Allāhu” kò níí fi ọ̀nà kan kan lòdì sí hadīth kan nínú àwọn hadīth Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - tó fẹsẹ̀ rinlẹ̀.
Síwájú sí i, ọ̀tọ̀ ni pàápàá bíbẹ Allāhu - tó ga jùlọ -, ọ̀tọ̀ ni “àmì Ọlọ́hun”. Ẹlẹ́dàá ni Allāhu. Àmì Ọlọ́hun sì ń túmọ̀ sí ẹ̀dá Ọlọ́hun tàbí ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun gẹ́gẹ́ bí āyah al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé. Nítorí náà, àmì Ọlọ́hun ni a lè fojú rí nílé ayé yìí, kì í ṣe pàápàá bíbẹ Allāhu. Ẹni tí ó rí àmì Ọlọ́hun, kò rí Ọlọ́hun. Wallāhu ’a‘lam.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (81) Capítulo: Sura Ghafir
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar