Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Capítulo: Sura Al-Mursalaa   Versículo:

Suuratul-Mur'salaat

وَٱلۡمُرۡسَلَٰتِ عُرۡفٗا
Allāhu fi àwọn atẹ́gùn tó ń sáré ní tẹ̀léǹtẹ̀lé búra.
Las Exégesis Árabes:
فَٱلۡعَٰصِفَٰتِ عَصۡفٗا
Ó fi àwọn ìjì atẹ́gùn tó ń jà búra.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلنَّٰشِرَٰتِ نَشۡرٗا
Ó fi àwọn atẹ́gùn tó ń tú èṣújò ká búra.
Las Exégesis Árabes:
فَٱلۡفَٰرِقَٰتِ فَرۡقٗا
Ó fi àwọn tó ń ṣèpínyà láààrin òdodo àti irọ́ búra.
Las Exégesis Árabes:
فَٱلۡمُلۡقِيَٰتِ ذِكۡرًا
Ó fi àwọn mọlāika tó ń mú ìrántí wá (bá àwọn Òjíṣẹ́) búra.
Las Exégesis Árabes:
عُذۡرًا أَوۡ نُذۡرًا
(Ìrántí náà jẹ́) àwíjàre tàbí ìkìlọ̀.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّمَا تُوعَدُونَ لَوَٰقِعٞ
Dájúdájú ohun tí A ṣe ní àdéhùn fún yín kúkú máa ṣẹlẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
فَإِذَا ٱلنُّجُومُ طُمِسَتۡ
Nítorí náà, nígbà tí wọ́n bá pa (ìmọ́lẹ̀) ìràwọ̀ rẹ́,
Las Exégesis Árabes:
وَإِذَا ٱلسَّمَآءُ فُرِجَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ṣí sánmọ̀ sílẹ̀ gbagada,
Las Exégesis Árabes:
وَإِذَا ٱلۡجِبَالُ نُسِفَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ku àwọn àpáta dànù,
Las Exégesis Árabes:
وَإِذَا ٱلرُّسُلُ أُقِّتَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá fún àwọn Òjíṣẹ́ ní àsìkò láti kójọ (pẹ̀lú ìjọ wọn),
Las Exégesis Árabes:
لِأَيِّ يَوۡمٍ أُجِّلَتۡ
ọjọ́ wo ni wọ́n so (àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí) rọ̀ fún ná?
Las Exégesis Árabes:
لِيَوۡمِ ٱلۡفَصۡلِ
Fún ọjọ́ ìpínyà (láààrin àwọn ẹ̀dá) ni.
Las Exégesis Árabes:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا يَوۡمُ ٱلۡفَصۡلِ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ìpínyà?
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
أَلَمۡ نُهۡلِكِ ٱلۡأَوَّلِينَ
Ǹjẹ́ Àwa kò ti pa àwọn ẹni àkọ́kọ́ rẹ́ bí?
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ نُتۡبِعُهُمُ ٱلۡأٓخِرِينَ
Lẹ́yìn náà, A sì máa fi àwọn ẹni Ìkẹ́yìn tẹ̀lé wọn (nínú ìparun).
Las Exégesis Árabes:
كَذَٰلِكَ نَفۡعَلُ بِٱلۡمُجۡرِمِينَ
Báyẹn ni A ó ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
أَلَمۡ نَخۡلُقكُّم مِّن مَّآءٖ مَّهِينٖ
Ṣé A kò ṣẹ̀dá yin láti inú omi lílẹ yẹpẹrẹ bí?
Las Exégesis Árabes:
فَجَعَلۡنَٰهُ فِي قَرَارٖ مَّكِينٍ
Lẹ́yìn náà, A fi sínú àyè ààbò (ìyẹn, ilé-ọmọ)
Las Exégesis Árabes:
إِلَىٰ قَدَرٖ مَّعۡلُومٖ
títí di gbèdéke àkókò kan tí A ti mọ̀ (ìyen, ọjọ́ ìbímọ).
Las Exégesis Árabes:
فَقَدَرۡنَا فَنِعۡمَ ٱلۡقَٰدِرُونَ
A sì ní ìkápá àti àyànmọ́ (lórí rẹ̀. Àwa sì ni) Olùkápá àti Olùpèbùbù ẹ̀dá tó dára.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
أَلَمۡ نَجۡعَلِ ٱلۡأَرۡضَ كِفَاتًا
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ohun tó ń kó ẹ̀dá jọ mọ́ra wọn;
Las Exégesis Árabes:
أَحۡيَآءٗ وَأَمۡوَٰتٗا
(ìyẹn) àwọn alààyè àti àwọn òkú?
Las Exégesis Árabes:
وَجَعَلۡنَا فِيهَا رَوَٰسِيَ شَٰمِخَٰتٖ وَأَسۡقَيۡنَٰكُم مَّآءٗ فُرَاتٗا
A sì fi àwọn àpáta gbagidi gíga-gíga sínú rẹ̀. A sì fún yín ní omi dídùn mu.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
ٱنطَلِقُوٓاْ إِلَىٰ مَا كُنتُم بِهِۦ تُكَذِّبُونَ
Ẹ máa lọ sí ibi tí ẹ̀ ń pè ní irọ́.
Las Exégesis Árabes:
ٱنطَلِقُوٓاْ إِلَىٰ ظِلّٖ ذِي ثَلَٰثِ شُعَبٖ
Ẹ máa lọ sí ibi èéfín ẹlẹ́ka mẹ́ta.
Las Exégesis Árabes:
لَّا ظَلِيلٖ وَلَا يُغۡنِي مِنَ ٱللَّهَبِ
Kì í ṣe ibòji tútù. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ìjòfòfò Iná.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّهَا تَرۡمِي بِشَرَرٖ كَٱلۡقَصۡرِ
Dájúdájú (Iná náà) yóò máa ju ẹ̀tapàrà (rẹ̀ sókè tó máa dà) bí pẹ̀tẹ́ẹ̀sì.
Las Exégesis Árabes:
كَأَنَّهُۥ جِمَٰلَتٞ صُفۡرٞ
(Ó máa dà) bí àwọn ràkúnmí aláwọ̀ omi ọsàn.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́
Las Exégesis Árabes:
هَٰذَا يَوۡمُ لَا يَنطِقُونَ
Èyí ni ọjọ́ tí wọn kò níí sọ̀rọ̀.
Las Exégesis Árabes:
وَلَا يُؤۡذَنُ لَهُمۡ فَيَعۡتَذِرُونَ
A kò sì níí yọ̀ǹda (ọ̀rọ̀ sísọ) fún wọn, áḿbọ̀sìbọ́sí pé wọ́n yóò mú àwáwí wá.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
هَٰذَا يَوۡمُ ٱلۡفَصۡلِۖ جَمَعۡنَٰكُمۡ وَٱلۡأَوَّلِينَ
Èyí ni ọjọ́ ìpínyà. Àwa yó sì kó ẹ̀yin àti àwọn ẹni àkọ́kọ́ jọ.
Las Exégesis Árabes:
فَإِن كَانَ لَكُمۡ كَيۡدٞ فَكِيدُونِ
Tí ẹ bá ní ète kan lọ́wọ́, ẹ déte sí Mi wò.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّ ٱلۡمُتَّقِينَ فِي ظِلَٰلٖ وَعُيُونٖ
Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù Allāhu yóò wà níbi ibòji àti àwọn omi ìṣẹ́lẹ̀rú,
Las Exégesis Árabes:
وَفَوَٰكِهَ مِمَّا يَشۡتَهُونَ
àti àwọn èso èyí tí wọ́n bá ń fẹ́.
Las Exégesis Árabes:
كُلُواْ وَٱشۡرَبُواْ هَنِيٓـَٔۢا بِمَا كُنتُمۡ تَعۡمَلُونَ
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbádùn nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّا كَذَٰلِكَ نَجۡزِي ٱلۡمُحۡسِنِينَ
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
كُلُواْ وَتَمَتَّعُواْ قَلِيلًا إِنَّكُم مُّجۡرِمُونَ
Ẹ jẹ, kí ẹ sì gbádùn fún ìgbà díẹ̀. Dájúdájú ẹlẹ́ṣẹ̀ ni yín.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
وَإِذَا قِيلَ لَهُمُ ٱرۡكَعُواْ لَا يَرۡكَعُونَ
Nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé kí wọ́n kírun, wọn kò níí kírun.
Las Exégesis Árabes:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Las Exégesis Árabes:
فَبِأَيِّ حَدِيثِۭ بَعۡدَهُۥ يُؤۡمِنُونَ
Nígbà náà, ọ̀rọ̀ wo ni wọn yóò gbàgbọ́ lẹ́yìn rẹ̀?¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:185.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Capítulo: Sura Al-Mursalaa
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar