Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (108) Capítulo: Sura Al-Tawba
لَا تَقُمۡ فِيهِ أَبَدٗاۚ لَّمَسۡجِدٌ أُسِّسَ عَلَى ٱلتَّقۡوَىٰ مِنۡ أَوَّلِ يَوۡمٍ أَحَقُّ أَن تَقُومَ فِيهِۚ فِيهِ رِجَالٞ يُحِبُّونَ أَن يَتَطَهَّرُواْۚ وَٱللَّهُ يُحِبُّ ٱلۡمُطَّهِّرِينَ
Má ṣe dúró (kírun) nínú rẹ̀ láéláé.¹ Dájúdájú mọ́sálásí tí wọ́n bá fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí ìbẹ̀rù Allāhu láti ọjọ́ àkọ́kọ́ lo lẹ́tọ̀ọ́ jùlọ pé kí o dúró (kírun) nínú rẹ̀. Àwọn ènìyàn tó nífẹ̀ẹ́ láti máa ṣe ìmọ́ra wà nínú rẹ̀. Allāhu sì fẹ́ràn àwọn olùṣèmọ́ra.
1. Kíyè sí i! Gbólóhùn yìí “Má ṣe dúró (kírun) nínú rẹ̀ láéláé.” àti āyah 107 ló ń ṣe é ní èèwọ̀ fún àwa mùsùlùmí onisunnah láti kírun nínú àwọn mọ́sálásí àwọn mùsùlùmí onibidiah pẹ̀lú májẹ̀mu pé tí ó bá jẹ́ pé wọ́n fi mọ́sálásí náà sọrí bid‘ah wọn. Irú àwọn mọ́sálásí tí èyí kàn ni mọ́sálásí Ahmadiyyah àti Zāwiyah àwọn oníwírìdí Tijāniyah, Ƙọ̄diriyyah àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Tí ó bá wá jẹ́ pé wọn kò fi mọ́sálásí sọrí bid‘ah, àmọ́ tí wọ́n fi imām ẹlẹ́sìn Ahmadiyyah tàbí ẹlẹ́sìn Tijāniyyah tàbí Ƙọ̄diriyyah ṣe imām nínú mọ́sálásí náà, mùsùlùmí lè kírun nínú mọ́sálásí náà kò kàn níí kírun lẹ́yìn imām onibid'ah yẹn ni.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (108) Capítulo: Sura Al-Tawba
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar