Traduzione dei Significati del Sacro Corano - Traduzione in yoruba * - Indice Traduzioni

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduzione dei significati Sura: Al-Mutaffifîn   Versetto:

Suuratul-Mutoffifiin

وَيۡلٞ لِّلۡمُطَفِّفِينَ
Ègbé ni fún àwọn olùdín-òṣùwọ̀n-kù,
Esegesi in lingua araba:
ٱلَّذِينَ إِذَا ٱكۡتَالُواْ عَلَى ٱلنَّاسِ يَسۡتَوۡفُونَ
àwọn (òǹtajà) tó jẹ́ pé nígbà tí wọ́n bá wọn n̄ǹkan lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn,¹ wọ́n á gbà á ní ẹ̀kún,
1. “Àwọn ènìyàn” ní àyè yìí dúró fún bíi “ àwọn olóko”.
Esegesi in lingua araba:
وَإِذَا كَالُوهُمۡ أَو وَّزَنُوهُمۡ يُخۡسِرُونَ
nígbà tí àwọn (òǹtajà náà) bá sì lo ìwọ̀n fún àwọn (òǹrajà) tàbí lo òṣùwọ̀n fún wọn, wọn yóò dín in kù.
Esegesi in lingua araba:
أَلَا يَظُنُّ أُوْلَٰٓئِكَ أَنَّهُم مَّبۡعُوثُونَ
Ṣé àwọn wọ̀nyẹn kò mọ̀ dájú pé dájúdájú A máa gbé wọn dìde
Esegesi in lingua araba:
لِيَوۡمٍ عَظِيمٖ
ní Ọjọ́ ńlá kan?
Esegesi in lingua araba:
يَوۡمَ يَقُومُ ٱلنَّاسُ لِرَبِّ ٱلۡعَٰلَمِينَ
Ní ọjọ́ tí àwọn ènìyàn yóò dìde dúró fún Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
Esegesi in lingua araba:
كَلَّآ إِنَّ كِتَٰبَ ٱلۡفُجَّارِ لَفِي سِجِّينٖ
Ní ti òdodo dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni burúkú (tó ń dín òṣùwọ̀n kù) kúkú máa wà nínú Sijjīn.
Esegesi in lingua araba:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا سِجِّينٞ
Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Sijjīn!
Esegesi in lingua araba:
كِتَٰبٞ مَّرۡقُومٞ
Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ aburú ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sínú ilẹ̀ keje ni Sijjīn).
Esegesi in lingua araba:
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ní ọjọ́ yẹn, ègbé ni fún àwọn olùpe-òdodo- nírọ́,
Esegesi in lingua araba:
ٱلَّذِينَ يُكَذِّبُونَ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
àwọn tó ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́.
Esegesi in lingua araba:
وَمَا يُكَذِّبُ بِهِۦٓ إِلَّا كُلُّ مُعۡتَدٍ أَثِيمٍ
Kò sì sí ẹni tó ń pè é ní irọ́ àyàfi gbogbo alákọyọ, ẹlẹ́ṣẹ̀.
Esegesi in lingua araba:
إِذَا تُتۡلَىٰ عَلَيۡهِ ءَايَٰتُنَا قَالَ أَسَٰطِيرُ ٱلۡأَوَّلِينَ
Nígbà tí wọ́n bá ń ké àwọn āyah Wa fún un, ó máa wí pé: “Àwọn àkọsílẹ̀ àlọ́ àwọn ẹni àkọ́kọ́ (nìwọ̀nyí).”
Esegesi in lingua araba:
كَلَّاۖ بَلۡۜ رَانَ عَلَىٰ قُلُوبِهِم مَّا كَانُواْ يَكۡسِبُونَ
Rárá (al-Ƙur’ān kì í ṣe àkọsílẹ̀ àlọ́ àwọn ẹni àkọ́kọ́) bí kò ṣe pé ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́ aburú l’ó jọba lórí ọkàn wọn.
Esegesi in lingua araba:
كَلَّآ إِنَّهُمۡ عَن رَّبِّهِمۡ يَوۡمَئِذٖ لَّمَحۡجُوبُونَ
Rárá (kò rí bí wọ́n ṣe rò ó sí sẹ́), dájúdájú wọn yóò wà nínú gàgá, wọn kò sì níí rí Olúwa wọn ní ọjọ́ yẹn.
Esegesi in lingua araba:
ثُمَّ إِنَّهُمۡ لَصَالُواْ ٱلۡجَحِيمِ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú wọn yóò wọ inú iná Jẹhīm.
Esegesi in lingua araba:
ثُمَّ يُقَالُ هَٰذَا ٱلَّذِي كُنتُم بِهِۦ تُكَذِّبُونَ
Lẹ́yìn náà, wọ́n máa sọ (fún wọn) pe: “Èyí ni ohun tí ẹ̀ ń pè ní irọ́.”
Esegesi in lingua araba:
كَلَّآ إِنَّ كِتَٰبَ ٱلۡأَبۡرَارِ لَفِي عِلِّيِّينَ
Ní ti òdodo, dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni rere wà nínú ‘illiyyūn.
Esegesi in lingua araba:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا عِلِّيُّونَ
Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ‘illiyyūn!
Esegesi in lingua araba:
كِتَٰبٞ مَّرۡقُومٞ
Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ rere ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sí òkè sánmọ̀ ni ‘illiyyūn).
Esegesi in lingua araba:
يَشۡهَدُهُ ٱلۡمُقَرَّبُونَ
Àwọn (mọlāika) tí wọ́n súnmọ́ Allāhu ń jẹ́rìí sí i.
Esegesi in lingua araba:
إِنَّ ٱلۡأَبۡرَارَ لَفِي نَعِيمٍ
Dájúdájú àwọn ẹni rere máa wà nínú ìgbádùn.
Esegesi in lingua araba:
عَلَى ٱلۡأَرَآئِكِ يَنظُرُونَ
Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
Esegesi in lingua araba:
تَعۡرِفُ فِي وُجُوهِهِمۡ نَضۡرَةَ ٱلنَّعِيمِ
Ìwọ yóò dá ìtutù ojú ìgbádùn mọ̀ nínú ojú wọn.
Esegesi in lingua araba:
يُسۡقَوۡنَ مِن رَّحِيقٖ مَّخۡتُومٍ
Wọn yóò máa fún wọn mu nínú ọtí onídèérí.
Esegesi in lingua araba:
خِتَٰمُهُۥ مِسۡكٞۚ وَفِي ذَٰلِكَ فَلۡيَتَنَافَسِ ٱلۡمُتَنَٰفِسُونَ
Àlùmísìkí ni (òórùn) ìparí rẹ̀. Kí àwọn alápàáǹtètè ṣàpáǹtètè nínú ìyẹn.
Esegesi in lingua araba:
وَمِزَاجُهُۥ مِن تَسۡنِيمٍ
Tẹsnīm ni wọ́n yóò máa pòpọ̀ (mọ́ ọtí náà).
Esegesi in lingua araba:
عَيۡنٗا يَشۡرَبُ بِهَا ٱلۡمُقَرَّبُونَ
(Tẹsnīm ni) omi ìṣẹ́lẹ̀rú kan, tí àwọn olùsúnmọ́ (Allāhu) yóò máa mu.
Esegesi in lingua araba:
إِنَّ ٱلَّذِينَ أَجۡرَمُواْ كَانُواْ مِنَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ يَضۡحَكُونَ
Dájúdájú àwọn tó dẹ́ṣẹ̀, wọ́n máa ń fi àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo rẹ́rìn-ín.
Esegesi in lingua araba:
وَإِذَا مَرُّواْ بِهِمۡ يَتَغَامَزُونَ
Nígbà tí wọ́n bá gba ẹ̀gbẹ́ wọn kọjá, (àwọn olùdẹ́ṣẹ̀) yóò máa ṣẹ́jú síra wọn ní ti yẹ̀yẹ́.
Esegesi in lingua araba:
وَإِذَا ٱنقَلَبُوٓاْ إِلَىٰٓ أَهۡلِهِمُ ٱنقَلَبُواْ فَكِهِينَ
Nígbà tí wọ́n bá sì padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wọn, wọ́n á padà tí wọn yóò máa ṣe fáàrí.
Esegesi in lingua araba:
وَإِذَا رَأَوۡهُمۡ قَالُوٓاْ إِنَّ هَٰٓؤُلَآءِ لَضَآلُّونَ
Àti pé nígbà tí wọ́n bá rí (àwọn onígbàgbọ́ òdodo) wọ́n á wí pé: “Dájúdájú àwọn wọ̀nyí ni olùṣìnà.”
Esegesi in lingua araba:
وَمَآ أُرۡسِلُواْ عَلَيۡهِمۡ حَٰفِظِينَ
Àwa kò sì rán wọn ní iṣẹ́ olùṣọ́ sí wọn.
Esegesi in lingua araba:
فَٱلۡيَوۡمَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ مِنَ ٱلۡكُفَّارِ يَضۡحَكُونَ
Nítorí náà, ní òní àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo yóò fi àwọn aláìgbàgbọ́ rẹ́rìn-ín.
Esegesi in lingua araba:
عَلَى ٱلۡأَرَآئِكِ يَنظُرُونَ
Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
Esegesi in lingua araba:
هَلۡ ثُوِّبَ ٱلۡكُفَّارُ مَا كَانُواْ يَفۡعَلُونَ
Ṣebí wọ́n ti fi ohun tí àwọn aláìgbàgbọ́ ń ṣe níṣẹ́ san wọ́n lẹ́san (báyìí)?
Esegesi in lingua araba:
 
Traduzione dei significati Sura: Al-Mutaffifîn
Indice delle Sure Numero di pagina
 
Traduzione dei Significati del Sacro Corano - Traduzione in yoruba - Indice Traduzioni

Traduzione dei significati del Nobile Corano in yoruba, di Shaikh Abu Rahima Mika'il 'Aikweiny, ed. 1432 H.

Chiudi