1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al Baƙọrah; 2:1.
2.Pípe al-Ƙur’ān ní “hakīm” lè túmọ̀ sí n̄ǹkan mẹ́ta. Ìkíní: Bí ó bá jẹ́ pé láti ara “hikmọh” ni wọ́n ti ṣẹ̀dá “hakīm”, ó máa túmọ̀ sí “thū hikmọh” tírà tí ó kún fún ọgbọ́n. Ìkejì: Bí ó bá jẹ́ pé láti ara “hukm” ni wọ́n ti ṣẹ̀dá “hakīm”, ó máa túmọ̀ sí “hākim” tírà tí ó ń ṣe ìdájọ́. Ìkẹta: Bí ó bá jẹ́ pé láti ara “’ihkām” ni wọ́n ti ṣẹ̀dá “hakīm”, ó máa túmọ̀ sí “muhkam” tírà tí wọ́n to àwọn āyah rẹ̀ àti sūrah rẹ̀ tó gún régé láì sí ìdàrúdàpọ̀ àti ìtakora kan nínú rẹ̀.
Àdúà wọn nínú rẹ̀ ni “mímọ́ ni fún Ọ, Allāhu”. Ìkíni wọn nínú rẹ̀ ni “àlàáfíà”. Ìparí àdúà wọn sì ni pé, “Gbogbo ẹyìn ń jẹ́ ti Allāhu,¹ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.”
A kúkú ti pa àwọn ìran kan rẹ́ ṣíwájú yín nígbà tí wọ́n ṣe àbòsí. Àwọn Òjíṣẹ́ wọn mú àwọn ẹ̀rí tó yanjú wá bá wọn. Wọn kò sì gbàgbọ́. Báyẹn ni A ṣe ń san ìjọ ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ẹ̀san.
Wọ́n ń jọ́sìn fún ohun tí kò lè kó ìnira bá wọn, tí kò sì lè ṣe wọ́n ní àǹfààní lẹ́yìn Allāhu. Wọ́n sì ń wí pé: “Àwọn wọ̀nyí ni olùṣìpẹ̀ wa lọ́dọ̀ Allāhu.” Sọ pé: “Ṣé ẹ máa fún Allāhu ní ìró ohun tí kò mọ̀ nínú àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀ ni?” Mímọ́ ni fún Un, Ó ga tayọ n̄ǹkan tí wọ́n ń fi ṣẹbọ sí I.
Kí ni àwọn ènìyàn jẹ́ (ní ìpìlẹ̀) bí kò ṣe ìjọ ẹyọ kan (ìjọ ’Islām). Lẹ́yìn náà ni wọ́n yapa-ẹnu. Tí kò bá jẹ́ pé ọ̀rọ̀ kan tó ti ṣíwájú lọ́dọ̀ Olúwa rẹ, Àwa ìbá ti yanjú ohun tí wọ́n ń yapa-ẹnu lórí rẹ̀ láààrin ara wọn.
Àpèjúwe ìṣẹ̀mí ayé dà bí omi kan tí A sọ̀kalẹ̀ láti sánmọ̀, tí àwọn irúgbìn nínú ohun tí ènìyàn àti àwọn ẹran-ọ̀sìn ń jẹ sì gbà á sára, títí di ìgbà tí ilẹ̀ yóò fi lọ́ràá. Ó sì mú ọ̀ṣọ́ (ara) rẹ̀ jáde. Àwọn tó ni ín sì lérò pé àwọn ni alágbára lórí rẹ̀, (nígbà náà ni) àṣẹ Wa dé bá a ní òru tàbí ní ọ̀sán. A sì sọ ọ́ di oko tí wọ́n fà tu dànù bí ẹni pé kò sí níbẹ̀ rárá rí ní àná. Báyẹn ni A ṣe ń ṣàlàyé àwọn āyah fún ìjọ aláròjinlẹ̀.
Àwọn tó sì ṣ’iṣẹ́ aburú, ẹ̀san aburú bí irú rẹ̀ (ni ẹ̀san wọn). Ìyẹpẹrẹ sì máa bò wọ́n mọ́lẹ̀. Kò sí aláàbò kan fún wọn lọ́dọ̀ Allāhu. (Wọ́n máa dà bí) ẹni pé wọ́n fi apá kan òru tó ṣókùnkùn bò wọ́n lójú pa. Àwọn wọ̀nyẹn ni èrò inú Iná. Olùṣegbére ni wọ́n nínú rẹ̀.
Níbẹ̀ yẹn, ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan máa dá ohun tó ṣe síwájú mọ̀. Wọn yó sì da wọ́n padà sọ́dọ̀ Allāhu Olúwa wọn Òdodo. Ohun tí wọ́n ń dá ní àdápa irọ́ sì di òfo mọ́ wọn lọ́wọ́.¹
Ìyẹn ni Allāhu Olúwa yín Òdodo. Kí sì ni ó ń bẹ lẹ́yìn Òdodo bí kò ṣe ìṣìnà? Nítorí náà, báwo ni wọ́n ṣe ń ṣẹ́rí yín kúrò níbi òdodo?
Ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ wọn kò sì rí kiní kan tẹ̀lé bí kò ṣe àròsọ. Dájúdájú àbá dídá kò sì lè rọrọ̀ kiní kan níwájú òdodo. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀ nípa ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
Kò rí bẹ́è, wọ́n pe ohun tí wọn kò ní ìmọ̀ rẹ̀ nírọ́ ni. Àti pé ìmúṣẹ ọ̀rọ̀ Rẹ̀ kò tí ì dé bá wọn (ni wọ́n fi pè é nírọ́). Báyẹn ni àwọn tó ṣíwájú wọn ṣe pe (ọ̀rọ̀ Allāhu) nírọ́. Nítorí náà, wo bí àtubọ̀tán àwọn alábòsí ṣe rí.
Àti pé (rántí) Ọjọ́ tí (Allāhu) yóò kó wọn jọ àfi bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé ju àkókò kan nínú ọ̀sán. Wọn yó sì dára wọn mọ̀. Dájúdájú àwọn tó pe ìpàdé Allāhu nírọ́ ti ṣòfò; wọn kò sì jẹ́ olùmọ̀nà.
Ó ṣeé ṣe kí A fi apá kan èyí tí A ṣe ní ìlérí fún wọn hàn ọ́ tàbí kí A ti gba ẹ̀mí rẹ (ṣíwájú àsìkò náà), ọ̀dọ̀ Wa kúkú ni ibùpadàsí wọn. Lẹ́yìn náà, Allāhu ni Arínú-róde ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
Òjíṣẹ́ ti wà fún ìjọ kọ̀ọ̀kan.¹ Nítorí náà, nígbà tí Òjíṣẹ́ wọn bá dé, A óò ṣèdájọ́ láààrin wọn pẹ̀lú déédé; A ò sì níí ṣàbòsí sí wọn.
1. Āyah yìí àti tinú sūrah Fātir; 35:24 jẹ́ ọ̀kan nínú ọ̀nà tí ìjọ Ahmadiyyah gbà di kèfèrí. Ìdí ni pé, nítorí àwọn āyah wọ̀nyẹn ni ìjọ náà fi pe gbogbo òrìṣà ní ànábì Ọlọ́hun, àti pé wọ́n gbàgbọ́ pé kò sí ìlú tí Allāhu kò ti gbé òjíṣẹ́ kọ̀ọ̀kan dìde, títí dé ilẹ̀ Yorùbá, ilẹ̀ Haúsá, ilẹ̀ Yíbò àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ìtọ́kasí wọn nìyí: “In pursuance of this doctrine, he (mirza Ghulam Ahmad al-Ƙadiyyaaniy) testified to the truth of Krishna, Ram Chandra and Buddha, the prophets of India, and Zoroaster, the prophet of Persia, and described the rejection of their claims as, in a sense, amounting to a denial of the universal Providence of God.” Ìtúmọ̀ “Láti lè tẹ̀lé ìgbàgbọ́ yìí ló mú kí mirza Ghulam Ahmad jẹ́rìí pé òdodo ni òrìṣà Krishna, òrìṣà Ram Chandra àti òrìṣà Buda, tí wọ́n jẹ́ àwọn ànábì ilẹ̀ India. Àti òrìṣà Zoroaster, tí ó jẹ́ ànábì ilẹ̀ Persia. Mirza Ghulam Ahmad sì gbà pé ẹni tí ó bá tako àwọn òrìṣà náà, ó ti tako oore tí Allāhu ṣe fún àgbáyé.” Ahmadiyyah Movement, láti ọwọ́ Bashirud-din Mahmud Ahmad, ojú ewé: 69.
Lẹ́yìn náà, A óò sọ fún àwọn tó ṣàbòsí pé: “Ẹ tọ́ ìyà gbére wò.” Ṣé A óò san yín ní ẹ̀san kan bí kò ṣe ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́?
Wọ́n sì ń bèèrè fún ìró rẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “ṣé òdodo ni?” Sọ pé: “Bẹ́ẹ̀ ni. Mo fi Olúwa mi búra. Dájúdájú òdodo ni. Ẹ̀yin kò sì níí mórí bọ́.”
Àti pé tí ó bá jẹ́ pé gbogbo n̄ǹkan tí ń bẹ lórí ilẹ̀ jẹ́ ti ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan tó ṣàbòsí, ìbá fi ṣèràpadà (fún ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi ìyà). Wọn yóò fi igbe àbámọ̀ pamọ́ nígbà tí wọ́n bá rí Ìyà. A ó ṣe ìdájọ́ láààrin wọn pẹ̀lú déédé; Wọn kò sì níí ṣàbòsí sí wọn.
Gbọ́, dájúdájú ti Allāhu ni ẹnikẹ́ni tó ń bẹ nínú àwọn sánmọ̀ àti ẹnikẹ́ni tó ń bẹ lórí ilẹ̀. Àwọn tó ń pe àwọn òrìṣà lẹ́yìn Allāhu kò (rí) akẹgbẹ́ Allāhu tẹ̀lé (torí pé, kò sí akẹgbẹ́ fún Allāhu níbìkan kan) Wọn kò tẹ̀lé (kiní kan) bí kò ṣe àbá dídá.¹ Wọn kò sì ṣe kiní kan bí kò ṣe pé wọ́n ń parọ́.
1. Fúnra wọn ni wọ́n rò wọ́n sí akẹgbẹ́ Allāhu, wọ́n dá a ní àbá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ lọ́dọ̀ ara wọn pé, “Ìwọ̀nyí ni akẹgbẹ́ fún Allāhu” Allāhu kò sì ní akẹgbẹ́. Bí àpẹ̀ẹrẹ, àwọn nasọ̄rọ̄ rò pé Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - ni “ọmọ Ọlọ́hun, ọlọ́hun ọmọ, olúwa àti olùgbàlà” Wọ́n dá a ní àbá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ́dọ̀ ara wọn. Kì í ṣe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - ló pe ara rẹ̀ bẹ́ẹ̀ fún wọn.
Nígbà náà, wọ́n pè é ní òpùrọ́. Nítorí náà, A gbà á là, òun àti àwọn tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ojú-omi. A sì ṣe wọ́n ní àrólé (lórí ilẹ̀). A sì tẹ àwọn tó pe āyah Wa nírọ́ rì sínú agbami. Nítorí náà, wo bí ìkángun àwọn ẹni-akìlọ̀-fún ṣe rí.
Lẹ́yìn náà, A gbé àwọn Òjíṣẹ́ kan dìde sí àwọn ìjọ wọn. Wọ́n sì mú àwọn ẹ̀rí tó yanjú wá bá wọn. Àwọn náà kò kúkú gbàgbọ́ nínú ohun tí (ijọ́ Ànábì Nūh) pè nírọ́ ṣíwájú (wọn, ìyẹn ni pé, irú kan-ùn ni wọ́n).¹ Báyẹn ni A ṣe ń fi èdídí bo ọkàn àwọn alákọyọ.
Lẹ́yìn náà, lẹ́yìn wọn A fi àwọn àmì Wa rán (Ànábì) Mūsā àti Hārūn níṣẹ́ sí Fir‘aon àti àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà náà, wọ́n ṣègbéraga. Wọ́n sì jẹ́ ìjọ ẹlẹ́ṣẹ̀.
Wọ́n wí pé: “Ṣé o wá bá wa nítorí kí o lè ṣẹ́rí wa kúrò níbi ohun tí a bá àwọn bàbá wa lórí rẹ̀ (nínú ìbọ̀rìṣà) àti nítorí kí títóbi sì lè jẹ́ tẹ̀yin méjèèjì lórí ilẹ̀? Àwa kò sì níí gba ẹ̀yin méjèèjì gbọ́.”
Nítorí náà, wọ́n sọ pé: “Allāhu la gbáralé. Olúwa wa, má ṣe wá ní àdánwò¹ fún ìjọ alábòsí.
1. Ìyẹn ni pé, kí Allāhu má ṣe fi ọ̀tá ẹ̀sìn wa borí wa. Tàbí àdánwò tó máa kàn wá tí àwọn ọ̀tá ẹ̀sìn wa yóò fi lérò pé a kì í ṣe ẹni Allāhu, kí Allāhu má ṣe fi kàn wá. Ìdí ni pé, àdánwò tí Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā - ń fi kan ẹ̀dá nílé ayé, kò ní n̄ǹkan kan ṣepọ̀ pẹ̀lú jíjẹ́ ẹni Ọlọ́hun tàbí àìjẹ́ ẹni Ọlọ́hun nítorí pé, Aṣèyí-ó-wùú ni Allāhu. Bí àpẹ̀ẹrẹ, ẹ wo àdánwò àìlera tí Allāhu fi kan Ànábì ’Ayyūb - kí ọlà Allāhu máa bá a -, tòhun ti bí ó ṣe jẹ́ Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun! Ànábì Yūsuf - kí ọlà Allāhu máa bá a - di ẹni tí wọ́n fi sínú ẹ̀wọ̀n lórí ẹ̀sùn ìparọ́-sìná-mọ́ni, tòhun ti bí ó ṣe jẹ́ Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun! Nítorí náà, mùsùlùmí bùkátà sí ìrawọ́rasẹ̀ sí Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā -.
A mú àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl la agbami òkun já. Fir‘aon àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ sì gbá tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, ní ti ìlara àti ìtayọ ẹnu-ààlà, títí ìtẹ̀rì sínú agbami òkun fi bá a. Ó sì wí pé: “Mo gbàgbọ́ pé dájúdájú kò sí ọlọ́hun kan tí a gbọ́dọ̀ jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo àyàfi Ẹni tí àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl gbàgbọ́. Mo sì wà nínú àwọn mùsùlùmí.”¹
1. Àkíyèsí mẹ́ta ló wà nínú gbólóhùn tí Fir‘aon sọ yìí. Ìkíní: Fir‘aon sọ pé, “Mo gbàgbọ́ pé dájúdájú kò sí ọlọ́hun tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Ẹni tí àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl gbàgbọ́.”, dípò kí Fir‘aon sọ pé, “Mo gbàgbọ́ pé dájúdájú kò sí ọlọ́hun kan tí a gbọ́dọ̀ jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo àyàfi Allāhu.” Ìgbéraga rẹ̀ ló mú “àfi Allāhu.”wúwo lẹ́nu rẹ̀, tí ó fi wí pé “àfi Ẹni tí àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl gbàgbọ́.”
Ìkéjì: Nínú ẹ̀gbàwá Imām ’Ahmọd, nínú hadīth mọrfū‘ Sa‘īd bun Jubaer àti Ibn ‘Abbās - kí Allāhu yọ́nú sí wọn -, Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - sọ pé: “Dájúdájú Jibrīl - kí ọlà Allāhu máa bá a - ń rọ́ erùpẹ̀ sí ẹnu Fir‘aon ní ti ìpáyà pé kí ó má sọ pé, “kò sí ọlọ́hun kan tí a gbọ́dọ̀ jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo àyàfi Allāhu.”. Èyí fi hàn pé, Fir‘aon kò rí kalmọh wí bí ó ṣe yẹ kí ó wí i. Wọ́n ní kí ó sọ́ tó, ó ní òun kò lè sọ tótòtòó. Dípò kí ó sọ pé, “kò sí ọlọ́hun kan tí a gbọ́dọ̀ jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo àyàfi Allāhu.”, ó wí pé, “kò sí ọlọ́hun kan tí a gbọ́dọ̀ jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo àyàfi Ẹni tí àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl gbàgbọ́.” Ṣé Ọlọ́hun tí àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl gbàgbọ́ kò lórúkọ ni?
Ìkẹta: Ẹ̀sìn ’Islām ni ẹ̀sìn àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl lójú ayé Ànábì Mūsā - kí ọlà Allāhu máa bá a -. Mùsùlùmí sì ni wọ́n. Èyí ló hàn sí Fir‘aon l’òun náà fi sọ pé, “Mo sì wà nínú àwọn mùsùlùmí.” Àmọ́ lẹ́yìn ikú Ànábì Mūsā - kí ọlà Allāhu máa bá a -, àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl pa ẹ̀sìn ’Islām tì pátápátá, wọ́n sì gbé ẹ̀sìn mìíràn kalẹ̀ fúnra wọn. Orúkọ ẹ̀sìn àdádáálẹ̀ wọn sì ni Yẹhūdiyyah. Irú àdánwò yìí kan náà ló ṣẹlẹ̀ sí ìjọ Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - lẹ́yìn tí Allāhu gbé e gun sánmọ̀ lọ láàyè. Ìjọ tirẹ̀ náà pa ẹ̀sìn ’Islām tì pátápátá, wọ́n sì gbé ẹ̀sìn mìíràn kalẹ̀ fúnra wọn. Orúkọ ẹ̀sìn àdádáálẹ̀ wọn sì ni Nasrọ̄niyyah. Ẹ tún wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:62.
Lẹ́yìn náà, A óò gba àwọn Òjíṣẹ́ Wa àti àwọn tó gbàgbọ́ lódodo là. Báyẹn ní ó ṣe jẹ́ ojúṣe Wa láti gba àwọn onígbàgbọ́ òdodo là.
Tẹ̀lé ohun tí A fi ránṣẹ́ sí ọ nínú ìmísí. Kí o sì ṣe sùúrù títí Allāhu yóò fi ṣèdájọ́. Òun sì lóore julọ nínú àwọn olùdájọ́.
Contents of the translations can be downloaded and re-published, with the following terms and conditions:
1. No modification, addition, or deletion of the content.
2. Clearly referring to the publisher and the source (QuranEnc.com).
3. Mentioning the version number when re-publishing the translation.
4. Keeping the transcript information inside the document.
5. Notifying the source (QuranEnc.com) of any note on the translation.
6. Updating the translation according to the latest version issued from the source (QuranEnc.com).
7. Inappropriate advertisements must not be included when displaying translations of the meanings of the Noble Quran.
অনুসন্ধানের ফলসমূহ:
API specs
Endpoints:
Sura translation
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/sura/{translation_key}/{sura_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified sura (by its number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114)
Returns:
json object containing array of objects, each object contains the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/aya/{translation_key}/{sura_number}/{aya_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified aya (by its number sura_number and aya_number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114) aya_number: [1-...] (Aya number in the sura)
Returns:
json object containing the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".