কুরআনুল কারীমের অর্থসমূহের অনুবাদ - ইয়োরুবা ভাষায় অনুবাদ * - অনুবাদসমূহের সূচী

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

অর্থসমূহের অনুবাদ আয়াত: (20) সূরা: সূরা আস-সাজদাহ
وَأَمَّا ٱلَّذِينَ فَسَقُواْ فَمَأۡوَىٰهُمُ ٱلنَّارُۖ كُلَّمَآ أَرَادُوٓاْ أَن يَخۡرُجُواْ مِنۡهَآ أُعِيدُواْ فِيهَا وَقِيلَ لَهُمۡ ذُوقُواْ عَذَابَ ٱلنَّارِ ٱلَّذِي كُنتُم بِهِۦ تُكَذِّبُونَ
Ní ti àwọn tó balẹ̀jẹ́, Iná ni ibùgbé wọn. Ìgbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́ jáde kúrò nínú rẹ̀, A ó sì máa dá wọn padà sínú rẹ̀. A sì máa sọ fún wọn pé: “Ẹ tọ́ ìyà Iná tí ẹ̀ ń pè ní irọ́ wò.”¹
1. Láti ọ̀dọ̀ Yẹzīd Faƙīr, ó sọ pé, ìròrí kan nínú ìròrí ìjọ Kawārij ti kó sínú ọkàn mi. A sì jáde pẹ̀lú àwọn ènìyàn kan tí ó ní òǹkà, à = = ń lọ ṣe hajj. Lẹ́yìn náà, a máa ń jáde lọ bá àwọn ènìyàn. A sì gba Mọdīnah kọjá ni a bá rí Jābir ọmọ ‘Abdullāh tí ó ń sọ hadīth fún àwọn ènìyàn, ó jókòó síbi òpó kan, ó sọ pé láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Allāhu - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, ó sọ pé, … Àti pé Jābir sọ ọ̀rọ̀ àwọn Jahannamiyyūn. Yẹzīd sọ pé, mo sọ fún un pé, “Ìwọ Sọhābah Òjíṣẹ́ Allāhu, kí ni èyí tí ò ń sọ nínú hadīth báyìí o, tí Allāhu sì ń sọ pé, “ẹnikẹ́ni tí O bá mú wọ inú Iná, O ti dójú tì í.” (Sūrah āli-‘Imrọ̄n; 3:192), Allāhu tún sọ pé, “Ìgbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́ jáde kúrò nínú rẹ̀, A ó sì máa dá wọn padà sínú rẹ̀.” (sūrah as-Sajdah; 32:20) Nítorí náà, kí ni èyí tí ẹ wá ń sọ (pé hadīth kan sọ pe - àwọn kan máa jáde kúrò nínú Iná)?” Yẹzīd sọ pé, Jābir sọ pé, “Ṣé o máa ń ké al-Ƙur’ān?” Mo sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.” Jābir tún sọ pé, “Ǹjẹ́ o gbọ́ nípa àyè Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ìyẹn, ibi tí Allāhu máa gbé e sí ní ọ̀run?” Mo sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.” Jābir sọ pé, “Dájúdájú àyè Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ni àyè ògo èyí tí Allāhu yóò máa fi ẹni tí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - bá fẹ́ mú jáde kúrò nínú Iná kúrò nínú Iná.” Yẹzīd sọ pé, lẹ́yìn náà Jābir ròyìn àgbékalẹ̀ afárá Iná àti kíkọjá àwọn ènìyàn lórí rẹ̀. Yẹzīd sọ pé, “Mò ń páyà pé èmi kò rí i há sórí ju ìyẹn.” Yẹzīd tún sọ pé, yàtọ̀ sí pé dájúdájú Jābir sọ pé, “Dájúdájú àwọn ìjọ kan máa jáde kúrò nínú Iná lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wà nínú rẹ̀.” Ó sọ pé, ìyẹn túmọ̀ sí pé, “Wọ́n máa jáde kúrò nínú rẹ̀, wọ́n sì máa dàbí igi ìdáná simsim.” Jābir sọ pé, “Wọ́n máa wọ inú odò kan nínú odò Ọgbà Ìdẹ̀ra. Wọ́n máa wẹ̀ nínú rẹ̀, wọ́n sì máa jáde bí ẹni pé dájúdájú ìwé àjákọ fúnfun ni wọ́n.” Lẹ́yìn náà, a padà sí ìlú, a sì sọ pé, “Ṣíọ̀ yín - ẹ̀yin Kawārij - ṣé ẹ lérò pé àgbàlágbà Sọhābah ń parọ́ mọ́ Òjíṣẹ́ Allāhu - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ni?” Nítorí náà, àwa ṣẹ́rí padà kúrò níbi ìròrí kawārij. Mo sì fi Allāhu búra, kò sí ẹnì kan nínú wa tí ó yapa òdodo náà yàtọ̀ sí ọkùnrin ẹyọ kan - tàbí gẹ́gẹ́ bí bàbá Nu‘aem ṣe sọ.”
(Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wá fún iṣẹ́ hajj, wọ́n sì ní àdánwò àṣìgbọ́ kan pé àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ńlá, yàtọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ abẹ̀sìnjẹ́, wọn kò níí jáde kúrò nínú Iná gẹ́gẹ́ bí àwọn kèfèrí àti àwọn ọ̀ṣẹbọ ṣe máa ṣe gbére nínú Iná. Àwọn ènìyàn náà ń lo àwọn āyah tó wá lórí ọ̀rọ̀ àwọn aláìgbàgbọ́ fún àwọn mùsùlùmí tí wọ́n kú sórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ńlá. Àdìsọ́kàn náà jẹ ọ̀kan nínú àwọn àdìsọ́kàn ìjọ Kawārij.
Àwọn ènìyàn wọ̀nyí sì ń jáde sí àwọn ènìyàn pẹ̀lú àdìsọ́kàn burúkú yìí lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n parí iṣẹ́ hajj. Àmọ́ lórí ìrìn-àjò náà, Allāhu fi wọ́n ṣe kòǹgẹ́ Sọhābah kan Jābir ọmọ ‘Abdullāh ’Ansọ̄riy - kí Allāhu yọ́nú sí àwọn méjèèjì -. Ó sì ṣàlàyé aburú àṣìgbọ́ wọn fún wọn. Wọ́n sì kúrò lórí ohun tí wọ́n ti dì sọ́kàn tẹ́lẹ̀ àfi ẹnì kan nínú wọn tí ó kọ òdodo náà.
Ìṣẹ̀lẹ́ yìí tún fi hàn pé, àlòpọ̀ mọ́ra wọn ni al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé àti hadīth Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - tí ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àṣìgbọ̀ ẹ̀sìn ni mùsùlùmí yóò máa kàkún àgbọ́yé ẹ̀sìn.)
আরবি তাফসীরসমূহ:
 
অর্থসমূহের অনুবাদ আয়াত: (20) সূরা: সূরা আস-সাজদাহ
সূরাসমূহের সূচী পৃষ্ঠার নাম্বার
 
কুরআনুল কারীমের অর্থসমূহের অনুবাদ - ইয়োরুবা ভাষায় অনুবাদ - অনুবাদসমূহের সূচী

ইয়োরুবা ভাষায় কুরআনুল কারীমের অর্থসমূহের অনুবাদ। অনুবাদ করেছেন শায়খ আবূ রাহীমাহ মিকাঈল আইকুয়েনী। প্রকাশকাল ১৪৩২হি.।

বন্ধ