Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: Al-Muddaththir   Vers:

Suuratul-Muddathir

يَٰٓأَيُّهَا ٱلۡمُدَّثِّرُ
Ìwọ olùdaṣọbora.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
قُمۡ فَأَنذِرۡ
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَرَبَّكَ فَكَبِّرۡ
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَثِيَابَكَ فَطَهِّرۡ
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلرُّجۡزَ فَٱهۡجُرۡ
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَلَا تَمۡنُن تَسۡتَكۡثِرُ
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَلِرَبِّكَ فَٱصۡبِرۡ
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَإِذَا نُقِرَ فِي ٱلنَّاقُورِ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَذَٰلِكَ يَوۡمَئِذٖ يَوۡمٌ عَسِيرٌ
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَلَى ٱلۡكَٰفِرِينَ غَيۡرُ يَسِيرٖ
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ذَرۡنِي وَمَنۡ خَلَقۡتُ وَحِيدٗا
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan (ìyẹn nínú ikùn ìyá rẹ̀).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَجَعَلۡتُ لَهُۥ مَالٗا مَّمۡدُودٗا
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَبَنِينَ شُهُودٗا
àti àwọn ọmọkúnrin tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَمَهَّدتُّ لَهُۥ تَمۡهِيدٗا
Mo sì fi àyè ìrọ̀rùn gbá a dáadáa.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُمَّ يَطۡمَعُ أَنۡ أَزِيدَ
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَلَّآۖ إِنَّهُۥ كَانَ لِأٓيَٰتِنَا عَنِيدٗا
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
سَأُرۡهِقُهُۥ صَعُودًا
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná)¹.
[1] Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّهُۥ فَكَّرَ وَقَدَّرَ
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَقُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُمَّ قُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُمَّ نَظَرَ
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُمَّ عَبَسَ وَبَسَرَ
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُمَّ أَدۡبَرَ وَٱسۡتَكۡبَرَ
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìndà, ó sì ṣègbéraga.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَقَالَ إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا سِحۡرٞ يُؤۡثَرُ
Ó sì wí pé: “Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا قَوۡلُ ٱلۡبَشَرِ
Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
سَأُصۡلِيهِ سَقَرَ
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا سَقَرُ
Kí l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ iná Saƙọr?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَا تُبۡقِي وَلَا تَذَرُ
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.¹
1. Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَوَّاحَةٞ لِّلۡبَشَرِ
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَلَيۡهَا تِسۡعَةَ عَشَرَ
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَمَا جَعَلۡنَآ أَصۡحَٰبَ ٱلنَّارِ إِلَّا مَلَٰٓئِكَةٗۖ وَمَا جَعَلۡنَا عِدَّتَهُمۡ إِلَّا فِتۡنَةٗ لِّلَّذِينَ كَفَرُواْ لِيَسۡتَيۡقِنَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَيَزۡدَادَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُوٓاْ إِيمَٰنٗا وَلَا يَرۡتَابَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَٱلۡمُؤۡمِنُونَ وَلِيَقُولَ ٱلَّذِينَ فِي قُلُوبِهِم مَّرَضٞ وَٱلۡكَٰفِرُونَ مَاذَآ أَرَادَ ٱللَّهُ بِهَٰذَا مَثَلٗاۚ كَذَٰلِكَ يُضِلُّ ٱللَّهُ مَن يَشَآءُ وَيَهۡدِي مَن يَشَآءُۚ وَمَا يَعۡلَمُ جُنُودَ رَبِّكَ إِلَّا هُوَۚ وَمَا هِيَ إِلَّا ذِكۡرَىٰ لِلۡبَشَرِ
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: “Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?” Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَلَّا وَٱلۡقَمَرِ
Ẹ gbọ́! Allāhu fi òṣùpá búra.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّيۡلِ إِذۡ أَدۡبَرَ
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلصُّبۡحِ إِذَآ أَسۡفَرَ
Ó tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́ búra.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّهَا لَإِحۡدَى ٱلۡكُبَرِ
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) tó tóbi.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
نَذِيرٗا لِّلۡبَشَرِ
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لِمَن شَآءَ مِنكُمۡ أَن يَتَقَدَّمَ أَوۡ يَتَأَخَّرَ
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn (nínú ẹ̀ṣẹ̀).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كُلُّ نَفۡسِۭ بِمَا كَسَبَتۡ رَهِينَةٌ
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun tó ṣe níṣẹ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِلَّآ أَصۡحَٰبَ ٱلۡيَمِينِ
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فِي جَنَّٰتٖ يَتَسَآءَلُونَ
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَنِ ٱلۡمُجۡرِمِينَ
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
مَا سَلَكَكُمۡ فِي سَقَرَ
“Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
قَالُواْ لَمۡ نَكُ مِنَ ٱلۡمُصَلِّينَ
Wọn yóò wí pé: “Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَلَمۡ نَكُ نُطۡعِمُ ٱلۡمِسۡكِينَ
Àwa kò sì sí nínú àwọn tó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكُنَّا نَخُوضُ مَعَ ٱلۡخَآئِضِينَ
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكُنَّا نُكَذِّبُ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
حَتَّىٰٓ أَتَىٰنَا ٱلۡيَقِينُ
títí ikú fi dé bá wa.”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَمَا تَنفَعُهُمۡ شَفَٰعَةُ ٱلشَّٰفِعِينَ
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَمَا لَهُمۡ عَنِ ٱلتَّذۡكِرَةِ مُعۡرِضِينَ
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَأَنَّهُمۡ حُمُرٞ مُّسۡتَنفِرَةٞ
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń sá lọ,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَرَّتۡ مِن قَسۡوَرَةِۭ
tó sá fún kìnìhún?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
بَلۡ يُرِيدُ كُلُّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ أَن يُؤۡتَىٰ صُحُفٗا مُّنَشَّرَةٗ
Rárá, ńṣe ni ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَلَّاۖ بَل لَّا يَخَافُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَلَّآ إِنَّهُۥ تَذۡكِرَةٞ
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَمَن شَآءَ ذَكَرَهُۥ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́, kí ó rántí rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَمَا يَذۡكُرُونَ إِلَّآ أَن يَشَآءَ ٱللَّهُۚ هُوَ أَهۡلُ ٱلتَّقۡوَىٰ وَأَهۡلُ ٱلۡمَغۡفِرَةِ
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì ni àforíjìn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: Al-Muddaththir
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen