وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی * - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی المدثر   ئایه‌تی:

Suuratul-Muddathir

يَٰٓأَيُّهَا ٱلۡمُدَّثِّرُ
Ìwọ olùdaṣọbora.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
قُمۡ فَأَنذِرۡ
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَرَبَّكَ فَكَبِّرۡ
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَثِيَابَكَ فَطَهِّرۡ
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلرُّجۡزَ فَٱهۡجُرۡ
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَلَا تَمۡنُن تَسۡتَكۡثِرُ
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَلِرَبِّكَ فَٱصۡبِرۡ
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَإِذَا نُقِرَ فِي ٱلنَّاقُورِ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَذَٰلِكَ يَوۡمَئِذٖ يَوۡمٌ عَسِيرٌ
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
عَلَى ٱلۡكَٰفِرِينَ غَيۡرُ يَسِيرٖ
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ذَرۡنِي وَمَنۡ خَلَقۡتُ وَحِيدٗا
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan (ìyẹn nínú ikùn ìyá rẹ̀).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَجَعَلۡتُ لَهُۥ مَالٗا مَّمۡدُودٗا
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَبَنِينَ شُهُودٗا
àti àwọn ọmọkúnrin tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَمَهَّدتُّ لَهُۥ تَمۡهِيدٗا
Mo sì fi àyè ìrọ̀rùn gbá a dáadáa.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ثُمَّ يَطۡمَعُ أَنۡ أَزِيدَ
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَلَّآۖ إِنَّهُۥ كَانَ لِأٓيَٰتِنَا عَنِيدٗا
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
سَأُرۡهِقُهُۥ صَعُودًا
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná)¹.
[1] Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّهُۥ فَكَّرَ وَقَدَّرَ
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَقُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ثُمَّ قُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ثُمَّ نَظَرَ
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ثُمَّ عَبَسَ وَبَسَرَ
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ثُمَّ أَدۡبَرَ وَٱسۡتَكۡبَرَ
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìndà, ó sì ṣègbéraga.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَقَالَ إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا سِحۡرٞ يُؤۡثَرُ
Ó sì wí pé: “Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا قَوۡلُ ٱلۡبَشَرِ
Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
سَأُصۡلِيهِ سَقَرَ
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا سَقَرُ
Kí l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ iná Saƙọr?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
لَا تُبۡقِي وَلَا تَذَرُ
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.¹
1. Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
لَوَّاحَةٞ لِّلۡبَشَرِ
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
عَلَيۡهَا تِسۡعَةَ عَشَرَ
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَمَا جَعَلۡنَآ أَصۡحَٰبَ ٱلنَّارِ إِلَّا مَلَٰٓئِكَةٗۖ وَمَا جَعَلۡنَا عِدَّتَهُمۡ إِلَّا فِتۡنَةٗ لِّلَّذِينَ كَفَرُواْ لِيَسۡتَيۡقِنَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَيَزۡدَادَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُوٓاْ إِيمَٰنٗا وَلَا يَرۡتَابَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَٱلۡمُؤۡمِنُونَ وَلِيَقُولَ ٱلَّذِينَ فِي قُلُوبِهِم مَّرَضٞ وَٱلۡكَٰفِرُونَ مَاذَآ أَرَادَ ٱللَّهُ بِهَٰذَا مَثَلٗاۚ كَذَٰلِكَ يُضِلُّ ٱللَّهُ مَن يَشَآءُ وَيَهۡدِي مَن يَشَآءُۚ وَمَا يَعۡلَمُ جُنُودَ رَبِّكَ إِلَّا هُوَۚ وَمَا هِيَ إِلَّا ذِكۡرَىٰ لِلۡبَشَرِ
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: “Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?” Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَلَّا وَٱلۡقَمَرِ
Ẹ gbọ́! Allāhu fi òṣùpá búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّيۡلِ إِذۡ أَدۡبَرَ
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلصُّبۡحِ إِذَآ أَسۡفَرَ
Ó tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́ búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّهَا لَإِحۡدَى ٱلۡكُبَرِ
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) tó tóbi.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
نَذِيرٗا لِّلۡبَشَرِ
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
لِمَن شَآءَ مِنكُمۡ أَن يَتَقَدَّمَ أَوۡ يَتَأَخَّرَ
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn (nínú ẹ̀ṣẹ̀).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كُلُّ نَفۡسِۭ بِمَا كَسَبَتۡ رَهِينَةٌ
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun tó ṣe níṣẹ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِلَّآ أَصۡحَٰبَ ٱلۡيَمِينِ
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فِي جَنَّٰتٖ يَتَسَآءَلُونَ
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
تەفسیرە عەرەبیەکان:
عَنِ ٱلۡمُجۡرِمِينَ
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
تەفسیرە عەرەبیەکان:
مَا سَلَكَكُمۡ فِي سَقَرَ
“Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
قَالُواْ لَمۡ نَكُ مِنَ ٱلۡمُصَلِّينَ
Wọn yóò wí pé: “Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَلَمۡ نَكُ نُطۡعِمُ ٱلۡمِسۡكِينَ
Àwa kò sì sí nínú àwọn tó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَكُنَّا نَخُوضُ مَعَ ٱلۡخَآئِضِينَ
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَكُنَّا نُكَذِّبُ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́
تەفسیرە عەرەبیەکان:
حَتَّىٰٓ أَتَىٰنَا ٱلۡيَقِينُ
títí ikú fi dé bá wa.”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَمَا تَنفَعُهُمۡ شَفَٰعَةُ ٱلشَّٰفِعِينَ
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَمَا لَهُمۡ عَنِ ٱلتَّذۡكِرَةِ مُعۡرِضِينَ
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَأَنَّهُمۡ حُمُرٞ مُّسۡتَنفِرَةٞ
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń sá lọ,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَرَّتۡ مِن قَسۡوَرَةِۭ
tó sá fún kìnìhún?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
بَلۡ يُرِيدُ كُلُّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ أَن يُؤۡتَىٰ صُحُفٗا مُّنَشَّرَةٗ
Rárá, ńṣe ni ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَلَّاۖ بَل لَّا يَخَافُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَلَّآ إِنَّهُۥ تَذۡكِرَةٞ
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَمَن شَآءَ ذَكَرَهُۥ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́, kí ó rántí rẹ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَمَا يَذۡكُرُونَ إِلَّآ أَن يَشَآءَ ٱللَّهُۚ هُوَ أَهۡلُ ٱلتَّقۡوَىٰ وَأَهۡلُ ٱلۡمَغۡفِرَةِ
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì ni àforíjìn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
 
وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی المدثر
پێڕستی سوره‌ته‌كان ژمارەی پەڕە
 
وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

وەرگێڕاوی ماناکانی قورئانی پیرۆز بۆ زمانی یوربا، وەرگێڕان: شێخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني، چاپی ساڵی 1432ك.

داخستن