Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: An-Naba’   Vers:

Suuratun-Naba'

عَمَّ يَتَسَآءَلُونَ
Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَنِ ٱلنَّبَإِ ٱلۡعَظِيمِ
Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ٱلَّذِي هُمۡ فِيهِ مُخۡتَلِفُونَ
èyí tí wọ́n ń yapa-ẹnu lórí rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ثُمَّ كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Lẹ́yìn náà, rárá sẹ́, wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَلَمۡ نَجۡعَلِ ٱلۡأَرۡضَ مِهَٰدٗا
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلۡجِبَالَ أَوۡتَادٗا
àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَخَلَقۡنَٰكُمۡ أَزۡوَٰجٗا
A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَجَعَلۡنَا نَوۡمَكُمۡ سُبَاتٗا
A ṣe oorun yín ní ìsinmi.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَجَعَلۡنَا ٱلَّيۡلَ لِبَاسٗا
A tún ṣe alẹ́ ní ìbora.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَجَعَلۡنَا ٱلنَّهَارَ مَعَاشٗا
A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَبَنَيۡنَا فَوۡقَكُمۡ سَبۡعٗا شِدَادٗا
A tún mọ sánmọ̀ méje tó lágbára sókè yín.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَجَعَلۡنَا سِرَاجٗا وَهَّاجٗا
A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ tó ń tàn gbòlà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَأَنزَلۡنَا مِنَ ٱلۡمُعۡصِرَٰتِ مَآءٗ ثَجَّاجٗا
Àti pé A sọ omi tó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لِّنُخۡرِجَ بِهِۦ حَبّٗا وَنَبَاتٗا
nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَجَنَّٰتٍ أَلۡفَافًا
pẹ̀lú àwọn ọgbà tó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّ يَوۡمَ ٱلۡفَصۡلِ كَانَ مِيقَٰتٗا
Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
يَوۡمَ يُنفَخُ فِي ٱلصُّورِ فَتَأۡتُونَ أَفۡوَاجٗا
(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَفُتِحَتِ ٱلسَّمَآءُ فَكَانَتۡ أَبۡوَٰبٗا
Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَسُيِّرَتِ ٱلۡجِبَالُ فَكَانَتۡ سَرَابًا
Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّ جَهَنَّمَ كَانَتۡ مِرۡصَادٗا
Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لِّلطَّٰغِينَ مَـَٔابٗا
(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَّٰبِثِينَ فِيهَآ أَحۡقَابٗا
Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَّا يَذُوقُونَ فِيهَا بَرۡدٗا وَلَا شَرَابًا
Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِلَّا حَمِيمٗا وَغَسَّاقٗا
àyàfi omi tó gbóná parí àti àwọnúwẹ̀jẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
جَزَآءٗ وِفَاقًا
(Ó jẹ́) ẹ̀san tó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّهُمۡ كَانُواْ لَا يَرۡجُونَ حِسَابٗا
Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكَذَّبُواْ بِـَٔايَٰتِنَا كِذَّابٗا
Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa ní irọ́ gan-an.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكُلَّ شَيۡءٍ أَحۡصَيۡنَٰهُ كِتَٰبٗا
Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَذُوقُواْ فَلَن نَّزِيدَكُمۡ إِلَّا عَذَابًا
Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fún yín bí kò ṣe ìyà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّ لِلۡمُتَّقِينَ مَفَازًا
Dájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
حَدَآئِقَ وَأَعۡنَٰبٗا
Àwọn ọgbà oko àti èso àjàrà,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكَوَاعِبَ أَتۡرَابٗا
àti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَكَأۡسٗا دِهَاقٗا
àti ife ọtí tó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لَّا يَسۡمَعُونَ فِيهَا لَغۡوٗا وَلَا كِذَّٰبٗا
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
جَزَآءٗ مِّن رَّبِّكَ عَطَآءً حِسَابٗا
(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
رَّبِّ ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَٱلۡأَرۡضِ وَمَا بَيۡنَهُمَا ٱلرَّحۡمَٰنِۖ لَا يَمۡلِكُونَ مِنۡهُ خِطَابٗا
(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun tó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
يَوۡمَ يَقُومُ ٱلرُّوحُ وَٱلۡمَلَٰٓئِكَةُ صَفّٗاۖ لَّا يَتَكَلَّمُونَ إِلَّا مَنۡ أَذِنَ لَهُ ٱلرَّحۡمَٰنُ وَقَالَ صَوَابٗا
Ọjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ tó máa ṣe wẹ́kú.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ذَٰلِكَ ٱلۡيَوۡمُ ٱلۡحَقُّۖ فَمَن شَآءَ ٱتَّخَذَ إِلَىٰ رَبِّهِۦ مَـَٔابًا
Ìyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّآ أَنذَرۡنَٰكُمۡ عَذَابٗا قَرِيبٗا يَوۡمَ يَنظُرُ ٱلۡمَرۡءُ مَا قَدَّمَتۡ يَدَاهُ وَيَقُولُ ٱلۡكَافِرُ يَٰلَيۡتَنِي كُنتُ تُرَٰبَۢا
Dájúdájú A fi ìyà tó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fún yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: “Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà).”
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: An-Naba’
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen