《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 * - 译解目录

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

含义的翻译 章: 奈拜艾   段:

Suuratun-Naba'

عَمَّ يَتَسَآءَلُونَ
Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
阿拉伯语经注:
عَنِ ٱلنَّبَإِ ٱلۡعَظِيمِ
Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
阿拉伯语经注:
ٱلَّذِي هُمۡ فِيهِ مُخۡتَلِفُونَ
èyí tí wọ́n ń yapa-ẹnu lórí rẹ̀.
阿拉伯语经注:
كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Lẹ́yìn náà, rárá sẹ́, wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
阿拉伯语经注:
أَلَمۡ نَجۡعَلِ ٱلۡأَرۡضَ مِهَٰدٗا
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
阿拉伯语经注:
وَٱلۡجِبَالَ أَوۡتَادٗا
àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
阿拉伯语经注:
وَخَلَقۡنَٰكُمۡ أَزۡوَٰجٗا
A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
阿拉伯语经注:
وَجَعَلۡنَا نَوۡمَكُمۡ سُبَاتٗا
A ṣe oorun yín ní ìsinmi.
阿拉伯语经注:
وَجَعَلۡنَا ٱلَّيۡلَ لِبَاسٗا
A tún ṣe alẹ́ ní ìbora.
阿拉伯语经注:
وَجَعَلۡنَا ٱلنَّهَارَ مَعَاشٗا
A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
阿拉伯语经注:
وَبَنَيۡنَا فَوۡقَكُمۡ سَبۡعٗا شِدَادٗا
A tún mọ sánmọ̀ méje tó lágbára sókè yín.
阿拉伯语经注:
وَجَعَلۡنَا سِرَاجٗا وَهَّاجٗا
A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ tó ń tàn gbòlà.
阿拉伯语经注:
وَأَنزَلۡنَا مِنَ ٱلۡمُعۡصِرَٰتِ مَآءٗ ثَجَّاجٗا
Àti pé A sọ omi tó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
阿拉伯语经注:
لِّنُخۡرِجَ بِهِۦ حَبّٗا وَنَبَاتٗا
nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
阿拉伯语经注:
وَجَنَّٰتٍ أَلۡفَافًا
pẹ̀lú àwọn ọgbà tó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
阿拉伯语经注:
إِنَّ يَوۡمَ ٱلۡفَصۡلِ كَانَ مِيقَٰتٗا
Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
阿拉伯语经注:
يَوۡمَ يُنفَخُ فِي ٱلصُّورِ فَتَأۡتُونَ أَفۡوَاجٗا
(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
阿拉伯语经注:
وَفُتِحَتِ ٱلسَّمَآءُ فَكَانَتۡ أَبۡوَٰبٗا
Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
阿拉伯语经注:
وَسُيِّرَتِ ٱلۡجِبَالُ فَكَانَتۡ سَرَابًا
Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
阿拉伯语经注:
إِنَّ جَهَنَّمَ كَانَتۡ مِرۡصَادٗا
Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
阿拉伯语经注:
لِّلطَّٰغِينَ مَـَٔابٗا
(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
阿拉伯语经注:
لَّٰبِثِينَ فِيهَآ أَحۡقَابٗا
Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
阿拉伯语经注:
لَّا يَذُوقُونَ فِيهَا بَرۡدٗا وَلَا شَرَابًا
Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
阿拉伯语经注:
إِلَّا حَمِيمٗا وَغَسَّاقٗا
àyàfi omi tó gbóná parí àti àwọnúwẹ̀jẹ̀.
阿拉伯语经注:
جَزَآءٗ وِفَاقًا
(Ó jẹ́) ẹ̀san tó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
阿拉伯语经注:
إِنَّهُمۡ كَانُواْ لَا يَرۡجُونَ حِسَابٗا
Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
阿拉伯语经注:
وَكَذَّبُواْ بِـَٔايَٰتِنَا كِذَّابٗا
Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa ní irọ́ gan-an.
阿拉伯语经注:
وَكُلَّ شَيۡءٍ أَحۡصَيۡنَٰهُ كِتَٰبٗا
Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
阿拉伯语经注:
فَذُوقُواْ فَلَن نَّزِيدَكُمۡ إِلَّا عَذَابًا
Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fún yín bí kò ṣe ìyà.
阿拉伯语经注:
إِنَّ لِلۡمُتَّقِينَ مَفَازًا
Dájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
阿拉伯语经注:
حَدَآئِقَ وَأَعۡنَٰبٗا
Àwọn ọgbà oko àti èso àjàrà,
阿拉伯语经注:
وَكَوَاعِبَ أَتۡرَابٗا
àti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,
阿拉伯语经注:
وَكَأۡسٗا دِهَاقٗا
àti ife ọtí tó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).
阿拉伯语经注:
لَّا يَسۡمَعُونَ فِيهَا لَغۡوٗا وَلَا كِذَّٰبٗا
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.
阿拉伯语经注:
جَزَآءٗ مِّن رَّبِّكَ عَطَآءً حِسَابٗا
(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).
阿拉伯语经注:
رَّبِّ ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَٱلۡأَرۡضِ وَمَا بَيۡنَهُمَا ٱلرَّحۡمَٰنِۖ لَا يَمۡلِكُونَ مِنۡهُ خِطَابٗا
(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun tó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.
阿拉伯语经注:
يَوۡمَ يَقُومُ ٱلرُّوحُ وَٱلۡمَلَٰٓئِكَةُ صَفّٗاۖ لَّا يَتَكَلَّمُونَ إِلَّا مَنۡ أَذِنَ لَهُ ٱلرَّحۡمَٰنُ وَقَالَ صَوَابٗا
Ọjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ tó máa ṣe wẹ́kú.
阿拉伯语经注:
ذَٰلِكَ ٱلۡيَوۡمُ ٱلۡحَقُّۖ فَمَن شَآءَ ٱتَّخَذَ إِلَىٰ رَبِّهِۦ مَـَٔابًا
Ìyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).
阿拉伯语经注:
إِنَّآ أَنذَرۡنَٰكُمۡ عَذَابٗا قَرِيبٗا يَوۡمَ يَنظُرُ ٱلۡمَرۡءُ مَا قَدَّمَتۡ يَدَاهُ وَيَقُولُ ٱلۡكَافِرُ يَٰلَيۡتَنِي كُنتُ تُرَٰبَۢا
Dájúdájú A fi ìyà tó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fún yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: “Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà).”
阿拉伯语经注:
 
含义的翻译 章: 奈拜艾
章节目录 页码
 
《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 - 译解目录

古兰经泰卢固语译解,艾布·拉赫曼·米卡伊里·艾库比尼长老翻译,伊历1432年出版发行。

关闭