Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Ayah: (101) Surah: Āl-‘Imrān
وَكَيۡفَ تَكۡفُرُونَ وَأَنتُمۡ تُتۡلَىٰ عَلَيۡكُمۡ ءَايَٰتُ ٱللَّهِ وَفِيكُمۡ رَسُولُهُۥۗ وَمَن يَعۡتَصِم بِٱللَّهِ فَقَدۡ هُدِيَ إِلَىٰ صِرَٰطٖ مُّسۡتَقِيمٖ
Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè ṣàì gbàgbọ́, ẹ̀yin mà ni wọ́n ń ké àwọn āyah Allāhu fún, Òjíṣẹ́ Rẹ̀ sì wà láààrin yín! Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró ṣinṣin ti Allāhu, A ti tọ́ ọ sí ọ̀nà tààrà.¹
1. Kíyè sí i, gbólóhùn yìí, “Òjíṣẹ́ Rẹ̀ sì wà láààrin yín!” Ìyẹn ṣíwájú kí ó tó kú - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -. Àmọ́ lẹ́yìn ikú rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, kò sí láààrin wa mọ́. Irú āyah yìí wà nínú sūrah at-Taobah; 9:94 àti 105 àti sūrah an-Nisā’; 4:64.
Àwọn onibidia nìkan ni wọ́n tún gbà pé títí dí àsìkò yìí ni Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ń bẹ láààrin wa, tí ó ń rí iṣẹ́ ọwọ́ wa. Bí àpẹ̀ẹrẹ, ìjọ Ahmadiyyah gbà pé Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a- padà wá sáyé, ó sì ń bá mirza Ghulam Ahmad, olùdásílẹ̀ ìjọ Ahmadiyyah ṣe ìpàdé ojú ayé. Bákan náà, ìjọ Tijāniyyah náà gbà pé Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a- padà wá sáyé láti fún ṣeeu Ahmada Tijāni lọ́wọ́ wírìdí. Kódà wọ́n gbà pé lójoojúmọ́ àti níbi gbogbo ni Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a- àti àwọn àrólé rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin - kí Allāhu yọ́nú sí wọn - máa wá jókòó sórí aṣọ funfun, èyí tí wọ́n máa ń tẹ́ sáààrin lásìkò tí wọ́n bá ń ka Jaoharatul-kamāl lọ́wọ́. Irọ́ ńlá ni gbogbo àdìsọ́kàn burúkú wọ̀nyí. Àwọn āyah tí à ń tọsẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ kò sì jẹmọ́ “lẹ́yìn ikú Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a-” bí kò ṣe “ṣíwájú ikú rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a-”. Kí á lè mọ̀ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú àmọ̀dájú, Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a- sọ pé: “Kíyè sí i, dájúdájú wọn máa mú àwọn ọkùnrin kan wá nínú ìjọ mi (ìyẹn l’ọ́jọ́ Ìdájọ́), wọ́n sì máa mú wọn lọ sí apá òṣì, n̄g ó sì sọ pé; “Olúwa mi, àwọn ènìyàn mi (nìyí).” Wọ́n sì máa sọ pé: “Dájúdájú ìwọ kò mọ ohun tí wọ́n dáálẹ̀ lẹ́yìn (ikú) rẹ.” (Bukọ̄riy àti Muslim)
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Ayah: (101) Surah: Āl-‘Imrān
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close