Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Surah: Al-Burūj   Ayah:

Suuratul-Buruuj

وَٱلسَّمَآءِ ذَاتِ ٱلۡبُرُوجِ
(Allāhu) fi sánmọ̀ tí àwọn ibùsọ̀ (òòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀) wà nínú rẹ̀ búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱلۡيَوۡمِ ٱلۡمَوۡعُودِ
Ó tún fi ọjọ́ tí wọ́n ṣe ní àdéhùn (ìyẹn Ọjọ́ Àjíǹde) búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَشَاهِدٖ وَمَشۡهُودٖ
Ó tún fi olùjẹ́rìí àti ohun tó jẹ́rìí sí búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
قُتِلَ أَصۡحَٰبُ ٱلۡأُخۡدُودِ
A ṣẹ́bi lé àwọn tó gbẹ́ kòtò (iná),
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱلنَّارِ ذَاتِ ٱلۡوَقُودِ
(ìyẹn) iná tí wọ́n ń fi igi kò (nínú kòtò).
Arabic explanations of the Qur’an:
إِذۡ هُمۡ عَلَيۡهَا قُعُودٞ
(Rántí) nígbà tí wọ́n jókòó sí ìtòsí rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَهُمۡ عَلَىٰ مَا يَفۡعَلُونَ بِٱلۡمُؤۡمِنِينَ شُهُودٞ
Wọ́n sì ń wo ohun tí wọ́n ń ṣe fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَمَا نَقَمُواْ مِنۡهُمۡ إِلَّآ أَن يُؤۡمِنُواْ بِٱللَّهِ ٱلۡعَزِيزِ ٱلۡحَمِيدِ
Wọn kò rí àlèébù kan (wọn kò sì kórira kiní kan) lára wọn bí kò ṣe pé, wọ́n ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu, Alágbára, Ẹlẹ́yìn,
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱلَّذِي لَهُۥ مُلۡكُ ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَٱلۡأَرۡضِۚ وَٱللَّهُ عَلَىٰ كُلِّ شَيۡءٖ شَهِيدٌ
Ẹni tí Ó ni ìjọba àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Allāhu sì ni Ẹlẹ́rìí lórí gbogbo n̄ǹkan.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّ ٱلَّذِينَ فَتَنُواْ ٱلۡمُؤۡمِنِينَ وَٱلۡمُؤۡمِنَٰتِ ثُمَّ لَمۡ يَتُوبُواْ فَلَهُمۡ عَذَابُ جَهَنَّمَ وَلَهُمۡ عَذَابُ ٱلۡحَرِيقِ
Dájúdájú àwọn tó fi ìnira kan àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, lẹ́yìn náà tí wọn kò ronú pìwàdà, ìyà iná Jahanamọ ń bẹ fún wọn. Ìyà iná tó ń jó sì wà fún wọn.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ وَعَمِلُواْ ٱلصَّٰلِحَٰتِ لَهُمۡ جَنَّٰتٞ تَجۡرِي مِن تَحۡتِهَا ٱلۡأَنۡهَٰرُۚ ذَٰلِكَ ٱلۡفَوۡزُ ٱلۡكَبِيرُ
Dájúdájú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, tiwọn ni àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Ìyẹn sì ni èrèǹjẹ ńlá.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّ بَطۡشَ رَبِّكَ لَشَدِيدٌ
Dájúdájú ìgbámú ti Olúwa rẹ mà le.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّهُۥ هُوَ يُبۡدِئُ وَيُعِيدُ
Dájúdájú Òun ni Ó pìlẹ̀ (ẹ̀dá), Ó sì máa dá (ẹ̀dá) padà (fún àjíǹde).
Arabic explanations of the Qur’an:
وَهُوَ ٱلۡغَفُورُ ٱلۡوَدُودُ
Òun ni Aláforíjìn, Olólùfẹ́ (ẹ̀dá),
Arabic explanations of the Qur’an:
ذُو ٱلۡعَرۡشِ ٱلۡمَجِيدُ
Òun l’Ó ni Ìtẹ́-ọlá, Ológo (Ẹni-ọ̀wọ̀ jùlọ),
Arabic explanations of the Qur’an:
فَعَّالٞ لِّمَا يُرِيدُ
Olùṣe-ohun-t’Ó-bá-fẹ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ ٱلۡجُنُودِ
Ṣebí ìró àwọn ọmọ ogun ti dé ọ̀dọ̀ rẹ,
Arabic explanations of the Qur’an:
فِرۡعَوۡنَ وَثَمُودَ
(ọmọ ogun) Fir‘aon àti (ìjọ) Thamūd?
Arabic explanations of the Qur’an:
بَلِ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ فِي تَكۡذِيبٖ
Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn tó ṣàì gbàgbọ́ sì ń pe òdodo ní irọ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱللَّهُ مِن وَرَآئِهِم مُّحِيطُۢ
Allāhu sì yí wọn ká lẹ́yìn wọn.
Arabic explanations of the Qur’an:
بَلۡ هُوَ قُرۡءَانٞ مَّجِيدٞ
Àmọ́ sá, ohun (tí A fi ránṣẹ́ sí ọ ni) al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé,
Arabic explanations of the Qur’an:
فِي لَوۡحٖ مَّحۡفُوظِۭ
tí ó wà nínú wàláà tí wọ́n ń ṣọ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Surah: Al-Burūj
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close