وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی * - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی البروج   ئایه‌تی:

Suuratul-Buruuj

وَٱلسَّمَآءِ ذَاتِ ٱلۡبُرُوجِ
(Allāhu) fi sánmọ̀ tí àwọn ibùsọ̀ (òòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀) wà nínú rẹ̀ búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلۡيَوۡمِ ٱلۡمَوۡعُودِ
Ó tún fi ọjọ́ tí wọ́n ṣe ní àdéhùn (ìyẹn Ọjọ́ Àjíǹde) búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَشَاهِدٖ وَمَشۡهُودٖ
Ó tún fi olùjẹ́rìí àti ohun tó jẹ́rìí sí búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
قُتِلَ أَصۡحَٰبُ ٱلۡأُخۡدُودِ
A ṣẹ́bi lé àwọn tó gbẹ́ kòtò (iná),
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ٱلنَّارِ ذَاتِ ٱلۡوَقُودِ
(ìyẹn) iná tí wọ́n ń fi igi kò (nínú kòtò).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِذۡ هُمۡ عَلَيۡهَا قُعُودٞ
(Rántí) nígbà tí wọ́n jókòó sí ìtòsí rẹ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَهُمۡ عَلَىٰ مَا يَفۡعَلُونَ بِٱلۡمُؤۡمِنِينَ شُهُودٞ
Wọ́n sì ń wo ohun tí wọ́n ń ṣe fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَمَا نَقَمُواْ مِنۡهُمۡ إِلَّآ أَن يُؤۡمِنُواْ بِٱللَّهِ ٱلۡعَزِيزِ ٱلۡحَمِيدِ
Wọn kò rí àlèébù kan (wọn kò sì kórira kiní kan) lára wọn bí kò ṣe pé, wọ́n ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu, Alágbára, Ẹlẹ́yìn,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ٱلَّذِي لَهُۥ مُلۡكُ ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَٱلۡأَرۡضِۚ وَٱللَّهُ عَلَىٰ كُلِّ شَيۡءٖ شَهِيدٌ
Ẹni tí Ó ni ìjọba àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Allāhu sì ni Ẹlẹ́rìí lórí gbogbo n̄ǹkan.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّ ٱلَّذِينَ فَتَنُواْ ٱلۡمُؤۡمِنِينَ وَٱلۡمُؤۡمِنَٰتِ ثُمَّ لَمۡ يَتُوبُواْ فَلَهُمۡ عَذَابُ جَهَنَّمَ وَلَهُمۡ عَذَابُ ٱلۡحَرِيقِ
Dájúdájú àwọn tó fi ìnira kan àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, lẹ́yìn náà tí wọn kò ronú pìwàdà, ìyà iná Jahanamọ ń bẹ fún wọn. Ìyà iná tó ń jó sì wà fún wọn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ وَعَمِلُواْ ٱلصَّٰلِحَٰتِ لَهُمۡ جَنَّٰتٞ تَجۡرِي مِن تَحۡتِهَا ٱلۡأَنۡهَٰرُۚ ذَٰلِكَ ٱلۡفَوۡزُ ٱلۡكَبِيرُ
Dájúdájú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, tiwọn ni àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Ìyẹn sì ni èrèǹjẹ ńlá.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّ بَطۡشَ رَبِّكَ لَشَدِيدٌ
Dájúdájú ìgbámú ti Olúwa rẹ mà le.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّهُۥ هُوَ يُبۡدِئُ وَيُعِيدُ
Dájúdájú Òun ni Ó pìlẹ̀ (ẹ̀dá), Ó sì máa dá (ẹ̀dá) padà (fún àjíǹde).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَهُوَ ٱلۡغَفُورُ ٱلۡوَدُودُ
Òun ni Aláforíjìn, Olólùfẹ́ (ẹ̀dá),
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ذُو ٱلۡعَرۡشِ ٱلۡمَجِيدُ
Òun l’Ó ni Ìtẹ́-ọlá, Ológo (Ẹni-ọ̀wọ̀ jùlọ),
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَعَّالٞ لِّمَا يُرِيدُ
Olùṣe-ohun-t’Ó-bá-fẹ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ ٱلۡجُنُودِ
Ṣebí ìró àwọn ọmọ ogun ti dé ọ̀dọ̀ rẹ,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فِرۡعَوۡنَ وَثَمُودَ
(ọmọ ogun) Fir‘aon àti (ìjọ) Thamūd?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
بَلِ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ فِي تَكۡذِيبٖ
Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn tó ṣàì gbàgbọ́ sì ń pe òdodo ní irọ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱللَّهُ مِن وَرَآئِهِم مُّحِيطُۢ
Allāhu sì yí wọn ká lẹ́yìn wọn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
بَلۡ هُوَ قُرۡءَانٞ مَّجِيدٞ
Àmọ́ sá, ohun (tí A fi ránṣẹ́ sí ọ ni) al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فِي لَوۡحٖ مَّحۡفُوظِۭ
tí ó wà nínú wàláà tí wọ́n ń ṣọ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
 
وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی البروج
پێڕستی سوره‌ته‌كان ژمارەی پەڕە
 
وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

وەرگێڕاوی ماناکانی قورئانی پیرۆز بۆ زمانی یوربا، وەرگێڕان: شێخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني، چاپی ساڵی 1432ك.

داخستن