Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Versículo: (48) Capítulo: Sura Al-Anbiyaa
وَلَقَدۡ ءَاتَيۡنَا مُوسَىٰ وَهَٰرُونَ ٱلۡفُرۡقَانَ وَضِيَآءٗ وَذِكۡرٗا لِّلۡمُتَّقِينَ
Dájúdájú A fún (Ànábì) Mūsā àti (Ànábì) Hārūn ní ọ̀rọ̀-ìpínyà (ohun tó ń ṣòpínyà láààrin òdodo àti irọ́), ìmọ́lẹ̀ àti ìrántí fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).¹
1. Ọ̀rọ̀-ìpínyà, ìmọ́lẹ̀ àti ìrántí nínú āyah yìí dúró fún àwọn ìròyìn tó wà lára tírà kan ṣoṣo tí Allāhu - tó ga jùlọ - fún Ànábì Mūsā - kí ọlà Allāhu máa bá a -. Tírà náà ni at-Taorāt. Lẹ́yìn náà, ìwọ̀nyẹn ni àwọn ìròyìn tó máa ń wà lára ìkọ̀ọ̀kan tírà tí Allāhu máa ń sọ̀kalẹ̀ fún àwọn Ànábì Rẹ̀ àti àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀ - kí ọlà Allāhu máa bá wọn -.
Kíyè sí i, gbogbo tírà tó ṣíwájú ti parí iṣẹ́ wọn. Ní àsìkò yìí, tírà ìkẹ́yìn nìkan ló ku gbogbo ayé kù. Ìyẹn sì ni al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé. Kódà bí Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - bá padà sọ̀kalẹ̀ lópin ayé, kò níí tẹ̀lé tírà kan yàtọ̀ sí al-Ƙur’ān gẹ́gẹ́ bí mo ti sọ ṣíwájú nínú ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ āyah 8.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Versículo: (48) Capítulo: Sura Al-Anbiyaa
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar