Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Capítulo: Sura Al-A'laa   Versículo:

Suuratul-A'laa

سَبِّحِ ٱسۡمَ رَبِّكَ ٱلۡأَعۡلَى
Ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni gíga jùlọ.
Las Exégesis Árabes:
ٱلَّذِي خَلَقَ فَسَوَّىٰ
Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá. Ó sì ṣe (oríkèé-ríkèé rẹ̀) ní dọ́gbadọ́gba.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلَّذِي قَدَّرَ فَهَدَىٰ
Ẹni tí Ó yan kádàrá (fún ẹ̀dá). Ó sì tọ́ ọ sọ́nà.¹
1. Nínú āyah yìí, mẹ́ta gbòòrò ni ìtọ́sọ́nà náà èyí tí Allāhu Afinimọ̀nà ń ṣe fún àwa ènìyàn àti àlùjànnú. Ìkíní: ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām. Nítorí ìtọ́sọ́nà yìí gan-an ni Allāhu ṣe sọ àwọn Tírà Rẹ̀ kalẹ̀, tí Ó sì gbé àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀ dìde sí wa.
Ìkejì: ìtọ́sọ́nà ẹ̀rí-ọkàn. Nípa èyí ni a fi mọ ohun rere àti ohun burúkú ní ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Ìfirinlẹ̀ rẹ̀ sì ń jẹyọ nínú àwọn tírà sánmọ̀ àti nínú ọ̀rọ̀ àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu - kí ọlà Allāhu máa bá wọn -.
Ìkẹta: ìtọ́sọ́nà òye àtinúwá. Nípa èyí ni a ṣe ń ṣàmúlò àwọn ohun àmúṣọrọ̀ fún ìgbáyé-gbádùn. Ìtọ́sọ́nà yìí kò sì sọ ẹnikẹ́ni di Òjíṣẹ́ Allāhu. Tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá rí ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀, kò sí ẹ̀san rere kan fún un lórí rẹ̀ ní ọ̀run. Ó kàn wúlò dànù fún ayé ni.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلَّذِيٓ أَخۡرَجَ ٱلۡمَرۡعَىٰ
Ẹni tí Ó mú koríko tútù hù jáde,
Las Exégesis Árabes:
فَجَعَلَهُۥ غُثَآءً أَحۡوَىٰ
Ó sì sọ ọ́ di gbígbẹ tó dúdú.
Las Exégesis Árabes:
سَنُقۡرِئُكَ فَلَا تَنسَىٰٓ
Àwa yóò máa ké (al-Ƙur’ān) fún ọ. Ìwọ kò sì níí gbàgbé.
Las Exégesis Árabes:
إِلَّا مَا شَآءَ ٱللَّهُۚ إِنَّهُۥ يَعۡلَمُ ٱلۡجَهۡرَ وَمَا يَخۡفَىٰ
Àyàfi ohun tí Allāhu bá fẹ́.¹ Dájúdájú Ó mọ gban̄gba àti ohun tó pamọ́.
1. Ìyẹn nípasẹ̀ fífí ìdájọ́ kan pa ìdájọ́ tó ṣíwájú rẹ̀ rẹ́. Ẹ wo sūrah al-Baƙọrah; 2:106.
Las Exégesis Árabes:
وَنُيَسِّرُكَ لِلۡيُسۡرَىٰ
Àwa yó sì ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún ọ.
Las Exégesis Árabes:
فَذَكِّرۡ إِن نَّفَعَتِ ٱلذِّكۡرَىٰ
Nítorí náà, ṣèrántí ní àyè tí ìrántí ti wúlò.¹
1. Ìyẹn ni pé, wọ́n fẹ́ kí ṣíṣe ìrántí ọ̀rọ̀ Allāhu jìnnà sí àyè ìhunrírà (bí ilé ọtí), ilé eré àti ilé awàdà nítorí pé, àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀ kò níí kọbi ara sí olùsọ̀rọ̀. Āyah yìí jọ sūrah an-Nisā’; 4:140 àti sūrah al-’Ani‘ām; 6:68.
Las Exégesis Árabes:
سَيَذَّكَّرُ مَن يَخۡشَىٰ
Ẹni tí ó máa páyà (Allāhu) máa lo ìrántí.
Las Exégesis Árabes:
وَيَتَجَنَّبُهَا ٱلۡأَشۡقَى
Olórí-burúkú sì máa takété sí i.
Las Exégesis Árabes:
ٱلَّذِي يَصۡلَى ٱلنَّارَ ٱلۡكُبۡرَىٰ
(Òun sì ni) ẹni tí ó máa wọ inú Iná tó tóbi.
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ لَا يَمُوتُ فِيهَا وَلَا يَحۡيَىٰ
Lẹ́yìn náà, kò níí kú sínú rẹ̀, kò sì níí ṣẹ̀mí (àlàáfíà).
Las Exégesis Árabes:
قَدۡ أَفۡلَحَ مَن تَزَكَّىٰ
Dájúdájú ẹni tí ó bá ṣe àfọ̀mọ́ (ẹ̀sìn rẹ̀) ti jèrè.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Mu’minūn; 23:4.
Las Exégesis Árabes:
وَذَكَرَ ٱسۡمَ رَبِّهِۦ فَصَلَّىٰ
Ó sì rántí orúkọ Olúwa rẹ̀, ó sì kírun.
Las Exégesis Árabes:
بَلۡ تُؤۡثِرُونَ ٱلۡحَيَوٰةَ ٱلدُّنۡيَا
Rárá, ńṣe l’ẹ̀ ń gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلۡأٓخِرَةُ خَيۡرٞ وَأَبۡقَىٰٓ
Ọ̀run sì lóore jùlọ, ó sì máa wà títí láéláé.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّ هَٰذَا لَفِي ٱلصُّحُفِ ٱلۡأُولَىٰ
Dájúdájú èyí wà nínú àwọn tákàǹdá àkọ́kọ́,
Las Exégesis Árabes:
صُحُفِ إِبۡرَٰهِيمَ وَمُوسَىٰ
tákàdá (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm àti (Ànábì) Mūsā.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Capítulo: Sura Al-A'laa
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar