Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Capítulo: Sura Al-Balad   Versículo:

Suuratul-Balad

لَآ أُقۡسِمُ بِهَٰذَا ٱلۡبَلَدِ
Èmi (Allāhu) ń fi ìlú yìí[1] búra.
1. Allāhu lè fi ohunkóhun búra, àmọ́ fífi Allāhu nìkan ṣoṣo búra ni ẹ̀sìn gbà àwa láyè mọ láti fi búra. Bíbá Allāhu wá akẹgbẹ́ (ẹbọ ṣíṣe) sì ni fífi n̄ǹkan mìíràn búra lẹ́yìn Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā -.
Las Exégesis Árabes:
وَأَنتَ حِلُّۢ بِهَٰذَا ٱلۡبَلَدِ
Ìwọ sì ní ẹ̀tọ́ sí ìlú yìí (láti jagun nínú rẹ̀).[1]
1. Ẹ̀tọ́ tí Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā - fún Ànábì Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ni kíkógun ja ìlú Mọkkah lásìkò ogun Ìṣí Mọkkah “Fat-hu Mọkkah”. Ṣíwájú àsìkò yìí àti lẹ́yìn rẹ̀, kò lẹ́tọ̀ọ́ fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti jagun nínú ìlú Mọkkah alápọ̀n-ọ́nlé.
Las Exégesis Árabes:
وَوَالِدٖ وَمَا وَلَدَ
Èmi (Allāhu) ń fi òbí àti ohun tó bí búra.
Las Exégesis Árabes:
لَقَدۡ خَلَقۡنَا ٱلۡإِنسَٰنَ فِي كَبَدٍ
Dájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn sínú ìṣòro.
Las Exégesis Árabes:
أَيَحۡسَبُ أَن لَّن يَقۡدِرَ عَلَيۡهِ أَحَدٞ
Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò ní agbára lórí òun ni?
Las Exégesis Árabes:
يَقُولُ أَهۡلَكۡتُ مَالٗا لُّبَدًا
Ó (sì) ń wí pé: “Èmi ti bàná dúkìá ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (láti fi tako Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -)”
Las Exégesis Árabes:
أَيَحۡسَبُ أَن لَّمۡ يَرَهُۥٓ أَحَدٌ
Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò rí òun ni?
Las Exégesis Árabes:
أَلَمۡ نَجۡعَل لَّهُۥ عَيۡنَيۡنِ
Ṣé A kò ṣe ojú méjì fún un?
Las Exégesis Árabes:
وَلِسَانٗا وَشَفَتَيۡنِ
Àti ahọ́n pẹ̀lú ètè méjì (tí A ṣe fún un)?
Las Exégesis Árabes:
وَهَدَيۡنَٰهُ ٱلنَّجۡدَيۡنِ
A sì fi ọ̀nà méjì mọ̀ ọ́n.
Las Exégesis Árabes:
فَلَا ٱقۡتَحَمَ ٱلۡعَقَبَةَ
Kò sì lọ rin ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí níbi Iná!
Las Exégesis Árabes:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا ٱلۡعَقَبَةُ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí?
Las Exégesis Árabes:
فَكُّ رَقَبَةٍ
(Òhun ni) títú ẹrú sílẹ̀ lóko ẹrú.
Las Exégesis Árabes:
أَوۡ إِطۡعَٰمٞ فِي يَوۡمٖ ذِي مَسۡغَبَةٖ
Tàbí fífún ènìyàn ní oúnjẹ ní ọjọ́ ebi.
Las Exégesis Árabes:
يَتِيمٗا ذَا مَقۡرَبَةٍ
(Ẹ lè fún) ọmọ-òrukàn nínú ẹbí,
Las Exégesis Árabes:
أَوۡ مِسۡكِينٗا ذَا مَتۡرَبَةٖ
tàbí mẹ̀kúnnù tí kò ní gá tí kò ní go (olòṣì paraku).
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ كَانَ مِنَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ وَتَوَاصَوۡاْ بِٱلصَّبۡرِ وَتَوَاصَوۡاْ بِٱلۡمَرۡحَمَةِ
Lẹ́yìn náà, kí ó wà nínú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ń gbara wọn níyànjú sùúrù ṣíṣe, tí wọ́n sì tún ń gbara wọn níyànjú àánú ṣíṣe.
Las Exégesis Árabes:
أُوْلَٰٓئِكَ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَيۡمَنَةِ
Àwọn wọ̀nyẹn ni èrò ọwọ́ ọ̀tún.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلَّذِينَ كَفَرُواْ بِـَٔايَٰتِنَا هُمۡ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَشۡـَٔمَةِ
Àwọn tó sì ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Wa, àwọn ni èrò ọwọ́ òsì.[1]
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:7.
Las Exégesis Árabes:
عَلَيۡهِمۡ نَارٞ مُّؤۡصَدَةُۢ
Wọ́n máa ti àwọn ìlẹ̀kùn Iná pa mọ́ wọn lórí pátápátá.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Capítulo: Sura Al-Balad
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar