TiRẹ̀ ni ìpè òdodo. Àwọn tí wọ́n ń pè lẹ́yìn Rẹ̀, wọn kò lè fi kiní kan jẹ́ pè wọn àfi bí ẹni tí ó tẹ́wọ́ rẹ̀ méjèèjì (lásán) sí omi nítorí kí omi lè dé ẹnu rẹ̀. Omi kò sì lè dé ẹnu rẹ̀. Àdúà (àti ìpè) àwọn aláìgbàgbọ́ kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe sínú ìṣìnà.¹
1. Nínú sūrah al-Baƙọrah; 2:186, Allāhu - subhānahu wa ta'ālā - fi kalmọh “rọṣād” parí àdúà àwọn onígbàgbọ́ òdodo (ìyẹn, “la‘llahum yẹrṣudūn”) àmọ́ nínú sūrah yìí àti sūrah Gọ̄fir; 40:50 , Ó fi kalmọh “dọlāl” parí àdúà àwọn aláìgbàgbọ́. “Rọṣād” túmọ̀ sí “ìmọ̀nà”, “dọlāl” sì túmọ̀ sí “ìṣìnà”. Àdúà tó wà lórí ìmọ̀nà ni àdúà tó máa lọ tààrà sọ́dọ̀ Allāhu. Àdúà náà sì máa jẹ́ àtẹ́wọ́gbà. Èyí ni Allāhu fi rinlẹ̀ nínú sūrah aṣ-Ṣūrọ̄; 42:26. Àmọ́ àdúà tó wà lórí ìṣìnà, kò níí lọ sọ́dọ̀ Allāhu. Ẹ̀dá tí wọ́n sì dojú àdúà kọ kò níí gbọ́ ìpè náà, áḿbọ̀sìbọ́sí pé ó máa jẹ́pè rẹ̀ (ní ìbámu sí sūrah al-’Ahƙọ̄f; 46:5). Kò sì sí ẹni tí ó ń gba àdúà lẹ́yìn Allāhu. Ìdí nìyí tí àdúà náà fi máa gúnlẹ̀ sí èbúté anù àti òfò. Kí á wá wòye sí àwọn n̄ǹkan méjì wọ̀nyí: Ìkíní: Ọ̀nà wo ni àwọn aláìgbàgbọ́ ń gbà rí oore láyé? Kò sí oore ayé kan ní'lé ayé tí ó lè tẹ aláìgbàgbọ́ lọ́wọ́ nípasẹ̀ àdúà bí kò ṣe nípasẹ̀ ìpín kan tí ó wà fún un nínú kádàrá rẹ̀. Àmọ́ ní ti onígbàgbọ́ òdodo, oore inú kádàrá àti oore àdúà ló wà fún un níwọ̀n ìgbà tí àdúà rẹ̀ bá ti wà ní ìbámu sí sunnah Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - .
Ìkejì: Ìdí tí kò fi sí gbígbà àdúà fún àwọn aláìgbàgbọ́ ni pé, wọ́n dojú àdúà wọn kọ àwọn ẹ̀dá kan lẹ́yìn Allāhu - tó ga jùlọ - . Bí mùsùlùmí kan bá ṣe bẹ́ẹ̀, tàbí ó ṣe “āmīn” sí àdúà ẹni tí ó ṣe bẹ́ẹ̀, òun náà kò níí rí gbígbà àdúà náà, ẹ̀sìn rẹ̀ sì máa bàjẹ́ pẹ̀lú.
Contents of the translations can be downloaded and re-published, with the following terms and conditions:
1. No modification, addition, or deletion of the content.
2. Clearly referring to the publisher and the source (QuranEnc.com).
3. Mentioning the version number when re-publishing the translation.
4. Keeping the transcript information inside the document.
5. Notifying the source (QuranEnc.com) of any note on the translation.
6. Updating the translation according to the latest version issued from the source (QuranEnc.com).
7. Inappropriate advertisements must not be included when displaying translations of the meanings of the Noble Quran.
Résultats de la recherche:
API specs
Endpoints:
Sura translation
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/sura/{translation_key}/{sura_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified sura (by its number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114)
Returns:
json object containing array of objects, each object contains the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/aya/{translation_key}/{sura_number}/{aya_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified aya (by its number sura_number and aya_number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114) aya_number: [1-...] (Aya number in the sura)
Returns:
json object containing the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".