Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Verset: (19) Sourate: MARIAM
قَالَ إِنَّمَآ أَنَا۠ رَسُولُ رَبِّكِ لِأَهَبَ لَكِ غُلَٰمٗا زَكِيّٗا
(Mọlāika) sọ pé: “Èmi ni Òjíṣẹ́ Olúwa rẹ, (Ó rán mi sí ọ) pé kí n̄g fún ọ ní ọmọkùnrin mímọ́ kan.”¹
1. Àwọn nasọ̄rọ̄ ń sọ pé Ànábì ‘Īsā - kí ọlà Allāhu máa bá a - nìkan ṣoṣo ni al-Ƙur’ān pè ní “ẹni mímọ́” gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà nínú āyah yìí. Èsì ní ṣókí ni pé, ní òdodo ẹni mímọ́ ni Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a -, àmọ́ kì í ṣe òun nìkan ni ẹni mímọ́. Āayah 13 nínú sūrah yìí kan náà pe Ànábì Yahyā - kí ọlà Allāhu máa bá a - ní ẹni mímọ́. Bákan náà, ọmọ tí àsọọ́lẹ̀ wáyé lórí rẹ̀ nínú sūrah al-Kahf; 17:81, ẹni mímọ́ ni al-Ƙur’ān pe òun náà. Báwo ni jíjẹ́ ẹni mímọ́ Ànábì ‘Īsā ṣe máa sọ ọ́ di olúwa àti olùgbàlà nígbà tí jíjẹ́ ẹni mímọ́ àwọn méjèèjì wọ̀nyẹn kò sọ wọ́n di bẹ́ẹ̀.
Sì kíyè sì i, gbogbo àwọn Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun nínú al-Ƙur’ān ni ẹni mímọ́. Àti pé ìdà kejì ẹni mímọ́ ni ẹni àìmọ́. Báwo ni Allāhu ṣe máa fi iṣẹ́ mímọ́ rán ẹni àìmọ́? Kò lè ṣẹlẹ̀. Ṣíwájú sí i, nínú èdè Lárúbáwá, ìsọdorúkọ olùṣe fún “ẹni mímọ́” ni “zakiyyun”, ìsọdorúkọ àfòyemọ̀ fún “mímọ́” ni “zakāt”. Ìgbà tí ìròyìn bá bùáyà tán lára ẹni tí a fẹ́ pọ́n ní àpọ́npo, dípò kí Lárúbáwá lo ìsọdorúkọ olùṣe fún irú ẹni náà, ìsọdorúkọ àfòyemọ̀ ni wọ́n máa lò. Ìyẹn ni pé, jíjẹ́ ẹni mímọ́ tó lágbára gan-an ni ìlò èdè tí al-Ƙur’ān lò fún Ànábì Yahyā - kí ọlà Allāhu máa bá a - àti ọmọ alásọọ́lẹ̀ náà. Ta wá ni ó mọ́ jùlọ láààrin “zakiyyu” tó túmọ̀ sí “ẹni mímọ́” àti “zakāt” tó túmọ̀ sí “mímọ́”? Kò wa tán bí!
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Verset: (19) Sourate: MARIAM
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture