Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Verset: (67) Sourate: AL-HAJJ
لِّكُلِّ أُمَّةٖ جَعَلۡنَا مَنسَكًا هُمۡ نَاسِكُوهُۖ فَلَا يُنَٰزِعُنَّكَ فِي ٱلۡأَمۡرِۚ وَٱدۡعُ إِلَىٰ رَبِّكَۖ إِنَّكَ لَعَلَىٰ هُدٗى مُّسۡتَقِيمٖ
Ìjọ kọ̀ọ̀kan l’A fún ní ìlànà tí wọ́n máa lò. Nítorí náà, kí wọ́n má ṣe jà ọ́ níyàn nípa ọ̀rọ̀ náà. Kí o sì pèpè sọ́dọ̀ Olúwa rẹ. Dájúdájú o kúkú wà lójú ọ̀nà tààrà. ¹
1. Gbólóhùn yìí “Ìjọ kọ̀ọ̀kan l’A fún ní ìlànà tí wọ́n máa lò.” Ìyẹn nínú ’Islām tí Allāhu fi rán Òjíṣẹ́ wọn sí wọn nítorí pé, ’Islām ni ẹ̀sìn gbogbo àwọn Ànábì àti àwọn Òjísẹ́ Olọ́hun, àmọ́ ìlànà ìjọ́sìn kan láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn lè yàtọ̀. Bí àpẹ̀ẹrẹ, kò sí ìjọ Òjíṣẹ́ kan tí kò ní ìrun tirẹ̀, àmọ́ òǹkà rakaa àti àsìkò ìrun ń yàtọ̀ láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn.
Bákan náà ni ìyàtọ̀ tún lè wà nínú ìṣe àti àṣà láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn. Bí àpẹ̀ẹrẹ, àṣà ìkúnlẹ̀-kíni jẹ́ ìṣe tó ní ẹ̀tọ́ nínú ìjọ ìṣáájú, àmọ́ tí ó jẹ́ ìṣe tí ó di èèwọ̀ nínú ìjọ Ànábì wa Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - . Gbogbo ìjọ Òjíṣẹ́ ni wọ́n lè yàtọ̀ síra wọn ní ojú pọ̀n-nà wọ̀nyẹn, àmọ́ kò sí ìyàtọ̀ láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn lórí jíjẹ́ tí Allāhu ń jẹ́ Ọlọ́hun ọ̀kan ṣoṣo, Olúwa àti Olùgbàlà. Allāhu sì ṣe ẹbọ ṣíṣe ní èèwọ̀ fún gbogbo wọn pátápátá. Èyí gan-an ni ìpìlẹ̀ fún ìgbàgbọ́ òdodo tí gbogbo àwọn Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun mú wá - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá wọn - .
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Verset: (67) Sourate: AL-HAJJ
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture