Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Verset: (2) Sourate: AN-NOUR
ٱلزَّانِيَةُ وَٱلزَّانِي فَٱجۡلِدُواْ كُلَّ وَٰحِدٖ مِّنۡهُمَا مِاْئَةَ جَلۡدَةٖۖ وَلَا تَأۡخُذۡكُم بِهِمَا رَأۡفَةٞ فِي دِينِ ٱللَّهِ إِن كُنتُمۡ تُؤۡمِنُونَ بِٱللَّهِ وَٱلۡيَوۡمِ ٱلۡأٓخِرِۖ وَلۡيَشۡهَدۡ عَذَابَهُمَا طَآئِفَةٞ مِّنَ ٱلۡمُؤۡمِنِينَ
Onísìná lóbìnrin àti onísìná lọ́kùnrin, ẹ na ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú àwọn méjèèjì ní ọgọ́rùn-ún kòbókò. Ẹ má ṣe jẹ́ kí àánú wọn ṣe yín nípa ìdájọ́ Allāhu tí ẹ bá ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu àti Ọjọ́ Ìkẹ́yìn. Kí igun kan nínú àwọn onígbàgbọ́ òdodo sì jẹ́rìí sí ìyà àwọn méjèèjì.¹
1. Ọgọ́rùn-ún kòbókò àti ẹ̀wọ̀n ọdún kan tàbí ọgọ́rùn-ún kòbókò àti lílé kúrò nínú ìlú fún ọdún kan ni ìjìyà fún onísìná tí kò ì ṣe ‘akdu-nnikāh pẹ̀lú ẹnikẹ́ni rí. Àmọ́ lílẹ̀ lókòpa ni ìjìyà fún onísìná tí ó ti ṣe ‘akdu-nnikāh rí. Ẹ̀dá ìbá mọ ìjìyà wọ̀nyí lọ́ràn, ìbá jìnnà sí àgbèrè ṣíṣe. Ìwọ arákùnrin àti arábìnrin mi, bí ọ̀ràn sìná bá fúyẹ́ ni, ìbá tí la ìjìyà lọ bí kò ṣe títọrọ àforíjìn lọ́dọ̀ Allāhu - tó ga jùlọ -.
Ronú pìwàdà lónìí, má sì ṣe tìràn mọ́ àìsí Ṣẹria lórílẹ̀ èdè wa.
Ó ṣeé ṣe kí ẹnì kan sọ pé, āyah wo ló ní kí á lẹ onísìná tó ti ṣe ‘akdu-nnikāh rí lókò pa? Kì í ṣe āyah nìkan ni mùsùlùmí ń tẹ̀lé nínú Ṣẹria àti ohun gbogbo tó rọ̀mọ́ ẹ̀sìn rẹ̀. Hadīth Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ló ṣe é lófin fún wa láti ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí pé, lílẹ̀ lókòpa ni ìjìyà tí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - gbé dìde lórí àwọn kan tí wọ́n jẹ́wọ́ ọ̀ràn sìná lásìkò rẹ̀. Bí ó sì ṣe wà nìyẹn nínú òfin Ànábì Mūsā àti Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam. Ìdájọ́ tí Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - náà mú wá nìyẹn. Kò sì sí āyah kan tó lòdì sí èyí. Mùsùlùmí tó bá sì yapa Ànábì wa - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - lórí èyí ti sọnù jìnnà.
Bákan náà, bí ẹni tí kò sí nílé ọkọ bá ṣe zinā, tí ó sì doyún, ọmọ náà kò níí jẹ́ ọmọ fún arákùnrin tó ṣe zinā pẹ̀lú arábìnrin náà, kò sì níí jẹ́ orúkọ rẹ̀ àyàfi tí ó bá fi rinlẹ̀ pé òun l’òun ni oyún. Ọmọ rẹ̀ ni ọmọ náà, àmọ́ ó bí i nípasẹ̀ zinā. Ìkíní kejì bàbá àti ìyá ọmọ náà sì lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjìyà zinā láti rí àforíjìn Ọlọ́hun.
Síwájú sí i, àwọn onímọ̀ yapa-ẹnu lórí síso yìgì lórí oyún sìná. Àwọn kan sọ pé wọ́n lè so yìgì lórí oyún sìná. Àwọn mìíràn sì sọ pé kò lẹ́tọ̀ọ́.
Bákan náà, waliyyu ọmọbìnrin náà lẹ́tọ̀ọ́ láti kọ ìtakókó yìgì fún arákùnrin náà lẹ́yìn ìbímọ tí kò bá yọ́nú sí ẹ̀sìn àti ìwà arákùnrin náà.
Àmọ́ lábẹ́ àìmọ̀kan, tọkọ tìyàwó tó bẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé wọn lórí zinā, waliyyu obìnrin lẹ́tọ̀ọ́ láti ṣe ìtakókó yìgì fún arákùnrin náà, wọn ìbáà ti bí ọmọ púpọ̀ fúnra wọn ṣíwájú. Èyí sì ni àtúnṣe ọ̀rọ̀ àwọn méjèèjì.
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Verset: (2) Sourate: AN-NOUR
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture