Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Verset: (23) Sourate: ACH-CHOURÂ
ذَٰلِكَ ٱلَّذِي يُبَشِّرُ ٱللَّهُ عِبَادَهُ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ وَعَمِلُواْ ٱلصَّٰلِحَٰتِۗ قُل لَّآ أَسۡـَٔلُكُمۡ عَلَيۡهِ أَجۡرًا إِلَّا ٱلۡمَوَدَّةَ فِي ٱلۡقُرۡبَىٰۗ وَمَن يَقۡتَرِفۡ حَسَنَةٗ نَّزِدۡ لَهُۥ فِيهَا حُسۡنًاۚ إِنَّ ٱللَّهَ غَفُورٞ شَكُورٌ
Ìyẹn ni èyí tí Allāhu fi ń ṣe ìró ìdùnnú fún àwọn ẹrúsìn Rẹ̀, àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere. Sọ pé: “Èmi kò bèèrè owó-ọ̀yà lọ́wọ́ yín lórí rẹ̀ bí kò ṣe ìfẹ́ ẹbí.”¹ Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe rere kan, A máa ṣe àlékún rere fún un. Dájúdájú Allāhu ni Aláforíjìn, Ọlọ́pẹ́.²
1. Ìyẹn ni pé, Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ń sọ fún àwọn ẹbí rẹ̀ pé, ẹ má ṣe tìtorí pé mò ń pèyín sínú ẹ̀sìn ’Islām kí ẹ wá máa fi ìnira kan èmi àti àwọn ará ilé mi. Èmi kò kúkú bèèrè owó-ọ̀yà kan kan lọ́wọ́ yín. Ẹ sì mọ̀ pé ẹbí ni wá. Ẹbí sì gbọ́dọ̀ ní ìfẹ́ ẹbí rẹ̀. Nítorí náà, ẹ má ṣe fi fífi ìnira kan ará ilé mi ṣe ẹ̀san fún mi.
2. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:158.
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Verset: (23) Sourate: ACH-CHOURÂ
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture